< Job 30 >

1 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn tí mo gbà ní àbúrò ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà baba ẹni tí èmi kẹ́gàn láti tò pẹ̀lú àwọn ajá nínú agbo ẹran mi.
Ныне же поругашамися малейшии: ныне учат мя от части, ихже отцев уничтожах, ихже не вменях достойными псов моих стад.
2 Kí ni ìwúlò agbára ọwọ́ wọn sí mi, níwọ̀n ìgbà tí agbára wọn ti fi wọ́n sílẹ̀?
Крепость же рук их во что мне бысть? У них погибаше скончание.
3 Wọ́n rù nítorí àìní àti ìyàn wọ́n ń rìn káàkiri ní ilẹ̀ gbígbẹ ní ibi ìkọ̀sílẹ̀ ní òru.
В скудости и гладе безплоден: иже бежаху в безводное вчера сотеснение и бедность:
4 Àwọn ẹni tí ń já ewé iyọ̀ ní ẹ̀bá igbó; gbogbo igikígi ni oúnjẹ jíjẹ wọn.
иже обхождаху былие в дебрех, имже былие бяше брашно, безчестнии же и похуленнии, скудни всякаго блага, иже и корение древес жваху от глада великаго.
5 A lé wọn kúrò láàrín ènìyàn, àwọn ènìyàn sì pariwo lé wọn lórí bí ẹní pariwo lé olè lórí.
Восташа на мя татие,
6 A mú wọn gbe inú pàlàpálá òkúta àfonífojì, nínú ihò ilẹ̀ àti ti òkúta.
ихже домове беша пещеры каменны:
7 Wọ́n ń dún ní àárín igbó wọ́n kó ara wọn jọ pọ̀ ní abẹ́ ẹ̀gún neteli.
от среды доброгласных возопиют, иже под хврастием дивиим живяху:
8 Àwọn ọmọ ẹni tí òye kò yé, àní àwọn ọmọ lásán, a sì lé wọn jáde kúrò ní orí ilẹ̀.
безумных сынове и безчестных, имя и слава угашена на земли.
9 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, àwọn ọmọ wọn ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà nínú orin; àní èmi di ẹni ìṣọ̀rọ̀ sí láàrín wọn.
Ныне же гусли есмь аз им, и мене в притчу имут:
10 Wọ́n kórìíra mi; wọ́n sá kúrò jìnnà sí mi, wọn kò sì bìkítà láti tutọ́ sí mi lójú.
возгнушалися же мною отступивше далече, ни лица моего пощадеша от плюновения.
11 Nítorí Ọlọ́run ti tú okùn ìyè mi, ó sì pọ́n mi lójú; àwọn pẹ̀lú sì dẹ ìdẹ̀kùn níwájú mi.
Отверз бо тул Свой уязви мя, и узду устам моим наложи.
12 Àwọn ènìyàn lásán dìde ní apá ọ̀tún mi; wọ́n tì ẹsẹ̀ mi kúrò, wọ́n sì la ipa ọ̀nà ìparun sílẹ̀ dè mí.
На десную отрасли восташа, нозе свои простроша и путесотвориша на мя стези пагубы своея.
13 Wọ́n da ipa ọ̀nà mi rú; wọ́n sì sọ ìparun mi di púpọ̀, àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.
Сотрошася стези моя, совлекоша бо ми одежду.
14 Wọ́n ya sí mi bí i omi tí ó ya gbuuru; ní ariwo ńlá ni wọ́n rọ́ wá.
Стрелами своими устрели мя: сотвори ми, якоже восхоте: в болезнех скисохся, обращаются же ми скорби.
15 Ẹ̀rù ńlá bà mí; wọ́n lépa ọkàn mi bí ẹ̀fúùfù, àlàáfíà mi sì kọjá lọ bí àwọ̀ sánmọ̀.
Отиде ми надежда якоже ветр, и якоже облак спасение мое.
16 “Àti nísinsin yìí, ayé mi n yòrò lọ díẹ̀díẹ̀; ọjọ́ ìpọ́njú mi dì mímú.
И ныне на мя излиется душа моя: и одержат мя дние печалей:
17 Òru gún mi nínú egungun mi, èyí tí ó bù mí jẹ kò sì sinmi.
нощию же кости моя смятошася, жилы же моя разслабеша.
18 Nípa agbára ńlá rẹ̀ Ọlọ́run wà bí aṣọ ìbora fún mi, ó sì lẹ̀ mọ́ mi ní ara yíká bí aṣọ ìlekè mi.
Многою крепостию ятся за ризу мою: якоже ожерелие ризы моея объя мя.
19 Ọlọ́run ti mú mi lọ sínú ẹrẹ̀, èmi sì dàbí eruku àti eérú.
Вменяеши же мя равна брению, в земли и пепеле часть моя.
20 “Èmi ké pè ọ́ ìwọ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi lóhùn; èmi dìde dúró ìwọ sì wò mí lásán.
Возопих же к Тебе, и не услышал мя еси: сташа же и смотриша на мя.
21 Ìwọ padà di ẹni ìkà sí mi; ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ fi dè mí ní ọ̀nà.
Наидоша же на мя без милости, рукою крепкою уязвил мя еси:
22 Ìwọ gbé mi sókè sí inú ẹ̀fúùfù, ìwọ mú mi fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì sọ mí di asán pátápátá.
вчинил же мя еси в болезнех и отвергл еси мя от спасения.
23 Èmi sá à mọ̀ pé ìwọ yóò mú mi lọ sínú ikú, sí ilé ìpéjọ tí a yàn fún gbogbo alààyè.
Вем бо, яко смерть мя сотрет: дом бо всякому смертну земля.
24 “Bí ó ti wù kí ó rí, ẹnìkan kí yóò ha nawọ́ rẹ̀ nígbà ìṣubú rẹ̀, tàbí kì yóò ké nínú ìparun rẹ̀.
Аще бы возможно было, сам бых себе убил, или молил бых иного, дабы ми то сотворил.
25 Èmi kò ha sọkún bí fún ẹni tí ó wà nínú ìṣòro? Ọkàn mi kò ha bàjẹ́ fún tálákà bí?
Аз же о всяцем немощнем восплакахся, воздохнух же видев мужа в бедах.
26 Nígbà tí mo fojú ṣọ́nà fún àlàáfíà, ibi sì dé; nígbà tí mo dúró de ìmọ́lẹ̀, òkùnkùn sì dé.
Аз же ждах благих, и се, сретоша мя паче дние зол.
27 Ikùn mí n ru kò sì sinmi, ọjọ́ ìpọ́njú ti dé bá mi.
Чрево мое воскипе и не умолчит: предвариша мя дние нищеты.
28 Èmí ń rìn kiri nínú ọ̀fọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú oòrùn; èmi dìde dúró ní àwùjọ mo sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́.
Стеня ходих без обуздания, стоях же в соборе вопия.
29 Èmi ti di arákùnrin ìkookò, èmi di ẹgbẹ́ àwọn ògòǹgò.
Брат бых сиринам, друг же птичий.
30 Àwọ̀ mi di dúdú ní ara mi; egungun mi sì jórun fún ooru.
Кожа же моя помрачися вельми, и кости моя сгореша от зноя.
31 Ohun èlò orin mi pẹ̀lú sì di ti ọ̀fọ̀, àti ìpè orin mi sì di ohùn àwọn tí ń sọkún.
Обратишася же в плачь гусли моя, песнь же моя в рыдание мне.

< Job 30 >