< Job 34 >

1 Nígbà náà ni Elihu dáhùn, ó sì wí pé,
És szóla Elihu, és monda:
2 “Ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí ẹ sì fi etí sílẹ̀ sí mi ẹ̀yin tí ẹ ní ìmòye.
Halljátok meg bölcsek az én szavaimat, és ti tudósok hajtsátok hozzám füleiteket!
3 Nítorí pé etí a máa dán ọ̀rọ̀ wò, bí adùn ẹnu ti ń tọ́ oúnjẹ wò.
Mert a fül próbálja meg a szót, mint az íny kóstolja meg az ételt.
4 Ẹ jẹ́ kí a mọ òye ohun tí o tọ́ fún ara wa; ẹ jẹ́ kí a mọ ohun tí ó dára láàrín wa.
Keressük csak magunk az igazságot, értsük meg magunk között, mi a jó?
5 “Nítorí pé Jobu wí pé, ‘Aláìlẹ́ṣẹ̀ ni èmi; Ọlọ́run sì ti gba ìdájọ́ mi lọ.
Mert Jób azt mondá: Igaz vagyok, de Isten megtagadja igazságomat.
6 Èmi ha purọ́ sí ẹ̀tọ́ mi bí, bí mo tilẹ̀ jẹ́ aláìjẹ̀bi, ọfà rẹ̀ kò ní àwòtán ọgbẹ́.’
Igazságom ellenére kell hazugnak lennem; halálos nyíl talált hibám nélkül!
7 Ọkùnrin wo ni ó dàbí Jobu, tí ń mu ẹ̀gàn bí ẹní mú omi?
Melyik ember olyan, mint Jób, a ki iszsza a csúfolást, mint a vizet.
8 Tí ń bá àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kẹ́gbẹ́ tí ó sì ń bá àwọn ènìyàn búburú rìn.
És egy társaságban forog a gonosztevőkkel, és az istentelen emberekkel jár!
9 Nítorí ó sá ti wí pé, ‘Èrè kan kò sí fún ènìyàn, tí yóò fi máa ṣe inú dídùn sí Ọlọ́run.’
Mert azt mondja: Nem használ az az embernek, ha Istennel békességben él.
10 “Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ fetísílẹ̀ sí mi, ẹ fi etí sí mi ẹ̀yin ènìyàn amòye: Ó di èèwọ̀ fún Ọlọ́run ti ìbá fi hùwà búburú, àti fún Olódùmarè, tí yóò fi ṣe àìṣedéédéé!
Azért, ti tudós emberek, hallgassatok meg engem! Távol legyen Istentől a gonoszság, és a Mindenhatótól az álnokság!
11 Nítorí pé ó ń sán fún ènìyàn fún gẹ́gẹ́ bi ohun tí a bá ṣe, yóò sì mú olúkúlùkù kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ipa ọ̀nà rẹ̀.
Sőt inkább, a mint cselekszik az ember, úgy fizet néki, és kiki az ő útja szerint találja meg, a mit keres.
12 Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò hùwàkiwà; bẹ́ẹ̀ ni Olódùmarè kì yóò yí ìdájọ́ po.
Bizonyára az Isten nem cselekszik gonoszságot, a Mindenható el nem ferdíti az igazságot!
13 Ta ni ó fi ìtọ́jú ayé lé e lọ́wọ́, tàbí ta ni ó fi gbogbo ayé lé e lọ́wọ́?
Kicsoda bízta reá a földet és ki rendezte az egész világot?
14 Bí ó bá gbé ayé rẹ̀ lé kìkì ara rẹ̀ tí ó sì gba ọkàn rẹ̀ àti ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,
Ha csak ő magára volna gondja, lelkét és lehellését magához vonná:
15 gbogbo ènìyàn ni yóò parun pọ̀, ènìyàn a sì tún padà di erùpẹ̀.
Elhervadna együtt minden test és az ember visszatérne a porba.
16 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, bí ìwọ bá ní òye, gbọ́ èyí; fetísí ohùn ẹnu mi.
Ha tehát van eszed, halld meg ezt, és a te füledet hajtsd az én beszédeimnek szavára!
17 Ẹni tí ó kórìíra òtítọ́ ha le ṣe olórí bí? Ìwọ ó ha sì dá olóòótọ́ àti ẹni ńlá lẹ́bi?
Vajjon, a ki gyűlöli az igazságot, kormányozhat-é? Avagy az ellenállhatatlan igazat kárhoztathatod-é?
18 O ha tọ́ láti wí fún ọba pé, ‘Ènìyàn búburú ní ìwọ,’ tàbí fún àwọn ọmọ-aládé pé, ‘Ìkà ni ẹ̀yin,’
A ki azt mondja a királynak: Te semmirevaló! És a főembereknek: Te gonosztevő!
19 mélòó mélòó fún ẹni tí kì í ṣe ojúsàájú àwọn ọmọ-aládé tàbí tí kò kà ọlọ́rọ̀ sí ju tálákà lọ, nítorí pé iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn í ṣe?
A ki nem nézi a fejedelmek személyét és a gazdagot a szegénynek fölibe nem helyezteti; mert mindnyájan az ő kezének munkája.
20 Ní ìṣẹ́jú kan ni wọn ó kú, àwọn ènìyàn á sì di yíyọ́ lẹ́nu láàrín ọ̀gànjọ́, wọn a sì kọjá lọ; a sì mú àwọn alágbára kúrò láìsí ọwọ́ ènìyàn níbẹ̀.
