< Job 34 >

1 Nígbà náà ni Elihu dáhùn, ó sì wí pé,
Ningĩ Elihu akiuga atĩrĩ:
2 “Ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí ẹ sì fi etí sílẹ̀ sí mi ẹ̀yin tí ẹ ní ìmòye.
“Iguai ciugo ciakwa, inyuĩ andũ aya oogĩ; thikĩrĩriai, inyuĩ amenyi a maũndũ.
3 Nítorí pé etí a máa dán ọ̀rọ̀ wò, bí adùn ẹnu ti ń tọ́ oúnjẹ wò.
Nĩgũkorwo gũtũ gũthuuranagia ciugo o ta ũrĩa rũrĩmĩ rũcamaga irio.
4 Ẹ jẹ́ kí a mọ òye ohun tí o tọ́ fún ara wa; ẹ jẹ́ kí a mọ ohun tí ó dára láàrín wa.
Nĩtwĩkũũranĩrei ithuĩ ene ũndũ ũrĩa wagĩrĩire; nĩtwĩrute tũrĩ hamwe ũndũ ũrĩa mwega.
5 “Nítorí pé Jobu wí pé, ‘Aláìlẹ́ṣẹ̀ ni èmi; Ọlọ́run sì ti gba ìdájọ́ mi lọ.
“Ayubu aroiga atĩrĩ, ‘Niĩ ndihĩtĩtie, no Mũrungu nĩanjagithĩtie kĩhooto gĩakwa.
6 Èmi ha purọ́ sí ẹ̀tọ́ mi bí, bí mo tilẹ̀ jẹ́ aláìjẹ̀bi, ọfà rẹ̀ kò ní àwòtán ọgbẹ́.’
O na gũtuĩka ndĩraria ũrĩa kũrĩ, ndĩratuuo mũheenania; o na gũtuĩka ndirĩ na mahĩtia, mũguĩ wake ũngurarĩtie kĩronda gĩtangĩhona.’
7 Ọkùnrin wo ni ó dàbí Jobu, tí ń mu ẹ̀gàn bí ẹní mú omi?
Nĩ mũndũ ũrĩkũ ũhaana ta Ayubu, mũndũ ũnyuuaga kĩnyũrũri taarĩ maaĩ aranyua?
8 Tí ń bá àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kẹ́gbẹ́ tí ó sì ń bá àwọn ènìyàn búburú rìn.
Atwaranaga na andũ arĩa mekaga ũũru; agĩĩaga thiritũ na andũ arĩa aaganu.
9 Nítorí ó sá ti wí pé, ‘Èrè kan kò sí fún ènìyàn, tí yóò fi máa ṣe inú dídùn sí Ọlọ́run.’
Nĩgũkorwo oigaga atĩrĩ, ‘Gũtirĩ uumithio mũndũ onaga rĩrĩa arageria gũkenia Ngai.’
10 “Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ fetísílẹ̀ sí mi, ẹ fi etí sí mi ẹ̀yin ènìyàn amòye: Ó di èèwọ̀ fún Ọlọ́run ti ìbá fi hùwà búburú, àti fún Olódùmarè, tí yóò fi ṣe àìṣedéédéé!
“Nĩ ũndũ ũcio gĩĩthikĩrĩriei, inyuĩ andũ aya mũrĩ na ũtaũku. Ũhoro wa kwĩhia ũroaga kuoneka harĩ Mũrungu, Mwene-Hinya-Wothe aroaga gwĩka ũũru.
11 Nítorí pé ó ń sán fún ènìyàn fún gẹ́gẹ́ bi ohun tí a bá ṣe, yóò sì mú olúkúlùkù kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ipa ọ̀nà rẹ̀.
Arĩhaga mũndũ kũringana na ũrĩa ekĩte; akamũrehere o kĩrĩa kĩringaine na mĩthiĩre yake.
12 Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò hùwàkiwà; bẹ́ẹ̀ ni Olódùmarè kì yóò yí ìdájọ́ po.
Gũtingĩhoteka atĩ Mũrungu no eeke mahĩtia, atĩ ũrĩa Mwene-Hinya-Wothe no ogomie kĩhooto.
13 Ta ni ó fi ìtọ́jú ayé lé e lọ́wọ́, tàbí ta ni ó fi gbogbo ayé lé e lọ́wọ́?
Nũũ wamũtuire mũrori wa thĩ? Nũũ wamũtuire mũrũgamĩrĩri wa thĩ yothe?
