< Job 36 >
1 Elihu sì tún sọ̀rọ̀ wí pé,
Elihu puhui vielä ja sanoi:
2 “Fún mi láyè díẹ̀ èmi ó sì fihàn ọ́, nítorí ọ̀rọ̀ sísọ ní ó kún fún Ọlọ́run.
Odota vielä vähä, minä osoitan sinulle sen; sillä minulla on vielä nyt jotakin Jumalan puolesta sanomista.
3 Èmi ó mú ìmọ̀ mi ti ọ̀nà jíjìn wá, èmi ó sì fi òdodo fún Ẹlẹ́dàá mi.
Minä tuon minun ymmärrykseni kaukaa, ja osoitan, että minun Luojani on hurskas.
4 Rí i dájú pé ọ̀rọ̀ mi kì yóò ṣèké nítòótọ́; ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
Sillä minun puheessani ei tosin ole petosta, minun ymmärrykseni on vilpitöin sinun edessäs.
5 “Kíyèsi i, Ọlọ́run ni alágbára, òun kò i sì gàn ènìyàn; ó ní agbára ní ipá àti òye.
Katso, Jumala on voimallinen, ei kuitenkaan hän ketään hylkää: Hän on voimallinen sydämensä väestä.
6 Òun kì í dá ẹ̀mí ènìyàn búburú sí, ṣùgbọ́n ó fi òtítọ́ fún àwọn tálákà.
Jumalatointa ei hän varjele, vaan auttaa köyhää oikeuteen.
7 Òun kì í mú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo, ṣùgbọ́n àwọn ọba ni wọ́n wà lórí ìtẹ́; àní ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé, a sì gbé wọn lékè.
Ei hän käännä silmiänsä pois hurskaasta: hän on myös kuningasten kanssa istuimella: hän antaa heidän pysyä alinomati, että he korkiaksi tulevat.
8 Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà, tí a sì fi okùn ìpọ́njú dè wọ́n,
Ja ehkä vangit olisivat jalkapuussa, ja sidottuna surkeuden köysillä:
9 nígbà náà ni ó ń sọ àwọn ohun tí wọn ti ṣe fún wọn, wí pé wọ́n ti ṣẹ̀ pẹ̀lú ìgbéraga wọn.
Niin hän ilmoittaa heille heidän työnsä ja rikoksensa, että he ovat tehneet väkivaltaa,
10 Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́, ó sì pàṣẹ kí wọn kí ó padà kúrò nínú àìṣedédé.
Ja avaa heidän korvansa kuritukseen, ja sanoo heille, että he kääntyisivät pois vääryydestä.
11 Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín, wọn ó lo ọjọ́ wọn ní ìrọ̀rùn, àti ọdún wọn nínú afẹ́.
Jos he kuulevat ja palvelevat häntä, niin he hyvissä päivissä vanhenevat ja ilolla elävät.
12 Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́, wọ́n ó ti ọwọ́ idà ṣègbé, wọ́n á sì kú láìní òye.
Jos ei he kuule, niin he kaatuvat miekalla, ja hukkuvat ennenkuin he sen havaitsevat.
13 “Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní ayé kó ìbínú jọ; wọn kò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nígbà tí ó bá wọ́n wí.
Ulkokullatut kartuttavat vihan: ei he huuda, kuin he vankina ovat;
14 Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú ní èwe, ní àárín àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà.
Niin heidän sielunsa kuolee nuoruudessa, ja heidän elämänsä huorintekiäin seassa.
15 Òun gba òtòṣì nínú ìpọ́njú wọn, a sì sọ̀rọ̀ sí wọn ní etí nínú ìnira wọn.
Mutta vaivaista auttaa hän vaivaisuudessa, ja avaa köyhäin korvan murheessa.
16 “Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó fa wọn yọ láti inú ìhágágá sí ibi gbòòrò, sí ibi tí ó ní ààyè tí kò ní wàhálà nínú rẹ̀, ohun tí a sì gbé kalẹ̀ ní tábìlì rẹ̀ jẹ́ kìkì ọ̀rá oúnjẹ tí ó fẹ́.