Egy pillanat alatt meghalnak; éjfélkor felriadnak a népek és elenyésznek, a hatalmas is eltűnik kéz nélkül!
21 “Nítorí pé ojú rẹ̀ ń bẹ ní ipa ọ̀nà ènìyàn, òun sì rí ìrìn rẹ̀ gbogbo.
Mert ő szemmel tartja mindenkinek útját, és minden lépését jól látja.
22 Kò sí ibi òkùnkùn, tàbí òjìji ikú, níbi tí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ yóò gbé sá pamọ́ sí.
Nincs setétség és nincs a halálnak árnyéka, a hova elrejtőzhessék a gonosztevő;
23 Nítorí pé òun kò pẹ́ àti kíyèsi ẹnìkan, kí òun kí ó sì mú lọ sínú ìdájọ́ níwájú Ọlọ́run.
Mert nem sokáig kell szemmel tartania az embert, hogy az Isten elé kerüljön ítéletre!
24 Òun ó sì fọ́ àwọn alágbára túútúú láìní ìwádìí, a sì fi ẹlòmíràn dípò wọn,
Megrontja a hatalmasokat vizsgálat nélkül, és másokat állít helyökbe.
25 nítorí pé ó mọ iṣẹ́ wọn, ó sì yí wọn po ní òru, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
Ekképen felismeri cselekedeteiket, és éjjel is ellenök fordul és szétmorzsoltatnak.
26 Ó kọlù wọ́n nítorí ìwà búburú wọn níbi tí àwọn ẹlòmíràn ti lè rí i,
Gonosztevők gyanánt tapodja meg őket olyan helyen, a hol látják.
27 nítorí pé wọ́n padà pẹ̀yìndà sí i, wọn kò sì fiyèsí ipa ọ̀nà rẹ̀ gbogbo,
A kik azért távoztak el, és azért nem gondoltak egyetlen útjával sem,
28 kí wọn kí ó sì mú igbe ẹkún àwọn tálákà lọ dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, òun sì gbọ́ igbe ẹkún aláìní.
Hogy a szegény kiáltását hozzájok juttatja, és ő a nyomorultak kiáltását meghallja.
29 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá dákẹ́ síbẹ̀, ta ni yóò dá lẹ́bi? Nígbà tí ó bá pa ojú rẹ̀ mọ́, ta ni yóò lè rí i? Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe si orílẹ̀-èdè tàbí sí ènìyàn kan ṣoṣo;
Ha ő nyugalmat ád, ki kárhoztatja őt? Ha elrejti arczát, ki láthatja meg azt? Akár nép elől, akár ember elől egyaránt;
30 kí aláìwà bi Ọlọ́run kí ó má bá à jẹ ọba kí wọn kí ó má di ìdẹwò fún ènìyàn.
Hogy képmutató ember ne uralkodjék, és ne legyen tőre a népnek.
31 “Nítorí pé ẹnìkan ha lè wí fún Ọlọ́run pé, èmi jẹ̀bi, èmi kò sì ní ṣẹ̀ mọ́?
Bizony az Istenhez így való szólani: Elszenvedem, nem leszek rossz többé;
32 Èyí tí èmi kò rí ìwọ fi kọ́ mi bi mo bá sì dẹ́ṣẹ̀ èmi kì yóò ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.
A mit át nem látok, arra te taníts meg engemet; ha gonoszságot cselekedtem, többet nem teszem!
33 Ǹjẹ́ bí ti inú rẹ̀ ni ki òun ó san ẹ̀ṣẹ̀ padà? Ǹjẹ́ òun yóò san án padà bí ìwọ bá kọ̀ ọ́ láti jẹ́wọ́, ìwọ gbọdọ̀ yan, kì í ṣe èmi. Nítorí náà sọ ohun tí o mọ̀, pẹ̀lúpẹ̀lú ohun tí ìwọ mọ̀, sọ ọ́!
Avagy te szerinted fizessen-é csak azért, mert ezt megveted, és hogy te szabd meg és nem én? Nos, mit tudsz? Mondd!
34 “Àwọn ènìyàn amòye yóò wí fún mi, àti pẹ̀lúpẹ̀lú ẹnikẹ́ni tí í ṣe ọlọ́gbọ́n tí ó sì gbọ́ mi pé,
Az okos emberek azt mondják majd nékem, és a bölcs férfiú, a ki reám hallgat:
35 ‘Jobu ti fi àìmọ̀ sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ṣe aláìgbọ́n.’
Jób tudatlanul szól, és szavai megfontolás nélkül valók.
36 Ìfẹ́ mi ni kí a dán Jobu wò dé òpin, nítorí ìdáhùn rẹ̀ dàbí i ti ènìyàn búburú.
Óh, bárcsak megpróbáltatnék Jób mind végiglen, a miért úgy felel, mint az álnok emberek!
37 Nítorí pe ó fi ìṣọ̀tẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; ó pàtẹ́wọ́ ní àárín wa, ó sì sọ ọ̀rọ̀ odi púpọ̀ sí Ọlọ́run.”
Mert vétkét gonoszsággal tetézi, csapkod közöttünk, és Isten ellen szószátyárkodik.

< Job 34 >