< Job 30 >
1 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn tí mo gbà ní àbúrò ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà baba ẹni tí èmi kẹ́gàn láti tò pẹ̀lú àwọn ajá nínú agbo ẹran mi.
“Mas agora, aqueles que são mais jovens do que eu me ridicularizaram, cujos pais eu considerava indignos de colocar com meus cães de ovelha.
2 Kí ni ìwúlò agbára ọwọ́ wọn sí mi, níwọ̀n ìgbà tí agbára wọn ti fi wọ́n sílẹ̀?
De que me serve a força de suas mãos? homens em que a idade madura pereceu?
3 Wọ́n rù nítorí àìní àti ìyàn wọ́n ń rìn káàkiri ní ilẹ̀ gbígbẹ ní ibi ìkọ̀sílẹ̀ ní òru.
They são gafanhotos da falta e da fome. Eles roem o solo seco, no meio da escuridão do desperdício e da desolação.
4 Àwọn ẹni tí ń já ewé iyọ̀ ní ẹ̀bá igbó; gbogbo igikígi ni oúnjẹ jíjẹ wọn.
Eles depenam ervas salinas junto aos arbustos. As raízes da árvore da vassoura são seu alimento.
5 A lé wọn kúrò láàrín ènìyàn, àwọn ènìyàn sì pariwo lé wọn lórí bí ẹní pariwo lé olè lórí.
Eles são expulsos do meio dos homens. Choram atrás deles como depois de um ladrão,
6 A mú wọn gbe inú pàlàpálá òkúta àfonífojì, nínú ihò ilẹ̀ àti ti òkúta.
so que eles vivem em vales assustadores, e em buracos da terra e das rochas.
7 Wọ́n ń dún ní àárín igbó wọ́n kó ara wọn jọ pọ̀ ní abẹ́ ẹ̀gún neteli.
Eles se vangloriam entre os arbustos. Elas são reunidas sob as urtigas.
8 Àwọn ọmọ ẹni tí òye kò yé, àní àwọn ọmọ lásán, a sì lé wọn jáde kúrò ní orí ilẹ̀.
Eles são filhos de tolos, sim, filhos de homens maus. Eles foram açoitados para fora da terra.
9 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, àwọn ọmọ wọn ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà nínú orin; àní èmi di ẹni ìṣọ̀rọ̀ sí láàrín wọn.
“Agora me tornei a canção deles. Sim, eu sou uma palavra de ordem para eles.
10 Wọ́n kórìíra mi; wọ́n sá kúrò jìnnà sí mi, wọn kò sì bìkítà láti tutọ́ sí mi lójú.
Eles me abominam, eles se distanciam de mim, e não hesite em cuspir na minha cara.
11 Nítorí Ọlọ́run ti tú okùn ìyè mi, ó sì pọ́n mi lójú; àwọn pẹ̀lú sì dẹ ìdẹ̀kùn níwájú mi.
Pois ele desatou seu cordão, e me afligiu; e eles se livraram da contenção diante de mim.
12 Àwọn ènìyàn lásán dìde ní apá ọ̀tún mi; wọ́n tì ẹsẹ̀ mi kúrò, wọ́n sì la ipa ọ̀nà ìparun sílẹ̀ dè mí.
À minha direita, levante a multidão. Eles empurram meus pés para o lado. Eles lançam seus caminhos de destruição contra mim.
13 Wọ́n da ipa ọ̀nà mi rú; wọ́n sì sọ ìparun mi di púpọ̀, àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.
Eles estragam meu caminho. Eles promovem minha destruição sem a ajuda de ninguém.
14 Wọ́n ya sí mi bí i omi tí ó ya gbuuru; ní ariwo ńlá ni wọ́n rọ́ wá.
Como através de uma ampla brecha, eles vêm. Eles se enrolam em meio à ruína.
15 Ẹ̀rù ńlá bà mí; wọ́n lépa ọkàn mi bí ẹ̀fúùfù, àlàáfíà mi sì kọjá lọ bí àwọ̀ sánmọ̀.
