< Job 33 >

1 “Ǹjẹ́ nítorí náà, Jobu, èmí bẹ̀ ọ, gbọ́ ọ̀rọ̀ mi kí o sì fetísí ọ̀rọ̀ mi!
“No rĩu Ayubu-rĩ, thikĩrĩria ciugo ciakwa; tega matũ ũigue ũrĩa wothe nguuga.
2 Kíyèsi i nísinsin yìí, èmí ya ẹnu mi, ahọ́n mi sì sọ̀rọ̀ ní ẹnu mi.
Ndĩ hakuhĩ gũtumũra kanua gakwa; ciugo ciakwa irĩ o rũrĩmĩ-inĩ rwakwa.
3 Ọ̀rọ̀ mi yóò sì jásí ìdúró ṣinṣin ọkàn mi, ètè mi yóò sì sọ ìmọ̀ mi jáde dájúdájú.
Ciugo ciakwa ciumĩte ngoro nũngĩrĩru; mĩromo yakwa yaragia ĩtarĩ na ũhinga.
4 Ẹ̀mí Ọlọ́run ni ó tí dá mi, àti ìmísí Olódùmarè ni ó ti fún mi ní ìyè.
Roho wa Mũrungu nĩwe ũnyũmbĩte; mĩhũmũ ya Mwene-Hinya-Wothe nĩyo ĩĩheaga muoyo.
5 Bí ìwọ bá le dá mi lóhùn, tò ọ̀rọ̀ rẹ̀ lẹ́sẹẹsẹ níwájú mi;
Nawe njookeria, akorwo nĩũkũhota; wĩhaarĩrie ũũngʼethere.
6 kíyèsi i, bí ìwọ ṣe jẹ́ ti Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni èmi náà; láti amọ̀ wá ni a sì ti dá mi pẹ̀lú.
Niĩ haana o tawe maitho-inĩ ma Mũrungu; o na niĩ ndombirwo na rĩũmba.
7 Kíyèsi i, ẹ̀rù ńlá mi kì yóò bà ọ; bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi kì yóò wúwo sí ọ lára.
Kwĩĩndigĩra gũtigakũmakie, kana guoko gwakwa gũkũritũhĩre.
8 “Nítòótọ́ ìwọ sọ ní etí mi, èmí sì gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ wí pé,
“No rĩrĩ, nĩuugĩte ngĩiguaga, ngaigua ciugo icio ũkiuga atĩ,
9 ‘Èmi mọ́, láìní ìrékọjá, aláìṣẹ̀ ní èmi; bẹ́ẹ̀ àìṣedéédéé kò sí ní ọwọ́ mi.
‘Ndĩ mũtheru na ndirĩ na mehia; ndiĩkĩte ũũru, na ndirĩ na mahĩtia.
10 Kíyèsi i, Ọlọ́run ti rí àìṣedéédéé pẹ̀lú mi; ó kà mí sì ọ̀tá rẹ̀.
No Ngai nĩanyonete na mahĩtia; anduĩte thũ yake.
11 Ó kan ẹ̀ṣẹ̀ mi sínú àbà; o kíyèsi ipa ọ̀nà mi gbogbo.’
Nĩanjohaga magũrũ na mĩnyororo; arangagĩra njĩra ciakwa ciothe.’
12 “Kíyèsi i, nínú èyí ìwọ ṣìnà! Èmi ó dá ọ lóhùn pé, Ọlọ́run tóbi jù ènìyàn lọ!
“No ngũkwĩra atĩrĩ, ũhoro-inĩ ũyũ wee ndũrĩ na kĩhooto, nĩgũkorwo Ngai nĩ mũnene gũkĩra mũndũ.
13 Nítorí kí ni ìwọ ṣe ń bá a jà, wí pé, òun kò ní sọ ọ̀rọ̀ kan nítorí iṣẹ́ rẹ̀?
Ũramũtetia nĩkĩ, atĩ ndacookagia kiugo kĩa mũndũ o na kĩmwe?
14 Nítorí pe Ọlọ́run sọ̀rọ̀ lẹ́ẹ̀kan, àní, lẹ́ẹ̀kejì, ṣùgbọ́n ènìyàn kò róye rẹ̀.
Nĩgũkorwo Mũrungu nĩaaragia, rĩmwe na njĩra ĩmwe, na rĩngĩ akaaria na njĩra ĩngĩ, o na gũtuĩka mũndũ no aage gũkũũrana.
15 Nínú àlá, ní ojúran òru, nígbà tí orun èjìká bá kùn ènìyàn lọ, ní sísùn lórí ibùsùn,
Rĩmwe akaaragia kĩroto-inĩ na kĩoneki-inĩ gĩa ũtukũ, rĩrĩa andũ mahĩtĩtwo nĩ toro mũnene marĩ ũrĩrĩ,
16 nígbà náà ni ó lè sọ̀rọ̀ ní etí wọn, yóò sì dẹ́rùbà wọ́n pẹ̀lú ìbáwí,
no amaarĩrie matũ-inĩ mao, na amamakie nĩguo amakaanie,
17 kí ó lè fa ènìyàn sẹ́yìn kúrò nínú ètè rẹ̀; kí ó sì pa ìgbéraga mọ́ kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn;
nĩguo agarũre mũndũ atige kũhĩtia, na atigane na mwĩtĩĩo,
18 Ó sì fa ọkàn rẹ̀ padà kúrò nínú isà òkú, àti ẹ̀mí rẹ̀ láti ṣègbé lọ́wọ́ idà.
nĩguo agitĩre roho wake kuuma gĩkuũ-inĩ, na agitĩre muoyo wake ndũkaniinwo na rũhiũ rwa njora.
