< Job 31 >

1 “Mo ti bá ojú mi dá májẹ̀mú, èmi yó ha ṣe tẹjúmọ́ wúńdíá?
“Eu fiz um pacto com meus olhos; como então devo olhar com luxúria para uma jovem mulher?
2 Nítorí pé kí ni ìpín Ọlọ́run láti ọ̀run wá? Tàbí kí ni ogún Olódùmarè láti òkè ọ̀run wá.
Para o que é a parte de Deus acima, e a herança do Todo-Poderoso nas alturas?
3 Kò ṣe pé àwọn ènìyàn búburú ni ìparun wà fún, àti àjàkálẹ̀-ààrùn fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀?
Não é uma calamidade para os injustos? e desastre para os trabalhadores da iniqüidade?
4 Òun kò ha ri ipa ọ̀nà mi, òun kò ha sì ka gbogbo ìṣísẹ̀ mi?
Ele não vê meus caminhos, e contar todos os meus passos?
5 “Bí ó bá ṣe pé èmi bá fi àìṣòótọ́ rìn, tàbí tí ẹsẹ̀ mi sì yára sí ẹ̀tàn,
“Se eu tenho andado com falsidade, e meu pé se apressou em enganar
6 (jẹ́ kí Ọlọ́run wọ́n mí nínú ìwọ̀n òdodo, kí Ọlọ́run le mọ ìdúró ṣinṣin mi.)
(deixe-me ser pesado em um balanço equilibrado, que Deus possa conhecer minha integridade);
7 Bí ẹsẹ̀ mí bá yà kúrò lójú ọ̀nà, tí àyà mí sì tẹ̀lé ipa ojú mi, tàbí bí àbàwọ́n kan bá sì lẹ̀ mọ́ mi ní ọwọ́,
se meu passo tiver saído do caminho, se meu coração andasse atrás dos meus olhos, se alguma impureza ficou presa às minhas mãos,
8 ǹjẹ́ kí èmi kí ó gbìn kí ẹlòmíràn kí ó sì mújẹ, àní kí a fa irú-ọmọ mi tu.
then deixe-me semear, e deixe outro comer. Sim, que os produtos do meu campo sejam erradicados.
9 “Bí àyà mi bá di fífà sí ipasẹ̀ obìnrin kan, tàbí bí mo bá lọ í ba de ènìyàn ní ẹnu-ọ̀nà ilé aládùúgbò mi,
“Se meu coração foi seduzido por uma mulher, e eu tenho feito uma espera na porta do meu vizinho,
10 kí àyà mi kí ó lọ ọlọ fún ẹlòmíràn, kí àwọn ẹlòmíràn kí ó tẹ̀ ara wọn ní ara rẹ̀.
e depois deixar minha esposa moer por outro, e deixar outros dormirem com ela.
11 Nítorí pé yóò jẹ́ ohun ìtìjú àní, ẹ̀ṣẹ̀ tí a ó ṣe onídàájọ́ rẹ̀.
Pois isso seria um crime hediondo. Sim, seria uma iniquidade ser punido pelos juízes,
12 Nítorí pé iná ní èyí tí ó jó dé ibi ìparun, tí ìbá sì fa gbòǹgbò ohun ìbísí mi gbogbo tu.
pois é um incêndio que consome até a destruição, e que erradicaria todo o meu aumento.
13 “Tí mo bá sì ṣe àìka ọ̀ràn ìránṣẹ́kùnrin mi tàbí ìránṣẹ́bìnrin mi sí, nígbà tí wọ́n bá ń bá mi jà;
“Se eu desprezei a causa de meu servo masculino ou de minha funcionária, quando eles contendiam comigo,
14 kí ni èmi ó ha ṣe nígbà tí Ọlọ́run bá dìde? Nígbà tí ó bá sì ṣe ìbẹ̀wò, ohùn kí ni èmi ó dá?
o que então farei quando Deus se erguer? Quando ele me visitar, o que lhe responderei?
15 Ẹni tí ó dá mi ní inú kọ́ ni ó dá a? Ẹnìkan náà kí ó mọ wá ní inú ìyá wa?
Aquele que me fez no útero não o fez? Não nos moldou um no útero?
16 “Bí mo bá fa ọwọ́ sẹ́yìn fún ìfẹ́ inú tálákà, tàbí bí mo bá sì mú kí ojú opó rẹ̀wẹ̀sì,
“Se eu retive os pobres de seu desejo, ou causaram o fracasso dos olhos da viúva,
17 tàbí tí mo bá nìkan bu òkèlè mi jẹ, tí aláìní baba kò jẹ nínú rẹ̀;
ou ter comido meu bocado sozinho, e o sem-pai não comeu
18 nítorí pé láti ìgbà èwe mi wá ni a ti tọ́ ọ dàgbà pẹ̀lú mi bí ẹni pé baba, èmi sì ń ṣe ìtọ́jú opó láti inú ìyá mi wá:
(não, desde minha juventude ele cresceu comigo como com um pai, Eu a guiei desde o ventre de minha mãe);
19 bí èmi bá rí olùpọ́njú láìní aṣọ, tàbí tálákà kan láìní ìbora;
se eu vi algum perecer por falta de roupas, ou que os necessitados não tinham cobertura;
20 bí ọkàn rẹ̀ kò bá súre fún mi, tàbí bí ara rẹ̀ kò sì gbóná nípasẹ̀ irun àgùntàn mi;
se seu coração não me abençoou, se não tiver sido aquecido com o velo das minhas ovelhas;
21 bí mo bá sì gbé ọwọ́ mi sókè sí aláìní baba, nítorí pé mo rí ìrànlọ́wọ́ mi ní ẹnu ibodè,
se eu levantei minha mão contra os órfãos de pai, porque eu vi minha ajuda no portão;
22 ǹjẹ́, ní apá mi kí o wọ́n kúrò ní ihò èjìká rẹ̀, kí apá mi kí ó sì ṣẹ́ láti egungun rẹ̀ wá.
depois deixar meu ombro cair da omoplata, e meu braço ser quebrado do osso.
