< Job 31 >

1 “Mo ti bá ojú mi dá májẹ̀mú, èmi yó ha ṣe tẹjúmọ́ wúńdíá?
J’ai fait un pacte avec mes yeux pour ne pas même penser à une vierge.
2 Nítorí pé kí ni ìpín Ọlọ́run láti ọ̀run wá? Tàbí kí ni ogún Olódùmarè láti òkè ọ̀run wá.
Car autrement quelle part d’en haut aurait Dieu pour moi, et quel héritage des cieux, le Tout-Puissant?
3 Kò ṣe pé àwọn ènìyàn búburú ni ìparun wà fún, àti àjàkálẹ̀-ààrùn fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀?
Est-ce que la ruine n’est pas pour le méchant, et l’aliénation des héritages pour ceux qui opèrent l’injustice?
4 Òun kò ha ri ipa ọ̀nà mi, òun kò ha sì ka gbogbo ìṣísẹ̀ mi?
Dieu ne considère-t-il pas mes voies, et tous mes pas, ne les compte-t-il point?
5 “Bí ó bá ṣe pé èmi bá fi àìṣòótọ́ rìn, tàbí tí ẹsẹ̀ mi sì yára sí ẹ̀tàn,
Si j’ai marché dans la vanité; si mon pied s’est hâté dans la ruse;
6 (jẹ́ kí Ọlọ́run wọ́n mí nínú ìwọ̀n òdodo, kí Ọlọ́run le mọ ìdúró ṣinṣin mi.)
Que Dieu me pèse dans une balance juste, et qu’il connaisse ma simplicité.
7 Bí ẹsẹ̀ mí bá yà kúrò lójú ọ̀nà, tí àyà mí sì tẹ̀lé ipa ojú mi, tàbí bí àbàwọ́n kan bá sì lẹ̀ mọ́ mi ní ọwọ́,
Que si mon pas s’est détourné de la voie, et si mon cœur a suivi mes yeux, et si à mes mains s’est attachée quelque souillure;
8 ǹjẹ́ kí èmi kí ó gbìn kí ẹlòmíràn kí ó sì mújẹ, àní kí a fa irú-ọmọ mi tu.
Que je sème et qu’un autre mange, et que ma race soit arrachée jusqu’à la racine.
9 “Bí àyà mi bá di fífà sí ipasẹ̀ obìnrin kan, tàbí bí mo bá lọ í ba de ènìyàn ní ẹnu-ọ̀nà ilé aládùúgbò mi,
Si mon cœur a été séduit au sujet d’une femme, et si à la porte de mon ami j’ai dressé des embûches;
10 kí àyà mi kí ó lọ ọlọ fún ẹlòmíràn, kí àwọn ẹlòmíràn kí ó tẹ̀ ara wọn ní ara rẹ̀.
Que ma femme soit la prostituée d’un autre, et que d’autres la déshonorent.
11 Nítorí pé yóò jẹ́ ohun ìtìjú àní, ẹ̀ṣẹ̀ tí a ó ṣe onídàájọ́ rẹ̀.
Car l’adultère est un crime énorme, et une iniquité très grande.
12 Nítorí pé iná ní èyí tí ó jó dé ibi ìparun, tí ìbá sì fa gbòǹgbò ohun ìbísí mi gbogbo tu.
C’est un feu qui dévore jusqu’à la perdition, et qui extirpe toutes les productions.
13 “Tí mo bá sì ṣe àìka ọ̀ràn ìránṣẹ́kùnrin mi tàbí ìránṣẹ́bìnrin mi sí, nígbà tí wọ́n bá ń bá mi jà;
Si j’ai dédaigné d’aller en jugement avec mon serviteur et ma servante, lorsqu’ils disputaient contre moi.
14 kí ni èmi ó ha ṣe nígbà tí Ọlọ́run bá dìde? Nígbà tí ó bá sì ṣe ìbẹ̀wò, ohùn kí ni èmi ó dá?
