< Job 33 >
1 “Ǹjẹ́ nítorí náà, Jobu, èmí bẹ̀ ọ, gbọ́ ọ̀rọ̀ mi kí o sì fetísí ọ̀rọ̀ mi!
NOLAILA ke noi aku nei au ia oe, e Ioba, e hoolohe mai i ka'u mau olelo, A e haliu mai i ka'u mau huaolelo a pau.
2 Kíyèsi i nísinsin yìí, èmí ya ẹnu mi, ahọ́n mi sì sọ̀rọ̀ ní ẹnu mi.
Aia hoi, ano, ke wehe nei au i kuu waha, Ke olelo aku nei kuu elelo ma kuu waha.
3 Ọ̀rọ̀ mi yóò sì jásí ìdúró ṣinṣin ọkàn mi, ètè mi yóò sì sọ ìmọ̀ mi jáde dájúdájú.
Ma ka pono o kuu naau ka'u olelo; A e olelo akaka kuu lehelehe i ka naauao.
4 Ẹ̀mí Ọlọ́run ni ó tí dá mi, àti ìmísí Olódùmarè ni ó ti fún mi ní ìyè.
Na ka Uhane o ke Akua owau i hana, Na ka hanu hoi o ka Mea mana owau i hoola.
5 Bí ìwọ bá le dá mi lóhùn, tò ọ̀rọ̀ rẹ̀ lẹ́sẹẹsẹ níwájú mi;
Ina e hiki ia oe ke ekemu mai ia'u, E hooponopono oe imua o'u, e kupaa.
6 kíyèsi i, bí ìwọ ṣe jẹ́ ti Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni èmi náà; láti amọ̀ wá ni a sì ti dá mi pẹ̀lú.
Aia hoi, no ke Akua no wau e like me oe; Ua hanaia hoi au mai ka lepo mai.
7 Kíyèsi i, ẹ̀rù ńlá mi kì yóò bà ọ; bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi kì yóò wúwo sí ọ lára.
Aia hoi, aole ko'u makau e hooweliweli ia oe, Aole e hookaumahaia ko'u lima maluna ou.
8 “Nítòótọ́ ìwọ sọ ní etí mi, èmí sì gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ wí pé,
He oiaio, ua olelo mai oe maloko o kuu pepeiao, A ua lohe au i ka leo o kau mau olelo;
9 ‘Èmi mọ́, láìní ìrékọjá, aláìṣẹ̀ ní èmi; bẹ́ẹ̀ àìṣedéédéé kò sí ní ọwọ́ mi.
Ua maemae wau, me ka hala ole, Ua maemae wau, aohe hewa iloko o'u.
10 Kíyèsi i, Ọlọ́run ti rí àìṣedéédéé pẹ̀lú mi; ó kà mí sì ọ̀tá rẹ̀.
Aia hoi, ua imi no ia i na mea ku e ia'u, Ua manao mai ia ia'u he enemi nona;
11 Ó kan ẹ̀ṣẹ̀ mi sínú àbà; o kíyèsi ipa ọ̀nà mi gbogbo.’
Ua hookomo no ia i kuu mau wawae ma ka laau kupee, Ua hoohalua no ia i ko'u mau aoao a pau.
12 “Kíyèsi i, nínú èyí ìwọ ṣìnà! Èmi ó dá ọ lóhùn pé, Ọlọ́run tóbi jù ènìyàn lọ!
Aia hoi, ma keia ua pono ole oe; E olelo aku au ia oe, no ka mea, ua oi ke Akua mamua o ke kanaka.
13 Nítorí kí ni ìwọ ṣe ń bá a jà, wí pé, òun kò ní sọ ọ̀rọ̀ kan nítorí iṣẹ́ rẹ̀?
No ke aha la oe i hakaka pu ai me ia? No ka mea, aole ia i hoike mai i kana mau mea a pau.
14 Nítorí pe Ọlọ́run sọ̀rọ̀ lẹ́ẹ̀kan, àní, lẹ́ẹ̀kejì, ṣùgbọ́n ènìyàn kò róye rẹ̀.
No ka mea, hookahi ka ke Akua olelo ana mai, A elua hoi, aole nae i manaoia oia.
15 Nínú àlá, ní ojúran òru, nígbà tí orun èjìká bá kùn ènìyàn lọ, ní sísùn lórí ibùsùn,
Ma ka moeuhane, ma ka hihio i ka po, I ke kau ana o ka hiamoe nui maluna o kanaka, I ka hiamoe ana maluna o kahi moe;
16 nígbà náà ni ó lè sọ̀rọ̀ ní etí wọn, yóò sì dẹ́rùbà wọ́n pẹ̀lú ìbáwí,
Alaila wehe ae la ia i na pepeiao o kanaka, A hoopaa mai ia i ke ao ana o lakou,
17 kí ó lè fa ènìyàn sẹ́yìn kúrò nínú ètè rẹ̀; kí ó sì pa ìgbéraga mọ́ kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn;
I hoololi ai ia i ka ke kanaka hana, A e hookaa i ke kiekie mai ke kanaka aku.
