< Job 34 >

1 Nígbà náà ni Elihu dáhùn, ó sì wí pé,
Then Elihu continued:
2 “Ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí ẹ sì fi etí sílẹ̀ sí mi ẹ̀yin tí ẹ ní ìmòye.
“You [three] men who [think that you] [SAR] are very wise, hear me; listen to what I am saying, you men who [say that you] know so much.
3 Nítorí pé etí a máa dán ọ̀rọ̀ wò, bí adùn ẹnu ti ń tọ́ oúnjẹ wò.
When we [SYN] hear what other people [like you] say, we [RHQ] think carefully about what they say [to determine what is good and what is bad], like we [SYN] taste food [to determine what is good].
4 Ẹ jẹ́ kí a mọ òye ohun tí o tọ́ fún ara wa; ẹ jẹ́ kí a mọ ohun tí ó dára láàrín wa.
We need to decide [who is saying] what is right and to determine among ourselves what is good/best.
5 “Nítorí pé Jobu wí pé, ‘Aláìlẹ́ṣẹ̀ ni èmi; Ọlọ́run sì ti gba ìdájọ́ mi lọ.
Job has said, ‘I am innocent, but God has refused to judge me fairly/justly.
6 Èmi ha purọ́ sí ẹ̀tọ́ mi bí, bí mo tilẹ̀ jẹ́ aláìjẹ̀bi, ọfà rẹ̀ kò ní àwòtán ọgbẹ́.’
Even though I have always done what is right, he is lying about me. Even though I have not done what is wrong, he has caused me to suffer, and I will certainly die.’
7 Ọkùnrin wo ni ó dàbí Jobu, tí ń mu ẹ̀gàn bí ẹní mú omi?
(Is there any person like Job, who insults others as easily as people accept a drink of water?/There is no person like Job, who insults others as easily as people accept a drink of water.) [RHQ]
8 Tí ń bá àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kẹ́gbẹ́ tí ó sì ń bá àwọn ènìyàn búburú rìn.
He habitually associates with people who do what is evil and spends time with wicked people.
9 Nítorí ó sá ti wí pé, ‘Èrè kan kò sí fún ènìyàn, tí yóò fi máa ṣe inú dídùn sí Ọlọ́run.’
He has said, ‘It is useless for people to try to please God.’
10 “Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ fetísílẹ̀ sí mi, ẹ fi etí sí mi ẹ̀yin ènìyàn amòye: Ó di èèwọ̀ fún Ọlọ́run ti ìbá fi hùwà búburú, àti fún Olódùmarè, tí yóò fi ṣe àìṣedéédéé!
“So, you men who [claim that you] understand everything, listen to me! Almighty God would never consider doing anything that is wicked or wrong [DOU]!
11 Nítorí pé ó ń sán fún ènìyàn fún gẹ́gẹ́ bi ohun tí a bá ṣe, yóò sì mú olúkúlùkù kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ipa ọ̀nà rẹ̀.
He (pays back/punishes) people for what they have done; he gives them what they deserve for the way that they have conducted their lives.
12 Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò hùwàkiwà; bẹ́ẹ̀ ni Olódùmarè kì yóò yí ìdájọ́ po.
Truly, Almighty God never does what is wicked; he always [LIT] does what is fair/just.
13 Ta ni ó fi ìtọ́jú ayé lé e lọ́wọ́, tàbí ta ni ó fi gbogbo ayé lé e lọ́wọ́?
The authority that he has to rule everything on the earth, no one [RHQ] gave it to him; no one [RHQ] put him in control of the whole world. [He has always had that authority].
14 Bí ó bá gbé ayé rẹ̀ lé kìkì ara rẹ̀ tí ó sì gba ọkàn rẹ̀ àti ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,
If he would take his spirit back to himself,
15 gbogbo ènìyàn ni yóò parun pọ̀, ènìyàn a sì tún padà di erùpẹ̀.
everyone would die [immediately], and their corpses would soon become dirt again.
16 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, bí ìwọ bá ní òye, gbọ́ èyí; fetísí ohùn ẹnu mi.
“So, [Job], if [you say that you] understand everything, listen to what I am saying.
17 Ẹni tí ó kórìíra òtítọ́ ha le ṣe olórí bí? Ìwọ ó ha sì dá olóòótọ́ àti ẹni ńlá lẹ́bi?
God could certainly not [RHQ] govern the world if he hated doing what is fair/just. So, will you condemn God, who is righteous and powerful, [saying that what he has done is wrong]?
18 O ha tọ́ láti wí fún ọba pé, ‘Ènìyàn búburú ní ìwọ,’ tàbí fún àwọn ọmọ-aládé pé, ‘Ìkà ni ẹ̀yin,’
He tells [some] kings that they are worthless, and he says to [some] officials that they are wicked.
19 mélòó mélòó fún ẹni tí kì í ṣe ojúsàájú àwọn ọmọ-aládé tàbí tí kò kà ọlọ́rọ̀ sí ju tálákà lọ, nítorí pé iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn í ṣe?
He does not favor rulers [more than he favors others]; he does not favor rich people more than poor people, because he created all of them.