14 Bí ó bá gbé ayé rẹ̀ lé kìkì ara rẹ̀ tí ó sì gba ọkàn rẹ̀ àti ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,
Korwo aagĩa na muoroto wa kweheria roho wake na mĩhũmũ-rĩ,
15 gbogbo ènìyàn ni yóò parun pọ̀, ènìyàn a sì tún padà di erùpẹ̀.
andũ othe mangĩthiranĩra hamwe, nake mũndũ acooke rũkũngũ-inĩ.
16 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, bí ìwọ bá ní òye, gbọ́ èyí; fetísí ohùn ẹnu mi.
“Akorwo ũrĩ mũndũ ũrĩ na ũtaũku-rĩ, igua ũhoro ũyũ; thikĩrĩria ũrĩa nguuga.
17 Ẹni tí ó kórìíra òtítọ́ ha le ṣe olórí bí? Ìwọ ó ha sì dá olóòótọ́ àti ẹni ńlá lẹ́bi?
Mũndũ ũthũire kĩhooto-rĩ, no ahote gwathana? Ũrĩa ũrĩ kĩhooto, o Ũcio kĩhoti-rĩ, no ũmũtue mwĩhia?
18 O ha tọ́ láti wí fún ọba pé, ‘Ènìyàn búburú ní ìwọ,’ tàbí fún àwọn ọmọ-aládé pé, ‘Ìkà ni ẹ̀yin,’
Githĩ ti we wĩraga athamaki atĩrĩ, ‘Inyuĩ mũtirĩ kĩene,’ na akeera arĩa marĩ igweta atĩrĩ, ‘Inyuĩ mũrĩ aaganu,’
19 mélòó mélòó fún ẹni tí kì í ṣe ojúsàájú àwọn ọmọ-aládé tàbí tí kò kà ọlọ́rọ̀ sí ju tálákà lọ, nítorí pé iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn í ṣe?
o ũcio ũtatĩagĩra anene maũthĩ, na ndendaga arĩa atongu gũkĩra arĩa athĩĩni, nĩgũkorwo othe nĩ wĩra wa moko make?
20 Ní ìṣẹ́jú kan ni wọn ó kú, àwọn ènìyàn á sì di yíyọ́ lẹ́nu láàrín ọ̀gànjọ́, wọn a sì kọjá lọ; a sì mú àwọn alágbára kúrò láìsí ọwọ́ ènìyàn níbẹ̀.
Makuuaga o rĩmwe, o ũtukũ gatagatĩ; andũ mainainaga magakua; arĩa marĩ hinya meeheragio matahutĩtio nĩ guoko kwa mũndũ.
21 “Nítorí pé ojú rẹ̀ ń bẹ ní ipa ọ̀nà ènìyàn, òun sì rí ìrìn rẹ̀ gbogbo.
“Maitho make maikaraga macũthĩrĩirie mĩthiĩre ya andũ; nĩonaga mĩthiĩre yao yothe.
22 Kò sí ibi òkùnkùn, tàbí òjìji ikú, níbi tí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ yóò gbé sá pamọ́ sí.
Gũtirĩ handũ harĩ nduma, kana handũ harĩ kĩĩruru kĩnene, hangĩĩhithwo nĩ arĩa meekaga ũũru.
23 Nítorí pé òun kò pẹ́ àti kíyèsi ẹnìkan, kí òun kí ó sì mú lọ sínú ìdájọ́ níwájú Ọlọ́run.
Mũrungu ndabatairio nĩgũthuthuuria ndeto cia andũ makĩria, atĩ nĩguo moke mbere yake maciirithio.
24 Òun ó sì fọ́ àwọn alágbára túútúú láìní ìwádìí, a sì fi ẹlòmíràn dípò wọn,
Ahehenjaga arĩa marĩ ũhoti atekũũria mũndũ na akarũgamia andũ angĩ ithenya rĩao.
25 nítorí pé ó mọ iṣẹ́ wọn, ó sì yí wọn po ní òru, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
Tondũ we nĩamenyaga maũndũ marĩa meekaga, amangʼaũranagia ũtukũ magathuthĩka.
26 Ó kọlù wọ́n nítorí ìwà búburú wọn níbi tí àwọn ẹlòmíràn ti lè rí i,
Amaherithagĩria waganu wao makĩonagwo nĩ mũndũ o wothe,
27 nítorí pé wọ́n padà pẹ̀yìndà sí i, wọn kò sì fiyèsí ipa ọ̀nà rẹ̀ gbogbo,
tondũ nĩmagarũrũkire magĩtiga kũmũrũmĩrĩra, na matirũmbũyagia njĩra yake o na ĩrĩkũ.