18 Ó sì fa ọkàn rẹ̀ padà kúrò nínú isà òkú, àti ẹ̀mí rẹ̀ láti ṣègbé lọ́wọ́ idà.
Ua hoopakele no ia i kona uhane mai ka luakupapau mai, A i kona ola hoi mai ka make ana i ka pahikaua.
19 “A sì nà án lórí ibùsùn ìrora rẹ̀; pẹ̀lúpẹ̀lú a fi ìjà egungun rẹ̀ ti ó dúró pẹ́ nà án,
Ua hoopaiia oia i ka eha maluna o kona wahi moe, A o ka haukeke o kona mau iwi, ua ikaika ia.
20 bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀mí rẹ kọ oúnjẹ, ọkàn rẹ̀ sì kọ oúnjẹ dídùn.
Ua hoopailua kona naau i ka berena, A o kona uhane i ka ai maikai.
21 Ẹran-ara rẹ̀ run, títí a kò sì fi lè rí i mọ́ egungun rẹ̀ tí a kò tí rí sì ta jáde.
Ua hoopauia kona io mai ka maka aku, A ua ahuwale mai kona mau iwi i ike ole ia.
22 Àní, ọkàn rẹ̀ sì súnmọ́ isà òkú, ẹ̀mí rẹ̀ sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ ikú.
A ua hookokokeia kona uhane i ka luakupapau, A o kona ola i na mea hoopau.
23 Bí angẹli kan ba wà lọ́dọ̀ rẹ̀, ẹni tí ń ṣe alágbàwí, ọ̀kan nínú ẹgbẹ̀rún láti fi ọ̀nà pípé hàn ni,
Ina me ia he anela, he hoikeolelo, Hookahi noloko mai o ke tausani, E hoike aku i ke kanaka i kona pono;
24 nígbà náà ni ó ṣe oore-ọ̀fẹ́ fún un ó sì wí pé, gbà á kúrò nínú lílọ sínú isà òkú; èmi ti rà á padà.
A aloha mai oia ia ia, a i iho la, E hoopakele ia ia mai ka iho ana i ka lua; Ua loaa ia'u ka uku hoola.
25 Ara rẹ̀ yóò sì di ọ̀tun bí i ti ọmọ kékeré, yóò sì tún padà sí ọjọ́ ìgbà èwe rẹ̀;
E hana hou ia kona io me ia i ka wa kamalii, E hoi hou no ia i na la o kona wa opio:
26 Ó gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run, òun sì ṣe ojúrere rẹ̀, o sì rí ojú rẹ̀ pẹ̀lú ayọ̀, òhun o san òdodo rẹ̀ padà fún ènìyàn.
E pule aku no ia i ke Akua, a e oluolu no oia ia ia: A e ike aku ia i kona maka me ka hauoli; A e hoihoi aku no ia no ke kanaka i kona pono.
27 Ó wá sọ́dọ̀ ènìyàn ó sì wí pé, ‘Èmi ṣẹ̀, kò sì ṣí èyí tí o tọ́, mo sì ti yí èyí tí ó tọ́ po, a kò sì san ẹ̀san rẹ̀ fún mi;
E nana mai no ia i na kanaka, A e olelo iho kekahi, Ua hewa au, A ua hookahuli au i ka pono, aole nae i hooukuia mai au;
28 Ọlọ́run ti gba ọkàn mi kúrò nínú lílọ sínú ihò, ẹ̀mí mi yóò wà láti jẹ adùn ìmọ́lẹ̀ ayé.’
E hoopakele no ia i kona uhane mai ka hele ana i ka lua, A e ike kona mau maka i ka malamalama.
29 “Wò ó! Nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́run máa ń ṣe fún ènìyàn nígbà méjì àti nígbà mẹ́ta,
Aia hoi, o keia mau mea a pau i hana pinepine ai ke Akua me ke kanaka,
30 láti mú ọkàn rẹ padà kúrò nínú isà òkú, láti fi ìmọ́lẹ̀ alààyè han sí i.
E hoihoi mai i kona uhane mai ka lua mai, E hoomalamalamaia i ka malamalama o ka poe e ola ana.
31 “Jobu, kíyèsi i gidigidi, kí o sì fetí sí mi; pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì máa sọ ọ́.
E haliu mai oe, e Ioba, e hoolohe mai ia'u: E noho malie, a na'u e olelo aku.
32 Bí ìwọ bá sì ní ohun wí, dá mi lóhùn; máa sọ, nítorí pé èmi fẹ́ dá ọ láre.
Ina he wahi mea, e ekemu mai oe ia'u, E olelo mai, no ka mea ke makemake nei au i kou hoaponoia.
33 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, gbọ́ tèmi; pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì kọ́ ọ ní ọgbọ́n.”
A i ole hoi, e hoolohe mai oe ia'u, E noho malie, a e ao aku au ia oe i ka noeau.