Os terroristas se voltaram contra mim. Eles perseguem minha honra como o vento. Meu bem-estar faleceu como uma nuvem.
16 “Àti nísinsin yìí, ayé mi n yòrò lọ díẹ̀díẹ̀; ọjọ́ ìpọ́njú mi dì mímú.
“Agora minha alma está derramada dentro de mim. Os dias de aflição se apoderaram de mim.
17 Òru gún mi nínú egungun mi, èyí tí ó bù mí jẹ kò sì sinmi.
Na estação noturna meus ossos são trespassados em mim, e as dores que me roem não descansam.
18 Nípa agbára ńlá rẹ̀ Ọlọ́run wà bí aṣọ ìbora fún mi, ó sì lẹ̀ mọ́ mi ní ara yíká bí aṣọ ìlekè mi.
Minha peça de vestuário está desfigurada por uma grande força. Me prende como o colarinho da minha túnica.
19 Ọlọ́run ti mú mi lọ sínú ẹrẹ̀, èmi sì dàbí eruku àti eérú.
Ele me lançou na lama. Eu me tornei como poeira e cinzas.
20 “Èmi ké pè ọ́ ìwọ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi lóhùn; èmi dìde dúró ìwọ sì wò mí lásán.
Eu choro para você, e você não me responde. Eu me levanto e você me olha de frente.
21 Ìwọ padà di ẹni ìkà sí mi; ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ fi dè mí ní ọ̀nà.
Você se tornou cruel para mim. Com o poder de sua mão, você me persegue.
22 Ìwọ gbé mi sókè sí inú ẹ̀fúùfù, ìwọ mú mi fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì sọ mí di asán pátápátá.
Você me levanta até o vento e me leva com ele. Você me dissolve na tempestade.
23 Èmi sá à mọ̀ pé ìwọ yóò mú mi lọ sínú ikú, sí ilé ìpéjọ tí a yàn fún gbogbo alààyè.
Pois eu sei que você me trará à morte, para a casa designada para todos os habitantes.
24 “Bí ó ti wù kí ó rí, ẹnìkan kí yóò ha nawọ́ rẹ̀ nígbà ìṣubú rẹ̀, tàbí kì yóò ké nínú ìparun rẹ̀.
“Entretanto, não se estende uma mão em sua queda? Ou em sua calamidade, portanto, clamando por ajuda?
25 Èmi kò ha sọkún bí fún ẹni tí ó wà nínú ìṣòro? Ọkàn mi kò ha bàjẹ́ fún tálákà bí?
Eu não chorei por ele que estava em apuros? Minha alma não ficou de luto pelos necessitados?
26 Nígbà tí mo fojú ṣọ́nà fún àlàáfíà, ibi sì dé; nígbà tí mo dúró de ìmọ́lẹ̀, òkùnkùn sì dé.
Quando procurei o bem, então veio o mal. Quando esperei pela luz, veio a escuridão.
27 Ikùn mí n ru kò sì sinmi, ọjọ́ ìpọ́njú ti dé bá mi.
Meu coração está perturbado, e não descansa. Dias de aflição vieram sobre mim.
28 Èmí ń rìn kiri nínú ọ̀fọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú oòrùn; èmi dìde dúró ní àwùjọ mo sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́.
Vou de luto sem o sol. Eu me levanto na assembléia e clamo por ajuda.
29 Èmi ti di arákùnrin ìkookò, èmi di ẹgbẹ́ àwọn ògòǹgò.
Sou um irmão de chacais, e um companheiro de avestruzes.
30 Àwọ̀ mi di dúdú ní ara mi; egungun mi sì jórun fún ooru.
Minha pele cresce preta e se descasca de mim. Meus ossos estão queimados com o calor.
31 Ohun èlò orin mi pẹ̀lú sì di ti ọ̀fọ̀, àti ìpè orin mi sì di ohùn àwọn tí ń sọkún.
Por isso, minha harpa se transformou em luto, e meu cachimbo na voz daqueles que choram.