< Job 30 >
1 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn tí mo gbà ní àbúrò ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà baba ẹni tí èmi kẹ́gàn láti tò pẹ̀lú àwọn ajá nínú agbo ẹran mi.
But now they who are younger than I in years laugh at me, whose fathers I scorned to put as equals with the dogs of my flocks.
2 Kí ni ìwúlò agbára ọwọ́ wọn sí mi, níwọ̀n ìgbà tí agbára wọn ti fi wọ́n sílẹ̀?
Yea, what possible use can the strength of their hands be unto me, over whom old age hath passed fruitlessly?
3 Wọ́n rù nítorí àìní àti ìyàn wọ́n ń rìn káàkiri ní ilẹ̀ gbígbẹ ní ibi ìkọ̀sílẹ̀ ní òru.
Who suffer for want and famine in solitude; who flee into the wilderness [where all is] darkness, ruin, and desolation;
4 Àwọn ẹni tí ń já ewé iyọ̀ ní ẹ̀bá igbó; gbogbo igikígi ni oúnjẹ jíjẹ wọn.
Who crop off mallows by the bushes, and have broom-bush roots as their bread;
5 A lé wọn kúrò láàrín ènìyàn, àwọn ènìyàn sì pariwo lé wọn lórí bí ẹní pariwo lé olè lórí.
Who are driven forth from among [men], who are shouted after as though they were thieves,
6 A mú wọn gbe inú pàlàpálá òkúta àfonífojì, nínú ihò ilẹ̀ àti ti òkúta.
To dwell in the caverns of the valleys, in holes of the earth, and on naked cliffs.
7 Wọ́n ń dún ní àárín igbó wọ́n kó ara wọn jọ pọ̀ ní abẹ́ ẹ̀gún neteli.
Among the bushes they shriek; under briers they are huddled together,
8 Àwọn ọmọ ẹni tí òye kò yé, àní àwọn ọmọ lásán, a sì lé wọn jáde kúrò ní orí ilẹ̀.
The children of the worthless, yea, the children of the nameless, who were outcasts from the land.
9 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, àwọn ọmọ wọn ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà nínú orin; àní èmi di ẹni ìṣọ̀rọ̀ sí láàrín wọn.
But now I am become their song, and I am become a byword unto them.
10 Wọ́n kórìíra mi; wọ́n sá kúrò jìnnà sí mi, wọn kò sì bìkítà láti tutọ́ sí mi lójú.
They loathe me, they keep themselves far from me, and from my face they withhold not their spittle.
11 Nítorí Ọlọ́run ti tú okùn ìyè mi, ó sì pọ́n mi lójú; àwọn pẹ̀lú sì dẹ ìdẹ̀kùn níwájú mi.
Because he hath loosened the cord of my bow, and afflicted me, they have also cast off the bridle before me.
12 Àwọn ènìyàn lásán dìde ní apá ọ̀tún mi; wọ́n tì ẹsẹ̀ mi kúrò, wọ́n sì la ipa ọ̀nà ìparun sílẹ̀ dè mí.
Against my right hand rise up this swarm of worthless youths: they push away my feet, and they level against me their calamity-bringing paths.
13 Wọ́n da ipa ọ̀nà mi rú; wọ́n sì sọ ìparun mi di púpọ̀, àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.
They destroy my footpath, they help forward my downfall, without any one to aid them.
14 Wọ́n ya sí mi bí i omi tí ó ya gbuuru; ní ariwo ńlá ni wọ́n rọ́ wá.
As [through] a broad breach they come: amidst a loud noise they rolled themselves along.
15 Ẹ̀rù ńlá bà mí; wọ́n lépa ọkàn mi bí ẹ̀fúùfù, àlàáfíà mi sì kọjá lọ bí àwọ̀ sánmọ̀.
Terrors have turned their face against me; they chase like the wind my glory: and like a cloud is my happiness passed away.
16 “Àti nísinsin yìí, ayé mi n yòrò lọ díẹ̀díẹ̀; ọjọ́ ìpọ́njú mi dì mímú.
And now my soul is poured out over me; the days of affliction have seized on me;
17 Òru gún mi nínú egungun mi, èyí tí ó bù mí jẹ kò sì sinmi.
All night it holloweth out my bones out of my body; and my pursuers take no rest.
18 Nípa agbára ńlá rẹ̀ Ọlọ́run wà bí aṣọ ìbora fún mi, ó sì lẹ̀ mọ́ mi ní ara yíká bí aṣọ ìlekè mi.
Through the Almlghty's power is my garment made unknown: like the opening of my coat hath he enclosed me.
19 Ọlọ́run ti mú mi lọ sínú ẹrẹ̀, èmi sì dàbí eruku àti eérú.
He hath cast me into the mire, and I am become like dust and ashes.
20 “Èmi ké pè ọ́ ìwọ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi lóhùn; èmi dìde dúró ìwọ sì wò mí lásán.
I cry aloud unto thee, but thou answerest me not: I stand up, and thou fixest thy regard against me.
21 Ìwọ padà di ẹni ìkà sí mi; ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ fi dè mí ní ọ̀nà.
Thou art changed into a cruel master toward me: with the strength of thy hand thou assailest me.
22 Ìwọ gbé mi sókè sí inú ẹ̀fúùfù, ìwọ mú mi fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì sọ mí di asán pátápátá.
Thou liftest me up to the wind; thou causest me to pass away, and dissolvest in me all wise counsel.
23 Èmi sá à mọ̀ pé ìwọ yóò mú mi lọ sínú ikú, sí ilé ìpéjọ tí a yàn fún gbogbo alààyè.
For I know that thou wilt bring me back to death, and to the house of assembly for all the living.
24 “Bí ó ti wù kí ó rí, ẹnìkan kí yóò ha nawọ́ rẹ̀ nígbà ìṣubú rẹ̀, tàbí kì yóò ké nínú ìparun rẹ̀.
But doth not a man stretch out his hand among ruins? or doth one not cry out therefrom [for help] when he meeteth his downfall?
25 Èmi kò ha sọkún bí fún ẹni tí ó wà nínú ìṣòro? Ọkàn mi kò ha bàjẹ́ fún tálákà bí?
Did I not weep for him that was hard pressed by misfortune? was not my soul grieved for the needy?
26 Nígbà tí mo fojú ṣọ́nà fún àlàáfíà, ibi sì dé; nígbà tí mo dúró de ìmọ́lẹ̀, òkùnkùn sì dé.
That I hoped for good, but there came evil; and I waited for light, and there came darkness!
27 Ikùn mí n ru kò sì sinmi, ọjọ́ ìpọ́njú ti dé bá mi.
My bowels heave, and rest not: the days of affliction have overcome me.
28 Èmí ń rìn kiri nínú ọ̀fọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú oòrùn; èmi dìde dúró ní àwùjọ mo sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́.
I walk about mournfully without sunlight: when I rise up, in the assembly, I cry with pain.
29 Èmi ti di arákùnrin ìkookò, èmi di ẹgbẹ́ àwọn ògòǹgò.
I am a brother to [howling] monsters, and a companion to ostriches.
30 Àwọ̀ mi di dúdú ní ara mi; egungun mi sì jórun fún ooru.
My skin hangeth down black from me, and my bones are burnt from heat.
31 Ohun èlò orin mi pẹ̀lú sì di ti ọ̀fọ̀, àti ìpè orin mi sì di ohùn àwọn tí ń sọkún.
And thus is changed to mourning my harp, and my pipe to the sound of weeping.