< Job 33 >

1 “Ǹjẹ́ nítorí náà, Jobu, èmí bẹ̀ ọ, gbọ́ ọ̀rọ̀ mi kí o sì fetísí ọ̀rọ̀ mi!
“Na afei, Hiob, tie me nsɛm; yɛ aso ma biribiara a mɛka.
2 Kíyèsi i nísinsin yìí, èmí ya ẹnu mi, ahọ́n mi sì sọ̀rọ̀ ní ẹnu mi.
Merebebue mʼano; me nsɛm aba me tɛkrɛma so.
3 Ọ̀rọ̀ mi yóò sì jásí ìdúró ṣinṣin ọkàn mi, ètè mi yóò sì sọ ìmọ̀ mi jáde dájúdájú.
Me nsɛm fi koma a ɛteɛ mu; na mʼano de ahonim pa ka nea minim.
4 Ẹ̀mí Ọlọ́run ni ó tí dá mi, àti ìmísí Olódùmarè ni ó ti fún mi ní ìyè.
Onyankopɔn Honhom na abɔ me; Otumfo no home ma me nkwa.
5 Bí ìwọ bá le dá mi lóhùn, tò ọ̀rọ̀ rẹ̀ lẹ́sẹẹsẹ níwájú mi;
Sɛ wubetumi a, ma me mmuae; siesie wo ho, na ka si mʼanim.
6 kíyèsi i, bí ìwọ ṣe jẹ́ ti Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni èmi náà; láti amọ̀ wá ni a sì ti dá mi pẹ̀lú.
Wo ne me nyinaa yɛ pɛ wɔ Onyankopɔn anim; me nso wɔbɔɔ me fii dɔte mu.
7 Kíyèsi i, ẹ̀rù ńlá mi kì yóò bà ọ; bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi kì yóò wúwo sí ọ lára.
Ɛnsɛ sɛ wusuro me, na ɛnsɛ sɛ me nsa yɛ den wɔ wo so.
8 “Nítòótọ́ ìwọ sọ ní etí mi, èmí sì gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ wí pé,
“Nanso woaka ama mate, mete saa nsɛm no, na wokae se,
9 ‘Èmi mọ́, láìní ìrékọjá, aláìṣẹ̀ ní èmi; bẹ́ẹ̀ àìṣedéédéé kò sí ní ọwọ́ mi.
‘Meyɛ kronkron na minni bɔne; me ho tew na afɔdi biara nni me ho.
10 Kíyèsi i, Ọlọ́run ti rí àìṣedéédéé pẹ̀lú mi; ó kà mí sì ọ̀tá rẹ̀.
Nanso Onyankopɔn anya me ho mfomso wafa me sɛ ne tamfo.
11 Ó kan ẹ̀ṣẹ̀ mi sínú àbà; o kíyèsi ipa ọ̀nà mi gbogbo.’
Ɔde me nan hyɛ mpokyerɛ mu; na nʼani wɔ mʼakwan nyinaa so.’
12 “Kíyèsi i, nínú èyí ìwọ ṣìnà! Èmi ó dá ọ lóhùn pé, Ọlọ́run tóbi jù ènìyàn lọ!
“Nanso meka mekyerɛ wo se, eyi mu de woayɛ mfomso, efisɛ Onyankopɔn so sen ɔdesani.
13 Nítorí kí ni ìwọ ṣe ń bá a jà, wí pé, òun kò ní sọ ọ̀rọ̀ kan nítorí iṣẹ́ rẹ̀?
Na adɛn nti na wunwiinwii hyɛ no sɛ ommua onipa nsɛm biara ana?
14 Nítorí pe Ọlọ́run sọ̀rọ̀ lẹ́ẹ̀kan, àní, lẹ́ẹ̀kejì, ṣùgbọ́n ènìyàn kò róye rẹ̀.
Nanso Onyankopɔn kasa wɔ akwan ahorow so, na ebia nnipa nte.
15 Nínú àlá, ní ojúran òru, nígbà tí orun èjìká bá kùn ènìyàn lọ, ní sísùn lórí ibùsùn,
Ɔkasa wɔ daeso ne anadwo anisoadehu mu, bere a nna afa nnipa na wɔada hatee wɔ wɔn mpa so no,
16 nígbà náà ni ó lè sọ̀rọ̀ ní etí wọn, yóò sì dẹ́rùbà wọ́n pẹ̀lú ìbáwí,
otumi kasa gu wɔn asom na ɔde kɔkɔbɔ yi wɔn hu,
17 kí ó lè fa ènìyàn sẹ́yìn kúrò nínú ètè rẹ̀; kí ó sì pa ìgbéraga mọ́ kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn;
sɛ ɔbɛdan onipa afi nneyɛe bɔne ho na watwe no afi ahantan ho,
18 Ó sì fa ọkàn rẹ̀ padà kúrò nínú isà òkú, àti ẹ̀mí rẹ̀ láti ṣègbé lọ́wọ́ idà.
sɛ ɔmma ne kra nkɔ amoa mu na ɔnhwere ne nkwa wɔ afoa ano.