(Car que ferai-je, lorsque Dieu se lèvera pour me juger? et lorsqu’il m’interrogera, que lui répondrai-je?
15 Ẹni tí ó dá mi ní inú kọ́ ni ó dá a? Ẹnìkan náà kí ó mọ wá ní inú ìyá wa?
N’est-ce pas celui qui m’a fait dans le sein de ma mère, qui l’a fait lui aussi, et le même qui m’a formé en elle?)
16 “Bí mo bá fa ọwọ́ sẹ́yìn fún ìfẹ́ inú tálákà, tàbí bí mo bá sì mú kí ojú opó rẹ̀wẹ̀sì,
Si j’ai refusé aux pauvres ce qu’ils voulaient, et si j’ai fait attendre les yeux de la veuve;
17 tàbí tí mo bá nìkan bu òkèlè mi jẹ, tí aláìní baba kò jẹ nínú rẹ̀;
Si j’ai mangé seul ma bouchée de pain, et si le pupille n’en a pas mangé aussi:
18 nítorí pé láti ìgbà èwe mi wá ni a ti tọ́ ọ dàgbà pẹ̀lú mi bí ẹni pé baba, èmi sì ń ṣe ìtọ́jú opó láti inú ìyá mi wá:
(Car dès mon enfance la compassion a crû avec moi, et du sein de ma mère elle est sortie avec moi.)
19 bí èmi bá rí olùpọ́njú láìní aṣọ, tàbí tálákà kan láìní ìbora;
Si j’ai détourné mes yeux de celui qui mourait, parce qu’il n’avait pas de quoi se couvrir, et du pauvre qui était sans vêtement;
20 bí ọkàn rẹ̀ kò bá súre fún mi, tàbí bí ara rẹ̀ kò sì gbóná nípasẹ̀ irun àgùntàn mi;
Si ses flancs ne m’ont pas béni, et s’il n’a pas été réchauffé par les toisons de mes brebis:
21 bí mo bá sì gbé ọwọ́ mi sókè sí aláìní baba, nítorí pé mo rí ìrànlọ́wọ́ mi ní ẹnu ibodè,
Si j’ai levé ma main contre un orphelin, même lorsque je me voyais supérieur à la porte de la ville:
22 ǹjẹ́, ní apá mi kí o wọ́n kúrò ní ihò èjìká rẹ̀, kí apá mi kí ó sì ṣẹ́ láti egungun rẹ̀ wá.
Que mon épaule tombe séparée de sa jointure, et que mon bras avec tous mes os soit entièrement brisé:
23 Nítorí pé ìparun láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ni ẹ̀rù ńlá fún mi, àti nítorí ọláńlá rẹ̀ èmi kò le è dúró.
Car j’ai toujours craint Dieu comme des îlots soulevés au-dessus de moi, et je n’ai pu supporter le poids de sa majesté.
24 “Bí ó bá ṣe pé mo fi wúrà ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé mi, tàbí tí mo bá wí fún fàdákà dídára pé, ‘Ìwọ ni ààbò mi,’
Si j’ai pris l’or pour ma force, et si j’ai dit à l’or affiné: Tu es ma confiance:
25 bí mo bá yọ̀ nítorí ọrọ̀ mí pọ̀, àti nítorí ọwọ́ mi dara lọ́pọ̀lọ́pọ̀,
Si je me suis livré à l’allégresse à cause de mes abondantes richesses, et parce que ma main a trouvé des biens en très grand nombre;
26 bí mo bá bojú wo oòrùn nígbà tí ń ràn, tàbí òṣùpá tí ń ràn nínú ìtànmọ́lẹ̀,
Si j’ai vu le soleil, lorsqu’il brillait de son vif éclat, et la lune marchant dans son clair,
27 bí a bá tàn ọkàn mi jẹ láti fi ẹnu mi kò ọwọ́ mi,
Et si mon cœur s’est livré à la joie en secret, et si j’ai baisé ma main de ma bouche;
28 èyí pẹ̀lú ni ẹ̀ṣẹ̀ ti àwọn onídàájọ́ ní láti bẹ̀wò, nítorí pé èmí yóò jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run tí ó wà lókè.