Hän tempaa sinunkin ahdistuksen kidasta avaruuteen, jolla ei pohjaa ole; ja sinun pöydälläs on lepo, täytetty kaikella hyvällä.
17 Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọn búburú; ìdájọ́ àti òtítọ́ dì ọ́ mú.
Ja sinä olet täydellisesti havaitseva jumalattoman tuomion; mutta tuomio ja oikeus vahvistaa sinun.
18 Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹ máa bá a tàn ọ; láti jẹ́ kí títóbi rẹ mú ọ ṣìnà.
Katso, ettei viha ole vietellyt sinua voimassas, eli suuret lahjat ole kääntäneet sinua.
19 Ọrọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fi dé bá ọ bí? Tàbí ipa agbára rẹ?
Luuletkos hänen huolivan jalouttas, kultaa eli jonkun väkevyyttä ja varaa?
20 Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò ní ipò wọn.
Ei sinun tarvitse ikävöidä yötä, karatakses ihmisten päälle siallansa.
21 Máa ṣọ́ra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀ padà sí búburú, nítorí èyí tí ìwọ rò pé ó dára jù ìpọ́njú lọ.
Kavahda sinuas, ja älä käännä sinuas vääryyteen, niikuin sinä surkeuden tähden ruvennut olet.
22 “Kíyèsi i, Ọlọ́run ni gbéga nípa agbára rẹ̀; ta ni jẹ́ olùkọ́ni bí rẹ̀?
Katso, Jumala on korkia voimassansa: kuka on senkaltainen opettaja kuin hän on?
23 Ta ni ó là ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ fún un, tàbí ta ni ó lè wí pé ìwọ ti ń ṣe àìṣedéédéé?
Kuka tutkii hänen tiensä? ja kuka sanoo hänelle: sinä teet väärin?
24 Rántí kí ìwọ kí ó gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga, ti ènìyàn ni yín nínú orin.
Muista, ettäs ylistät hänen töitänsä, niinkuin ihmiset veisaavat.
25 Olúkúlùkù ènìyàn a máa rí i; ẹni ikú a máa wò ó ní òkèrè.
Sillä kaikki ihmiset sen nähneet ovat: Ihmiset näkevät sen kaukaa.
26 Kíyèsi i, Ọlọ́run tóbi, àwa kò sì mọ̀ bí ó ti ní òye tó, bẹ́ẹ̀ ni a kò lè wádìí iye ọdún rẹ̀ rí.
Katso, Jumala on suuri, ja emme tiedä sitä: hänen vuosilukunsa ovat arvaamattomat.
27 “Nítorí pé òun ni ó fa ìkán omi òjò sílẹ̀, kí wọn kí ó kán bí òjò ní ìkùùkuu rẹ̀,
Sillä hän tekee veden pieniksi pisaroiksi, ja ajaa pilvensä kokoon sateeksi,
28 tí àwọsánmọ̀ ń rọ̀ ìrì rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì fi ń sẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ lórí ènìyàn.
Että pilvet pisaroitsevat ja vuotavat vahvasti ihmisten päälle.
29 Pẹ̀lúpẹ̀lú ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè ní ìmọ̀ ìtànká àwọsánmọ̀, tàbí ariwo àrá láti àgọ́ rẹ̀?
Koska hän aikoo hajoittaa pilvensä ja majansa jylinän.
30 Kíyèsi i, ó tan ìmọ́lẹ̀ yí ara rẹ̀ ká ó sì bo ìsàlẹ̀ òkun mọ́lẹ̀.
Katso, niin hän levittää valkeutensa sen päälle, ja peittää meren syvyyden.
31 Nítorí pé nípa wọn ní ń ṣe dájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ènìyàn; ó sí ń pèsè oúnjẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Sillä näillä tuomitsee hän kansan; ja antaa ruokaa runsaasti.
32 Ó fi ìmọ́lẹ̀ bo ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì ó sì rán an sí ẹni olódì.
Hän kätkee valkeuden käsissänsä, ja käskee sen palata.
33 Ariwo àrá rẹ̀ fi ìjì hàn ní; ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú wí pé, ó súnmọ́ etílé!
Sen ilmoittaa hänen lähimmäisensä, joka on pitkäisen viha pilvissä.