< Job 3 >

1 Ẹ̀yìn èyí ní Jobu yanu, ó sì fi ọjọ́ ìbí rẹ̀ ré
Potem otworzył Ijob usta swoje, i złorzeczył dniowi swemu.
2 Jobu sọ, ó sì wí pé,
I zawołał Ijob, mówiąc:
3 “Kí ọjọ́ tí a bí mi kí ó di ìgbàgbé, àti òru ni, nínú èyí tí a wí pé, ‘A lóyún ọmọkùnrin kan!’
Bodaj był zginął dzień, któregom się urodził! i noc, w którą rzeczono: Począł się mężczyzna!
4 Kí ọjọ́ náà kí ó já si òkùnkùn, kí Ọlọ́run kí ó má ṣe kà á sí láti ọ̀run wá; bẹ́ẹ̀ ni kí ìmọ́lẹ̀ kí ó má ṣe mọ́ sí i.
Bodaj się był on dzień obrócił w ciemność! By się był o nim nie pytał Bóg z wysokości, i nie był oświecony światłością!
5 Kí òkùnkùn àti òjìji ikú fi ṣe ti ara wọn; kí àwọsánmọ̀ kí ó bà lé e; kí ìṣúdudu ọjọ́ kí ó pa láyà.
Bodaj go była zaćmiła ciemność i cień śmierci! by go był ogarnął obłok, i ustraszyła go gorącość dzienna!
6 Kí òkùnkùn kí ó ṣú bo òru náà biribiri, kí ó má ṣe yọ pẹ̀lú ọjọ́ ọdún náà: kí a má ṣe kà a mọ́ iye ọjọ́ oṣù.
Bodaj była noc onę osiadła ciemność, aby nie szła w liczbę dni rocznych, i w liczbę miesięcy nie przyszła!
7 Kí òru náà kí ó yàgàn; kí ohun ayọ̀ kan kí ó má ṣe wọ inú rẹ̀ lọ.
Bodaj noc ona była samotna, a śpiewania aby nie było w niej!
8 Kí àwọn tí í fi ọjọ́ gégùn ún kí o fi gégùn ún, tí wọ́n mura tán láti ru Lefitani sókè.
Bodaj ją byli przeklęli, którzy przeklinają dzień, którzy są gotowi, wzruszać płacz swój!
9 Kí ìràwọ̀ òwúrọ̀ ọjọ́ rẹ̀ kí ó ṣókùnkùn; kí ó má wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó máa mọ́ sí i, bẹ́ẹ̀ ni kí ó má ṣe rí àfẹ̀mọ́júmọ́
Bodaj się były zaćmiły gwiazdy przy zmierzkaniu jej! a czekając światła, aby się go była nie doczekała, ani nie oglądała zorzy porannej!
10 nítorí tí kò sé ìlẹ̀kùn inú ìyá mi, láti pa ìbànújẹ́ rẹ́ ní ojú mi.
Iż nie zawarła drzwi żywota mego, a nie skryła boleści od oczu moich.
11 “Èéṣe tí èmi kò fi kú láti inú wá, tàbí tí èmi kò kú ní ìgbà tí mo ti inú jáde wá?
Przeczżem w żywocie nie umarł, albo, gdym z żywota wyszedł, czemum nie zginął?
12 Èéṣe tí orúnkún wá pàdé mi, tàbí ọmú tí èmi yóò mu?
Przeczże mię piastowano na kolanach? a przeczżem ssał piersi?
13 Ǹjẹ́ nísinsin yìí èmi ìbá ti dùbúlẹ̀ jẹ́ẹ́; èmi ìbá ti sùn, èmi ìbá ti sinmi
Albowiembym teraz leżał i odpoczywał; spałbym i miałbym pokój,
14 pẹ̀lú àwọn ọba àti ìgbìmọ̀ ayé tí wọ́n mọ ilé fún ara wọn wá dùbúlẹ̀ nínú ìsọdahoro.
Z królmi i z radcami ziemi, którzy sobie budowali na miejscach pustych;
15 Tàbí pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé tí ó ní wúrà, tí wọ́n sì fi fàdákà kun ilé wọn.
Albo z książętami, którzy mieli złoto, a napełniali domy swe srebrem,
16 Tàbí bí ọlẹ̀ tí a sin, èmi kì bá ti sí: bí ọmọ ìṣunú tí kò rí ìmọ́lẹ̀?
Albo czemum się nie stał jako martwy płód skryty? albo jako niemowlątka, które nie oglądały światłości?
17 Níbẹ̀ ni ẹni búburú ṣíwọ́ ìyọnilẹ́nu, níbẹ̀ ni ẹni àárẹ̀ wà nínú ìsinmi.
Tam niepobożni przestawają straszyć, i tam odpoczywają zwątleni w siłę.
18 Níbẹ̀ ni àwọn ìgbèkùn sinmi pọ̀, wọn kò gbóhùn amúnisìn mọ́.
Tamże więźniowie sobie wydychają, a nie słyszą głosu trapiącego ich,
19 Àti èwe àti àgbà wà níbẹ̀, ẹrú sì di òmìnira kúrò lọ́wọ́ olówó rẹ̀.
Mały i wielki tam sobie są równi a niewolnik wolny od pana swego.
20 “Nítorí kí ni a ṣe fi ìmọ́lẹ̀ fún òtòṣì, àti ìyè fún ọlọ́kàn kíkorò,
Przecz nędznemu dana jest światłość, a żywot tym, którzy są utrapionego ducha?
21 tí wọ́n dúró de ikú, ṣùgbọ́n òun kò wá, tí wọ́n wá a jù ìṣúra tí a bò mọ́lẹ̀ pamọ́ lọ.
Którzy czekają śmierci, a nie przychodzi, choć jej pilniej szukają niż skarbów skrytych;
22 Ẹni tí ó yọ̀ gidigidi, tí inú wọ́n sì dùn nígbà tí wọ́n wá ibojì òkú rí?
Którzyby się z radością weselili, pląsając, gdyby znaleźli grób.
23 Kí ni a fi ìmọ́lẹ̀ fún ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ fi ara pamọ́ fún, tí Ọlọ́run sì ṣọgbà dí mọ́ ká?
Przecz dana jest światłość mężowi, którego droga skryta jest, a którego Bóg ciężkościami ogarnął?
24 Nítorí pé èémí-ẹ̀dùn wà ṣáájú oúnjẹ mi; ìkérora mi sì tú jáde bí omi.
Albowiem kiedy mam jeść, wzdychanie moje przychodzi, a rozchodzi się jako woda ryczenie moje;
25 Nítorí pé ohun náà tí mo bẹ̀rù gidigidi ni ó dé bá mi yìí, àti ohun tí mo fòyà rẹ̀ bá mi ó sì ṣubú lù mí.
Bo strach, któregom się lękał, przyszedł na mię, a czegom się obawiał, przydało mi się.
26 Èmi wà láìní àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ní ìsinmi; bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ni ìfàyàbalẹ̀, bí kò ṣe ìdààmú.”
Nie byłem bezpieczny, anim się uspokoił, anim odpoczywał, a przecież na mię przyszła trwoga.

< Job 3 >