19 “A sì nà án lórí ibùsùn ìrora rẹ̀; pẹ̀lúpẹ̀lú a fi ìjà egungun rẹ̀ ti ó dúró pẹ́ nà án,
Ningĩ mũndũ no arũithio na gũkomio ũrĩrĩ wa ruo, akorwo na thĩĩna wa mahĩndĩ ũtathiraga,
20 bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀mí rẹ kọ oúnjẹ, ọkàn rẹ̀ sì kọ oúnjẹ dídùn.
o nginya ngoro yake ĩgathũũra irio, na roho wake ũgathũũra irio iria njega mũno.
21 Ẹran-ara rẹ̀ run, títí a kò sì fi lè rí i mọ́ egungun rẹ̀ tí a kò tí rí sì ta jáde.
Nyama cia mwĩrĩ wake ihĩnjaga igathirĩrĩkĩra, na mahĩndĩ make marĩa mataroonekaga makoimĩra.
22 Àní, ọkàn rẹ̀ sì súnmọ́ isà òkú, ẹ̀mí rẹ̀ sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ ikú.
Roho wake ũgakuhĩrĩria mbĩrĩra, na muoyo wake ũgakuhĩrĩria arĩa mareehage gĩkuũ.
23 Bí angẹli kan ba wà lọ́dọ̀ rẹ̀, ẹni tí ń ṣe alágbàwí, ọ̀kan nínú ẹgbẹ̀rún láti fi ọ̀nà pípé hàn ni,
“No rĩrĩ, angĩkorwo harĩ na mũraika mwena wake arĩ mũiguithania, ũmwe harĩ ngiri, wa kwĩra mũndũ ũndũ ũrĩa ũmwagĩrĩire,
24 nígbà náà ni ó ṣe oore-ọ̀fẹ́ fún un ó sì wí pé, gbà á kúrò nínú lílọ sínú isà òkú; èmi ti rà á padà.
nake amũkinyĩrie wega wake na oige atĩrĩ, ‘Mũhonokie ndagatuĩke wa gũikũrũka mbĩrĩra-inĩ; nĩnyonete gĩa kũmũkũũra nakĩo,’
25 Ara rẹ̀ yóò sì di ọ̀tun bí i ti ọmọ kékeré, yóò sì tún padà sí ọjọ́ ìgbà èwe rẹ̀;
hĩndĩ ĩyo nyama cia mwĩrĩ wake igeethĩha ta cia mwana; igaacooka ta ũrĩa ciarĩ matukũ-inĩ ma wĩthĩ wake.
26 Ó gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run, òun sì ṣe ojúrere rẹ̀, o sì rí ojú rẹ̀ pẹ̀lú ayọ̀, òhun o san òdodo rẹ̀ padà fún ènìyàn.
Ahooyaga Ngai ageekwo wega nĩwe, oonaga ũthiũ wa Ngai akaanĩrĩra nĩ gũkena; agacookio ũthingu-inĩ wake nĩ Ngai.
27 Ó wá sọ́dọ̀ ènìyàn ó sì wí pé, ‘Èmi ṣẹ̀, kò sì ṣí èyí tí o tọ́, mo sì ti yí èyí tí ó tọ́ po, a kò sì san ẹ̀san rẹ̀ fún mi;
Nake agacooka agathiĩ kũrĩ andũ akameera atĩrĩ, ‘Nĩndehirie, na ngĩogomia ũndũ ũrĩa warĩ wa ma, no ndiigana kũherithio ũrĩa ndaagĩrĩirwo nĩkũherithio.
28 Ọlọ́run ti gba ọkàn mi kúrò nínú lílọ sínú ihò, ẹ̀mí mi yóò wà láti jẹ adùn ìmọ́lẹ̀ ayé.’
Nĩakũũrire roho wakwa ndũkaharũrũkio mbĩrĩra, na niĩ ngũtũũra ngenagĩra ũtheri ũcio.’
29 “Wò ó! Nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́run máa ń ṣe fún ènìyàn nígbà méjì àti nígbà mẹ́ta,
“Mũrungu nĩekaga mũndũ maũndũ macio mothe, maita meerĩ o na kana matatũ,
30 láti mú ọkàn rẹ padà kúrò nínú isà òkú, láti fi ìmọ́lẹ̀ alààyè han sí i.
nĩguo agarũre roho wake ndũkaharũrũkio mbĩrĩra, nĩgeetha ũtheri ũcio wa muoyo ũmũtherere.
31 “Jobu, kíyèsi i gidigidi, kí o sì fetí sí mi; pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì máa sọ ọ́.
“Atĩrĩrĩ Ayubu, tega matũ na ũũthikĩrĩrie; kira ki na niĩ njarie.
32 Bí ìwọ bá sì ní ohun wí, dá mi lóhùn; máa sọ, nítorí pé èmi fẹ́ dá ọ láre.
Wakorwo ũrĩ na ũndũ wa kuuga-rĩ, njĩĩra; aria, nĩgũkorwo ingĩenda woneke ndwĩhĩtie.
33 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, gbọ́ tèmi; pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì kọ́ ọ ní ọgbọ́n.”
No akorwo ti ũguo-rĩ, wee gĩthikĩrĩrie; kira ki, na nĩngũkũruta ũũgĩ.”

< Job 33 >