23 Nítorí pé ìparun láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ni ẹ̀rù ńlá fún mi, àti nítorí ọláńlá rẹ̀ èmi kò le è dúró.
Pois a calamidade de Deus é um terror para mim. Por causa de sua majestade, eu não posso fazer nada.
24 “Bí ó bá ṣe pé mo fi wúrà ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé mi, tàbí tí mo bá wí fún fàdákà dídára pé, ‘Ìwọ ni ààbò mi,’
“Se eu fiz do ouro minha esperança, e disse ao ouro fino: “Você é minha confiança”.
25 bí mo bá yọ̀ nítorí ọrọ̀ mí pọ̀, àti nítorí ọwọ́ mi dara lọ́pọ̀lọ́pọ̀,
Se eu me regozijei porque minha riqueza era grande, e porque minha mão tinha conseguido muito;
26 bí mo bá bojú wo oòrùn nígbà tí ń ràn, tàbí òṣùpá tí ń ràn nínú ìtànmọ́lẹ̀,
se eu tiver visto o sol quando brilhou, ou a lua se movendo em esplendor,
27 bí a bá tàn ọkàn mi jẹ láti fi ẹnu mi kò ọwọ́ mi,
e meu coração tem sido secretamente seduzido, e minha mão jogou um beijo da minha boca;
28 èyí pẹ̀lú ni ẹ̀ṣẹ̀ ti àwọn onídàájọ́ ní láti bẹ̀wò, nítorí pé èmí yóò jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run tí ó wà lókè.
isto também seria uma iniquidade a ser punida pelos juízes, pois eu teria negado o Deus que está acima.
29 “Bí ó bá ṣe pé mo yọ̀ sì ìparun ẹni tí ó kórìíra mi. Tàbí bí mo bá sì gbéraga sókè, nígbà tí ibi bá a.
“Se eu me alegrei com a destruição daquele que me odiava, ou me levantei quando o mal o encontrou
30 Bẹ́ẹ̀ èmi kò sì jẹ ki ẹnu mi ki ó ṣẹ̀ nípa fífẹ́ ègún sí ọkàn rẹ̀.
(certamente não permiti que minha boca pecasse perguntando sua vida com uma maldição);
31 Bí àwọn ènìyàn inú àgọ́ mi kò bá lè wí pé, ‘Ta ni kò ì tí ì jẹ ẹran rẹ̀ ní àjẹyó?’
se os homens da minha tenda não tiverem dito, “Quem pode encontrar alguém que não tenha sido preenchido com sua carne?
32 Àlejò kò wọ̀ ni ìgboro rí; èmí ṣí ìlẹ̀kùn mi sílẹ̀ fún èrò.
(o estrangeiro não acampou na rua, mas eu abri minhas portas para o viajante);
33 Bí mo bá bò ẹ̀ṣẹ̀ mi mọ́lẹ̀ bí Adamu ni pápá, ẹ̀bi mi pamọ́ ni àyà mi.
se, como Adam, eu já cobri minhas transgressões, escondendo minha iniqüidade em meu coração,
34 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni mo ha bẹ̀rù bí? Tàbí ẹ̀gàn àwọn ìdílé ní ń bà mí ní ẹ̀rù? Tí mo fi pa ẹnu mọ́, tí èmí kò sì fi sọ̀rọ̀ jáde?
porque eu temia a grande multidão, e o desprezo das famílias me aterrorizava, para que eu ficasse em silêncio e não saísse pela porta...
35 (“Ìbá ṣe pé ẹnìkan le gbọ́ ti èmí! Kíyèsi i, àmì mi, kí Olódùmarè kí ó dá mi lóhùn, kí èmí kí ó sì rí ìwé náà tí olùfisùn mi ti kọ.
oh que eu tinha um para me ouvir! Eis aqui a minha assinatura! Que o Todo-Poderoso me responda! Deixe o acusador escrever minha acusação!
36 Nítòótọ́ èmí ìbá gbé le èjìká mi, èmi ìbá sì dé bí adé mọ́ orí mi.
Com certeza, eu o carregaria no ombro, e eu a amarraria a mim como uma coroa.
37 Èmi ìbá sì sọ iye ìṣísẹ̀ mi fún un, bí ọmọ-aládé ni èmi ìbá súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀.)
Eu declararia a ele o número dos meus passos. Eu me aproximaria dele como um príncipe.
38 “Bí ilẹ̀ mi bá sì ké rara lòdì sí mi tí a sì fi omijé kún gbogbo poro rẹ̀.
Se minha terra gritar contra mim, e seus sulcos choram juntos;
39 Bí mo bá jẹ èso oko mi láìsan owó tàbí tí mo sì mú ọkàn olúwa rẹ̀ fò lọ,
se eu tiver comido suas frutas sem dinheiro, ou causaram a perda da vida de seus proprietários,
40 kí ẹ̀gún òṣùṣú kí ó hù dípò alikama, àti èpò búburú dípò ọkà barle.” Ọ̀rọ̀ Jobu parí.
let cresce o briers em vez do trigo, e malcheirosa ao invés de cevada”. As palavras de Jó estão terminadas.

< Job 31 >