< Job 35 >
And Elihu answereth and saith: —
2 “Ìwọ rò pé èyí ha tọ́, tí ìwọ wí pé, òdodo mi ni èyí níwájú Ọlọ́run?
This hast thou reckoned for judgment: Thou hast said — 'My righteousness [is] more than God's?'
3 Nítorí tí ìwọ wí pé èrè kí ní yóò jásí fún ọ, tàbí èrè kí ni èmi yóò fi jẹ́ ju èrè ẹ̀ṣẹ̀ mi lọ.
For thou sayest, 'What doth it profit Thee! What do I profit from my sin?'
4 “Èmi ó dá ọ lóhùn àti àwọn ẹgbẹ́ rẹ pẹ̀lú rẹ.
I return thee words, and thy friends with thee,
5 Síjú wo ọ̀run; kí o rí i, kí ó sì bojú wo àwọsánmọ̀ tí ó ga jù ọ́ lọ.
Behold attentively the heavens — and see, And behold the clouds, They have been higher than thou.
6 Bí ìwọ bá dẹ́ṣẹ̀, kí ni ìwọ fi sẹ̀ sí? Tàbí bí ìrékọjá rẹ di púpọ̀, kí ni ìwọ fi èyí nì ṣe sí i?
If thou hast sinned, what dost thou against Him? And thy transgressions have been multiplied, What dost thou to Him?
7 Bí ìwọ bá sì ṣe olódodo, kí ni ìwọ fi fún un, tàbí kí ni òun rí gbà láti ọwọ́ rẹ wá?
If thou hast been righteous, What dost thou give to Him? Or what from thy hand doth He receive?
8 Ìwà búburú rẹ ni fún ènìyàn bí ìwọ; òdodo rẹ sì ni fún ọmọ ènìyàn.
For a man like thyself [is] thy wickedness, And for a son of man thy righteousness.
9 “Nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìninilára, wọ́n mú ni kígbe; wọ́n kígbe nípa apá àwọn alágbára.
Because of the multitude of oppressions They cause to cry out, They cry because of the arm of the mighty.
10 Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó wí pé, ‘Níbo ni Ọlọ́run Ẹlẹ́dàá mi wà tí ó sì fi orin fún mi ní òru;
And none said, 'Where [is] God my maker? Giving songs in the night,
11 tí òun kọ́ wa ní ẹ̀kọ́ jù àwọn ẹranko ayé lọ, tí ó sì mú wa gbọ́n ju àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run lọ?’
Teaching us more than the beasts of the earth, Yea, than the fowl of the heavens He maketh us wiser.'
12 Nígbà náà ni wọ́n ń ké ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò dáhùn nítorí ìgbéraga ènìyàn búburú.
There they cry, and He doth not answer, Because of the pride of evil doers.
13 Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ asán; bẹ́ẹ̀ ní Olódùmarè kì yóò kà á sí.
Surely vanity God doth not hear, And the Mighty doth not behold it.
14 Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ìwọ wí pé ìwọ kì í rí i, ọ̀rọ̀ ìdájọ́ ń bẹ níwájú rẹ, ẹni tí ìwọ sì gbọdọ̀ dúró dè.
Yea, though thou sayest thou dost not behold Him, Judgment [is] before Him, and stay for Him.
15 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí nítorí tí ìbínú rẹ̀ kò tí fìyà jẹ ni, òun kò ni ka ìwà búburú si?
And, now, because there is not, He hath appointed His anger, And He hath not known in great extremity.
16 Nítorí náà ní Jobu ṣe ya ẹnu rẹ̀ lásán ó sọ ọ̀rọ̀ di púpọ̀ láìsí ìmọ̀.”
And Job [with] vanity doth open his mouth, Without knowledge words he multiplieth.