28 kí wọn kí ó sì mú igbe ẹkún àwọn tálákà lọ dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, òun sì gbọ́ igbe ẹkún aláìní.
Nĩmatũmire kĩrĩro kĩa arĩa athĩĩni gĩkinye hau mbere yake, nĩ ũndũ ũcio akĩigua kĩrĩro kĩa arĩa abatari.
29 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá dákẹ́ síbẹ̀, ta ni yóò dá lẹ́bi? Nígbà tí ó bá pa ojú rẹ̀ mọ́, ta ni yóò lè rí i? Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe si orílẹ̀-èdè tàbí sí ènìyàn kan ṣoṣo;
No rĩrĩ, angĩikara akirĩte-rĩ, nũũ ũngĩmũtua muhĩtia? Angĩhitha ũthiũ wake-rĩ, nũũ ũngĩmuona? Nowe arĩ igũrũ rĩa mũndũ na igũrũ rĩa rũrĩrĩ o ũndũ ũmwe,
30 kí aláìwà bi Ọlọ́run kí ó má bá à jẹ ọba kí wọn kí ó má di ìdẹwò fún ènìyàn.
nĩguo agirie mũndũ ũtarĩ na ũngai gwathana, amũgirie kũigĩra kĩrĩndĩ mĩtego.
31 “Nítorí pé ẹnìkan ha lè wí fún Ọlọ́run pé, èmi jẹ̀bi, èmi kò sì ní ṣẹ̀ mọ́?
“Korwo mũndũ no ere Mũrungu atĩrĩ, ‘Nĩnjĩhĩtie no ndikehia rĩngĩ.
32 Èyí tí èmi kò rí ìwọ fi kọ́ mi bi mo bá sì dẹ́ṣẹ̀ èmi kì yóò ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.
Nduta menye ũrĩa itarahota kuona; ingĩkorwo nĩnjĩkĩte ũũru-rĩ, ndigacooka gwĩka ũguo rĩngĩ.’
33 Ǹjẹ́ bí ti inú rẹ̀ ni ki òun ó san ẹ̀ṣẹ̀ padà? Ǹjẹ́ òun yóò san án padà bí ìwọ bá kọ̀ ọ́ láti jẹ́wọ́, ìwọ gbọdọ̀ yan, kì í ṣe èmi. Nítorí náà sọ ohun tí o mọ̀, pẹ̀lúpẹ̀lú ohun tí ìwọ mọ̀, sọ ọ́!
Ngai-rĩ, no agĩkũrĩhe kũringana na ũrĩa wee ũkwenda rĩrĩa ũregete kwĩrira? No nginya we ũtue itua, no ti niĩ; nĩ ũndũ ũcio kĩnjĩĩre ũrĩa ũũĩ.
34 “Àwọn ènìyàn amòye yóò wí fún mi, àti pẹ̀lúpẹ̀lú ẹnikẹ́ni tí í ṣe ọlọ́gbọ́n tí ó sì gbọ́ mi pé,
“Andũ arĩa marĩ na ũtaũku maroiga atĩrĩ, nao andũ acio oogĩ maiguĩte ngĩaria manjĩĩrĩte atĩrĩ,
35 ‘Jobu ti fi àìmọ̀ sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ṣe aláìgbọ́n.’
‘Ayubu aaragia atarĩ na ũmenyo; ciugo ciake nĩciagĩte ũũgĩ.’
36 Ìfẹ́ mi ni kí a dán Jobu wò dé òpin, nítorí ìdáhùn rẹ̀ dàbí i ti ènìyàn búburú.
Hĩ, naarĩ korwo Ayubu aagerio nginya mũthia, nĩ ũndũ macookio make nĩ ta ma mũndũ mwaganu!
37 Nítorí pe ó fi ìṣọ̀tẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; ó pàtẹ́wọ́ ní àárín wa, ó sì sọ ọ̀rọ̀ odi púpọ̀ sí Ọlọ́run.”
Nĩongereire ũremi harĩ mehia make; atũhũũragĩra hĩ cia kĩnyũrũri, na akaingĩhia ciugo ciake cia gũũkĩrĩra Mũrungu.”

< Job 34 >