Ce qui est une iniquité très grande, et nier le Dieu très haut:
29 “Bí ó bá ṣe pé mo yọ̀ sì ìparun ẹni tí ó kórìíra mi. Tàbí bí mo bá sì gbéraga sókè, nígbà tí ibi bá a.
Si je me suis réjoui de la ruine de celui qui me haïssait, et si j’ai bondi de joie de ce que le malheur l’avait atteint:
30 Bẹ́ẹ̀ èmi kò sì jẹ ki ẹnu mi ki ó ṣẹ̀ nípa fífẹ́ ègún sí ọkàn rẹ̀.
(Car je n’ai pas permis à ma bouche de pécher en cherchant à maudire son âme.)
31 Bí àwọn ènìyàn inú àgọ́ mi kò bá lè wí pé, ‘Ta ni kò ì tí ì jẹ ẹran rẹ̀ ní àjẹyó?’
Si les hommes de ma tente n’ont pas dit: Qui nous donnera de nous rassasier de sa chair?
32 Àlejò kò wọ̀ ni ìgboro rí; èmí ṣí ìlẹ̀kùn mi sílẹ̀ fún èrò.
(L’étranger en effet n’est pas resté dehors; ma porte a toujours été ouverte au voyageur.)
33 Bí mo bá bò ẹ̀ṣẹ̀ mi mọ́lẹ̀ bí Adamu ni pápá, ẹ̀bi mi pamọ́ ni àyà mi.
Si comme homme, j’ai tenu mon péché secret, et si j’ai caché dans mon sein mon iniquité;
34 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni mo ha bẹ̀rù bí? Tàbí ẹ̀gàn àwọn ìdílé ní ń bà mí ní ẹ̀rù? Tí mo fi pa ẹnu mọ́, tí èmí kò sì fi sọ̀rọ̀ jáde?
Si j’ai été saisi d’effroi à cause de la grande multitude, et si le mépris de mes reproches m’a épouvanté, et si je ne me suis pas plutôt tenu dans le silence, sans sortir de ma porte:
35 (“Ìbá ṣe pé ẹnìkan le gbọ́ ti èmí! Kíyèsi i, àmì mi, kí Olódùmarè kí ó dá mi lóhùn, kí èmí kí ó sì rí ìwé náà tí olùfisùn mi ti kọ.
Qui me donnera quelqu’un qui m’entende, afin que le Tout-Puissant écoute mon désir, et que celui qui juge, écrive lui-même un livre,
36 Nítòótọ́ èmí ìbá gbé le èjìká mi, èmi ìbá sì dé bí adé mọ́ orí mi.
Afin que sur mon épaule je porte ce livre, et que je le mette comme une couronne autour de ma tête?
37 Èmi ìbá sì sọ iye ìṣísẹ̀ mi fún un, bí ọmọ-aládé ni èmi ìbá súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀.)
À chacun de mes pas j’en prononcerai les paroles, et je le présenterai comme à un prince.
38 “Bí ilẹ̀ mi bá sì ké rara lòdì sí mi tí a sì fi omijé kún gbogbo poro rẹ̀.
Si la terre qui m’appartient crie contre moi, et que ses sillons pleurent avec elle;
39 Bí mo bá jẹ èso oko mi láìsan owó tàbí tí mo sì mú ọkàn olúwa rẹ̀ fò lọ,
Si j’ai mangé ses fruits sans argent, et si j’ai affligé l’âme de ses cultivateurs:
40 kí ẹ̀gún òṣùṣú kí ó hù dípò alikama, àti èpò búburú dípò ọkà barle.” Ọ̀rọ̀ Jobu parí.
Qu’au lieu de blé il me naisse des ronces, et au lieu d’orge, des épines.

< Job 31 >