19 “A sì nà án lórí ibùsùn ìrora rẹ̀; pẹ̀lúpẹ̀lú a fi ìjà egungun rẹ̀ ti ó dúró pẹ́ nà án,
Anaasɛ wotumi de mpa so yaw twe onipa aso nnompe mu yaw a ennyae da,
20 bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀mí rẹ kọ oúnjẹ, ọkàn rẹ̀ sì kọ oúnjẹ dídùn.
kosi sɛ ne kɔn nnɔ aduan na ne kra nso po aduan a ɛyɛ akɔnnɔ pa ara;
21 Ẹran-ara rẹ̀ run, títí a kò sì fi lè rí i mọ́ egungun rẹ̀ tí a kò tí rí sì ta jáde.
ɔfɔn yɛ basaa, na ne nnompe a anka ɛho akata no, ho da hɔ.
22 Àní, ọkàn rẹ̀ sì súnmọ́ isà òkú, ẹ̀mí rẹ̀ sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ ikú.
Ne kra bɛn ɔda, na ne nkwa bɛn owu abɔfo.
23 Bí angẹli kan ba wà lọ́dọ̀ rẹ̀, ẹni tí ń ṣe alágbàwí, ọ̀kan nínú ẹgbẹ̀rún láti fi ọ̀nà pípé hàn ni,
“Nanso sɛ ɔbɔfo bi wɔ nʼafa sɛ odimafo a, ɛyɛ apem mu baako, na ɔbɛkyerɛ no nea eye ma no,
24 nígbà náà ni ó ṣe oore-ọ̀fẹ́ fún un ó sì wí pé, gbà á kúrò nínú lílọ sínú isà òkú; èmi ti rà á padà.
obehu no mmɔbɔ na waka se, ‘Munnyaa no na wankɔ ɔda mu; na manya mpatade ama no,’
25 Ara rẹ̀ yóò sì di ọ̀tun bí i ti ọmọ kékeré, yóò sì tún padà sí ọjọ́ ìgbà èwe rẹ̀;
afei ne were yɛ foforo sɛ abofra; na esi ne dedaw mu yɛ sɛ mmerantebere mu de.
26 Ó gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run, òun sì ṣe ojúrere rẹ̀, o sì rí ojú rẹ̀ pẹ̀lú ayọ̀, òhun o san òdodo rẹ̀ padà fún ènìyàn.
Ɔbɔ Onyankopɔn mpae na onya adom fi ne hɔ, ohu Onyankopɔn anim na ɔde ahosɛpɛw teɛ mu; na Onyankopɔn gye no bio sɛ ɔtreneeni.
27 Ó wá sọ́dọ̀ ènìyàn ó sì wí pé, ‘Èmi ṣẹ̀, kò sì ṣí èyí tí o tọ́, mo sì ti yí èyí tí ó tọ́ po, a kò sì san ẹ̀san rẹ̀ fún mi;
Afei ɔba nnipa mu bɛka se, ‘Meyɛɛ bɔne na mekyeaa nea ɛteɛ, nanso mannya nea ɛfata me.
28 Ọlọ́run ti gba ọkàn mi kúrò nínú lílọ sínú ihò, ẹ̀mí mi yóò wà láti jẹ adùn ìmọ́lẹ̀ ayé.’
Ogyee me kra na wamma no ankɔ ɔda mu, enti mɛtena ase na madi hann no mu dɛ.’
29 “Wò ó! Nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́run máa ń ṣe fún ènìyàn nígbà méjì àti nígbà mẹ́ta,
“Onyankopɔn yɛ eyinom nyinaa ma onipa, mprenu ne ne mprɛnsa so,
30 láti mú ọkàn rẹ padà kúrò nínú isà òkú, láti fi ìmọ́lẹ̀ alààyè han sí i.
sɛnea ne kra renkɔ ɔda mu, na nkwa hann no ahyerɛn ne so.
31 “Jobu, kíyèsi i gidigidi, kí o sì fetí sí mi; pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì máa sọ ọ́.
“Yɛ aso, Hiob, na tie me; yɛ dinn na menkasa.
32 Bí ìwọ bá sì ní ohun wí, dá mi lóhùn; máa sọ, nítorí pé èmi fẹ́ dá ọ láre.
Na sɛ wowɔ biribi ka a, bua me; kasa, na mepɛ sɛ wobu wo bem.
33 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, gbọ́ tèmi; pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì kọ́ ọ ní ọgbọ́n.”
Sɛ ɛnte saa nso a, ɛno de tie me. Yɛ dinn na mɛkyerɛ wo nyansa.”

< Job 33 >