20 Ní ìṣẹ́jú kan ni wọn ó kú, àwọn ènìyàn á sì di yíyọ́ lẹ́nu láàrín ọ̀gànjọ́, wọn a sì kọjá lọ; a sì mú àwọn alágbára kúrò láìsí ọwọ́ ènìyàn níbẹ̀.
People [often] die suddenly; he strikes them at midnight and they die; he even gets rid of mighty people without the help of any humans [SYN].
21 “Nítorí pé ojú rẹ̀ ń bẹ ní ipa ọ̀nà ènìyàn, òun sì rí ìrìn rẹ̀ gbogbo.
“He sees [MTY] everything that people do; [when we walk, ] he watches every step that we take.
22 Kò sí ibi òkùnkùn, tàbí òjìji ikú, níbi tí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ yóò gbé sá pamọ́ sí.
There is no gloom or darkness [DOU] that is so dark that sinners can hide [from him] in that darkness.
23 Nítorí pé òun kò pẹ́ àti kíyèsi ẹnìkan, kí òun kí ó sì mú lọ sínú ìdájọ́ níwájú Ọlọ́run.
God does not [need to] set a time when we will stand in front of him in order that he may judge us. [He can judge us whenever he wants to].
24 Òun ó sì fọ́ àwọn alágbára túútúú láìní ìwádìí, a sì fi ẹlòmíràn dípò wọn,
He destroys mighty people without [needing to] investigate [what they have done], and he appoints others to take their places.
25 nítorí pé ó mọ iṣẹ́ wọn, ó sì yí wọn po ní òru, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
Because he [already] knows what they have done, he removes them at night and gets rid of them.
26 Ó kọlù wọ́n nítorí ìwà búburú wọn níbi tí àwọn ẹlòmíràn ti lè rí i,
Where [many] people can see it, he strikes/punishes them because of the wicked things that they have done;
27 nítorí pé wọ́n padà pẹ̀yìndà sí i, wọn kò sì fiyèsí ipa ọ̀nà rẹ̀ gbogbo,
he strikes them because they turned away from doing what he wanted them to do and did not pay attention to any of his commands.
28 kí wọn kí ó sì mú igbe ẹkún àwọn tálákà lọ dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, òun sì gbọ́ igbe ẹkún aláìní.
They [mistreated] the poor people, with the result that those poor people cried out to God [for help], and he heard those afflicted people when they cried out [to him].
29 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá dákẹ́ síbẹ̀, ta ni yóò dá lẹ́bi? Nígbà tí ó bá pa ojú rẹ̀ mọ́, ta ni yóò lè rí i? Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe si orílẹ̀-èdè tàbí sí ènìyàn kan ṣoṣo;
But if God decides to do nothing [to punish wicked people], no one can criticize/condemn him. If a godless/wicked man rules a nation, a man who tricks/deceives the people,
30 kí aláìwà bi Ọlọ́run kí ó má bá à jẹ ọba kí wọn kí ó má di ìdẹwò fún ènìyàn.
and if [God] hides his face [with the result that he does not see that ruler or punish him], no one will be able to prevent that ruler [from doing those things].
31 “Nítorí pé ẹnìkan ha lè wí fún Ọlọ́run pé, èmi jẹ̀bi, èmi kò sì ní ṣẹ̀ mọ́?
“Job, have you or anyone else ever said to God, ‘I have been punished [for my sins], and I will not sin any more;
32 Èyí tí èmi kò rí ìwọ fi kọ́ mi bi mo bá sì dẹ́ṣẹ̀ èmi kì yóò ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.
so teach/show me what [sins I have committed]; if I have done anything that is evil, I will not do it any more’?
33 Ǹjẹ́ bí ti inú rẹ̀ ni ki òun ó san ẹ̀ṣẹ̀ padà? Ǹjẹ́ òun yóò san án padà bí ìwọ bá kọ̀ ọ́ láti jẹ́wọ́, ìwọ gbọdọ̀ yan, kì í ṣe èmi. Nítorí náà sọ ohun tí o mọ̀, pẹ̀lúpẹ̀lú ohun tí ìwọ mọ̀, sọ ọ́!
[Job, ] you object to what God has done to you, but do you think that he will do what you want him to do? It is you who must choose [what you say to God], not I; so tell me what you are thinking about this.
34 “Àwọn ènìyàn amòye yóò wí fún mi, àti pẹ̀lúpẹ̀lú ẹnikẹ́ni tí í ṣe ọlọ́gbọ́n tí ó sì gbọ́ mi pé,
“People who have good sense, those who are wise and who listen to what I say, will say to me,
35 ‘Jobu ti fi àìmọ̀ sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ṣe aláìgbọ́n.’
‘Job is speaking ignorantly; what he says is nonsense.’
36 Ìfẹ́ mi ni kí a dán Jobu wò dé òpin, nítorí ìdáhùn rẹ̀ dàbí i ti ènìyàn búburú.
I think that Job should be taken to a court and (put on trial/judged), because he answers [us his friends] like wicked men would answer.
37 Nítorí pe ó fi ìṣọ̀tẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; ó pàtẹ́wọ́ ní àárín wa, ó sì sọ ọ̀rọ̀ odi púpọ̀ sí Ọlọ́run.”
To add to the [other] sins that he has committed, he is rebelling [against God]; he shows us that he does not respect God [IDM], making long speeches [saying that God has punished him unjustly].”

< Job 34 >