< Job 35 >
Elihu spoke moreover, and said,
2 “Ìwọ rò pé èyí ha tọ́, tí ìwọ wí pé, òdodo mi ni èyí níwájú Ọlọ́run?
Thinkest thou this to be right, [that] thou saidst, My righteousness [is] more than God's?
3 Nítorí tí ìwọ wí pé èrè kí ní yóò jásí fún ọ, tàbí èrè kí ni èmi yóò fi jẹ́ ju èrè ẹ̀ṣẹ̀ mi lọ.
For thou saidst, What advantage will it be to thee? [and], What profit shall I have, [if I be cleansed] from my sin?
4 “Èmi ó dá ọ lóhùn àti àwọn ẹgbẹ́ rẹ pẹ̀lú rẹ.
I will answer thee, and thy companions with thee.
5 Síjú wo ọ̀run; kí o rí i, kí ó sì bojú wo àwọsánmọ̀ tí ó ga jù ọ́ lọ.
Look to the heavens, and see; and behold the clouds [which] are higher than thou.
6 Bí ìwọ bá dẹ́ṣẹ̀, kí ni ìwọ fi sẹ̀ sí? Tàbí bí ìrékọjá rẹ di púpọ̀, kí ni ìwọ fi èyí nì ṣe sí i?
If thou sinnest, what doest thou against him? or [if] thy transgressions are multiplied, what doest thou to him?
7 Bí ìwọ bá sì ṣe olódodo, kí ni ìwọ fi fún un, tàbí kí ni òun rí gbà láti ọwọ́ rẹ wá?
If thou art righteous, what givest thou to him? or what receiveth he from thy hand?
8 Ìwà búburú rẹ ni fún ènìyàn bí ìwọ; òdodo rẹ sì ni fún ọmọ ènìyàn.
Thy wickedness [may hurt] a man as thou [art]: and thy righteousness [may profit] the son of man.
9 “Nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìninilára, wọ́n mú ni kígbe; wọ́n kígbe nípa apá àwọn alágbára.
By reason of the multitude of oppressions they make [the oppressed] to cry: they cry out by reason of the arm of the mighty.
10 Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó wí pé, ‘Níbo ni Ọlọ́run Ẹlẹ́dàá mi wà tí ó sì fi orin fún mi ní òru;
But none saith, Where [is] God my maker, who giveth songs in the night;
11 tí òun kọ́ wa ní ẹ̀kọ́ jù àwọn ẹranko ayé lọ, tí ó sì mú wa gbọ́n ju àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run lọ?’
Who teacheth us more than the beasts of the earth, and maketh us wiser than the fowls of heaven?
12 Nígbà náà ni wọ́n ń ké ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò dáhùn nítorí ìgbéraga ènìyàn búburú.
There they cry, but none giveth answer, because of the pride of evil men.
13 Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ asán; bẹ́ẹ̀ ní Olódùmarè kì yóò kà á sí.
Surely God will not hear vanity, neither will the Almighty regard it.
14 Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ìwọ wí pé ìwọ kì í rí i, ọ̀rọ̀ ìdájọ́ ń bẹ níwájú rẹ, ẹni tí ìwọ sì gbọdọ̀ dúró dè.
Although thou sayest thou shalt not see him, [yet] judgment [is] before him; therefore trust thou in him.
15 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí nítorí tí ìbínú rẹ̀ kò tí fìyà jẹ ni, òun kò ni ka ìwà búburú si?
But now, because [it is] not [so], he hath visited in his anger; yet he knoweth [it] not in great extremity:
16 Nítorí náà ní Jobu ṣe ya ẹnu rẹ̀ lásán ó sọ ọ̀rọ̀ di púpọ̀ láìsí ìmọ̀.”
Therefore doth Job open his mouth in vain; he multiplieth words without knowledge.