< Job 30 >
1 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn tí mo gbà ní àbúrò ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà baba ẹni tí èmi kẹ́gàn láti tò pẹ̀lú àwọn ajá nínú agbo ẹran mi.
But now they that are younger than I have me in derision, whose fathers I would have disdained to set with the dogs of my flock.
2 Kí ni ìwúlò agbára ọwọ́ wọn sí mi, níwọ̀n ìgbà tí agbára wọn ti fi wọ́n sílẹ̀?
Yea, whereto [should] the strength of their hands [profit] me, [men] in whom vigour hath perished?
3 Wọ́n rù nítorí àìní àti ìyàn wọ́n ń rìn káàkiri ní ilẹ̀ gbígbẹ ní ibi ìkọ̀sílẹ̀ ní òru.
Withered up through want and hunger, they flee into waste places long since desolate and desert:
4 Àwọn ẹni tí ń já ewé iyọ̀ ní ẹ̀bá igbó; gbogbo igikígi ni oúnjẹ jíjẹ wọn.
They gather the salt-wort among the bushes, and the roots of the broom for their food.
5 A lé wọn kúrò láàrín ènìyàn, àwọn ènìyàn sì pariwo lé wọn lórí bí ẹní pariwo lé olè lórí.
They are driven forth from among [men] — they cry after them as after a thief —
6 A mú wọn gbe inú pàlàpálá òkúta àfonífojì, nínú ihò ilẹ̀ àti ti òkúta.
To dwell in gloomy gorges, in caves of the earth and the rocks:
7 Wọ́n ń dún ní àárín igbó wọ́n kó ara wọn jọ pọ̀ ní abẹ́ ẹ̀gún neteli.
They bray among the bushes; under the brambles they are gathered together:
8 Àwọn ọmọ ẹni tí òye kò yé, àní àwọn ọmọ lásán, a sì lé wọn jáde kúrò ní orí ilẹ̀.
Sons of fools, and sons of nameless sires, they are driven out of the land.
9 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, àwọn ọmọ wọn ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà nínú orin; àní èmi di ẹni ìṣọ̀rọ̀ sí láàrín wọn.
And now I am their song, yea, I am their byword.
10 Wọ́n kórìíra mi; wọ́n sá kúrò jìnnà sí mi, wọn kò sì bìkítà láti tutọ́ sí mi lójú.
They abhor me, they stand aloof from me, yea, they spare not to spit in my face.
11 Nítorí Ọlọ́run ti tú okùn ìyè mi, ó sì pọ́n mi lójú; àwọn pẹ̀lú sì dẹ ìdẹ̀kùn níwájú mi.
For he hath loosed my cord and afflicted me; so they cast off the bridle before me.
12 Àwọn ènìyàn lásán dìde ní apá ọ̀tún mi; wọ́n tì ẹsẹ̀ mi kúrò, wọ́n sì la ipa ọ̀nà ìparun sílẹ̀ dè mí.
At [my] right hand rise the young brood; they push away my feet, and raise up against me their pernicious ways;
13 Wọ́n da ipa ọ̀nà mi rú; wọ́n sì sọ ìparun mi di púpọ̀, àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.
They mar my path, they set forward my calamity, without any to help them;
14 Wọ́n ya sí mi bí i omi tí ó ya gbuuru; ní ariwo ńlá ni wọ́n rọ́ wá.
They come in as through a wide breach: amid the confusion they roll themselves onward.
15 Ẹ̀rù ńlá bà mí; wọ́n lépa ọkàn mi bí ẹ̀fúùfù, àlàáfíà mi sì kọjá lọ bí àwọ̀ sánmọ̀.
Terrors are turned against me; they pursue mine honour as the wind; and my welfare is passed away like a cloud.
16 “Àti nísinsin yìí, ayé mi n yòrò lọ díẹ̀díẹ̀; ọjọ́ ìpọ́njú mi dì mímú.
And now my soul is poured out in me; days of affliction have taken hold upon me.
17 Òru gún mi nínú egungun mi, èyí tí ó bù mí jẹ kò sì sinmi.
The night pierceth through my bones [and detacheth them] from me, and my gnawing pains take no rest:
18 Nípa agbára ńlá rẹ̀ Ọlọ́run wà bí aṣọ ìbora fún mi, ó sì lẹ̀ mọ́ mi ní ara yíká bí aṣọ ìlekè mi.
By their great force they have become my raiment; they bind me about as the collar of my coat.
19 Ọlọ́run ti mú mi lọ sínú ẹrẹ̀, èmi sì dàbí eruku àti eérú.
He hath cast me into the mire, and I have become like dust and ashes.
20 “Èmi ké pè ọ́ ìwọ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi lóhùn; èmi dìde dúró ìwọ sì wò mí lásán.
I cry unto thee, and thou answerest me not; I stand up, and thou lookest at me.
21 Ìwọ padà di ẹni ìkà sí mi; ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ fi dè mí ní ọ̀nà.
Thou art changed to a cruel one to me; with the strength of thy hand thou pursuest me.
22 Ìwọ gbé mi sókè sí inú ẹ̀fúùfù, ìwọ mú mi fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì sọ mí di asán pátápátá.
Thou liftest me up to the wind; thou causest me to be borne away, and dissolvest my substance.
23 Èmi sá à mọ̀ pé ìwọ yóò mú mi lọ sínú ikú, sí ilé ìpéjọ tí a yàn fún gbogbo alààyè.
For I know that thou wilt bring me to death, and into the house of assemblage for all living.
24 “Bí ó ti wù kí ó rí, ẹnìkan kí yóò ha nawọ́ rẹ̀ nígbà ìṣubú rẹ̀, tàbí kì yóò ké nínú ìparun rẹ̀.
Indeed, no prayer [availeth] when he stretcheth out [his] hand: though they cry when he destroyeth.
25 Èmi kò ha sọkún bí fún ẹni tí ó wà nínú ìṣòro? Ọkàn mi kò ha bàjẹ́ fún tálákà bí?
Did not I weep for him whose days were hard? was not my soul grieved for the needy?
26 Nígbà tí mo fojú ṣọ́nà fún àlàáfíà, ibi sì dé; nígbà tí mo dúró de ìmọ́lẹ̀, òkùnkùn sì dé.
For I expected good, and there came evil; and I waited for light, but there came darkness.
27 Ikùn mí n ru kò sì sinmi, ọjọ́ ìpọ́njú ti dé bá mi.
My bowels well up, and rest not; days of affliction have confronted me.
28 Èmí ń rìn kiri nínú ọ̀fọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú oòrùn; èmi dìde dúró ní àwùjọ mo sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́.
I go about blackened, but not by the sun; I stand up, I cry in the congregation.
29 Èmi ti di arákùnrin ìkookò, èmi di ẹgbẹ́ àwọn ògòǹgò.
I am become a brother to jackals, and a companion of ostriches.
30 Àwọ̀ mi di dúdú ní ara mi; egungun mi sì jórun fún ooru.
My skin is become black [and falleth] off me, and my bones are parched with heat.
31 Ohun èlò orin mi pẹ̀lú sì di ti ọ̀fọ̀, àti ìpè orin mi sì di ohùn àwọn tí ń sọkún.
My harp also is [turned] to mourning, and my pipe into the voice of weepers.