< Job 3 >

1 Ẹ̀yìn èyí ní Jobu yanu, ó sì fi ọjọ́ ìbí rẹ̀ ré
Akyiri no Hiob kasae, na ɔdomee da a wɔwoo no.
2 Jobu sọ, ó sì wí pé,
Ɔkae se,
3 “Kí ọjọ́ tí a bí mi kí ó di ìgbàgbé, àti òru ni, nínú èyí tí a wí pé, ‘A lóyún ọmọkùnrin kan!’
“Ma da a wɔwoo me no nyera, ne anadwo a wɔkae se, ‘Wɔawo ɔbabarima no!’
4 Kí ọjọ́ náà kí ó já si òkùnkùn, kí Ọlọ́run kí ó má ṣe kà á sí láti ọ̀run wá; bẹ́ẹ̀ ni kí ìmọ́lẹ̀ kí ó má ṣe mọ́ sí i.
Saa da no nnuru sum; mma Ɔsoro Nyankopɔn nhwehwɛ akyi kwan; mma hann biara ntɔ ngu so.
5 Kí òkùnkùn àti òjìji ikú fi ṣe ti ara wọn; kí àwọsánmọ̀ kí ó bà lé e; kí ìṣúdudu ọjọ́ kí ó pa láyà.
Ma sum ne owusum nnye no mfa; ma omununkum nkata so; na sum mmunkam ne hann so.
6 Kí òkùnkùn kí ó ṣú bo òru náà biribiri, kí ó má ṣe yọ pẹ̀lú ọjọ́ ọdún náà: kí a má ṣe kà a mọ́ iye ọjọ́ oṣù.
Ma sum kabii nnye saa anadwo no mfa; ma wonyi saa anadwo no mfi asranna so na wɔmmfa nhyɛ ɔsram biara mu.
7 Kí òru náà kí ó yàgàn; kí ohun ayọ̀ kan kí ó má ṣe wọ inú rẹ̀ lọ.
Saa anadwo no nyɛ obonin; mma wɔnnte anigye nteɛmu wɔ mu.
8 Kí àwọn tí í fi ọjọ́ gégùn ún kí o fi gégùn ún, tí wọ́n mura tán láti ru Lefitani sókè.
Ma wɔn a wɔdome nna no nnome saa da no; wɔn a wɔayɛ krado sɛ wɔbɛkanyan dɛnkyɛmmirampɔn no.
9 Kí ìràwọ̀ òwúrọ̀ ọjọ́ rẹ̀ kí ó ṣókùnkùn; kí ó má wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó máa mọ́ sí i, bẹ́ẹ̀ ni kí ó má ṣe rí àfẹ̀mọ́júmọ́
Ma nʼanɔpa nsoromma nnuru sum; na ɔntwɛn adekyee kwa a onhu anɔpawia nsensanee a edi kan no,
10 nítorí tí kò sé ìlẹ̀kùn inú ìyá mi, láti pa ìbànújẹ́ rẹ́ ní ojú mi.
efisɛ anto nea ɔwoo me no awotwaa mu ama wawo me na anka mʼani renhu saa abɛbrɛsɛ yi.
11 “Èéṣe tí èmi kò fi kú láti inú wá, tàbí tí èmi kò kú ní ìgbà tí mo ti inú jáde wá?
“Adɛn nti na manwu awoe hɔ, bere a mifi me na awotwaa mu no?
12 Èéṣe tí orúnkún wá pàdé mi, tàbí ọmú tí èmi yóò mu?
Adɛn nti na nkotodwe gyee me ne nufu sɛ minnum?
13 Ǹjẹ́ nísinsin yìí èmi ìbá ti dùbúlẹ̀ jẹ́ẹ́; èmi ìbá ti sùn, èmi ìbá ti sinmi
Anka sesɛɛ meda hɔ asomdwoe mu; anka mada regye mʼahome
14 pẹ̀lú àwọn ọba àti ìgbìmọ̀ ayé tí wọ́n mọ ilé fún ara wọn wá dùbúlẹ̀ nínú ìsọdahoro.
me ne wiase ahemfo ne fotufo, wɔn a wosisii adan maa wɔn ho na nnɛ yi abubu no,
15 Tàbí pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé tí ó ní wúrà, tí wọ́n sì fi fàdákà kun ilé wọn.
me ne ahenemma a na wɔwɔ sika kɔkɔɔ, wɔn a wɔde dwetɛ hyɛɛ wɔn afi mu ma.
16 Tàbí bí ọlẹ̀ tí a sin, èmi kì bá ti sí: bí ọmọ ìṣunú tí kò rí ìmọ́lẹ̀?
Anaasɛ adɛn nti na wɔansie me sɛ ɔpɔnba, te sɛ akokoaa a wanhu adekyee hann da?
17 Níbẹ̀ ni ẹni búburú ṣíwọ́ ìyọnilẹ́nu, níbẹ̀ ni ẹni àárẹ̀ wà nínú ìsinmi.
Ɛhɔ na amumɔyɛfo gyae basabasayɛ, na abrɛfo nya ahomegye.
18 Níbẹ̀ ni àwọn ìgbèkùn sinmi pọ̀, wọn kò gbóhùn amúnisìn mọ́.
Nneduafo nso nya wɔn ahofadi; na wɔnte nnommumfo wuranom ateɛteɛ bio.
19 Àti èwe àti àgbà wà níbẹ̀, ẹrú sì di òmìnira kúrò lọ́wọ́ olówó rẹ̀.
Nketewa ne akɛse wɔ hɔ, na akoa de ne ho fi ne wura nsam.
20 “Nítorí kí ni a ṣe fi ìmọ́lẹ̀ fún òtòṣì, àti ìyè fún ọlọ́kàn kíkorò,
“Adɛn nti na wɔma mmɔborɔfo hann, na ɔkra mu ahohiahiafo nya nkwa,
21 tí wọ́n dúró de ikú, ṣùgbọ́n òun kò wá, tí wọ́n wá a jù ìṣúra tí a bò mọ́lẹ̀ pamọ́ lọ.
wɔn a wɔn kɔn dɔ owu nanso ɛmma, wɔn a wɔbrɛ hwehwɛ owu sen sɛnea wɔhwehwɛ nnwetɛbona,
22 Ẹni tí ó yọ̀ gidigidi, tí inú wọ́n sì dùn nígbà tí wọ́n wá ibojì òkú rí?
wɔn a anigye ahyɛ wɔn ma na wodu ɔda mu a wodi ahurusi.
23 Kí ni a fi ìmọ́lẹ̀ fún ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ fi ara pamọ́ fún, tí Ọlọ́run sì ṣọgbà dí mọ́ ká?
Adɛn nti na wɔde nkwa ma onipa a ne kwan ahintaw, nea Onyankopɔn aka no ahyɛ mu?
24 Nítorí pé èémí-ẹ̀dùn wà ṣáájú oúnjẹ mi; ìkérora mi sì tú jáde bí omi.
Ahomekokogu adan mʼaduan; na mʼapinisi gu te sɛ nsu.
25 Nítorí pé ohun náà tí mo bẹ̀rù gidigidi ni ó dé bá mi yìí, àti ohun tí mo fòyà rẹ̀ bá mi ó sì ṣubú lù mí.
Nea na misuro no aba me so; nea na ɛbɔ me hu no ato me.
26 Èmi wà láìní àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ní ìsinmi; bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ni ìfàyàbalẹ̀, bí kò ṣe ìdààmú.”
Minni ahotɔ, minni asomdwoe; minni ahomegye na mmom, ɔhaw nko ara.”

< Job 3 >