< Job 3 >

1 Ẹ̀yìn èyí ní Jobu yanu, ó sì fi ọjọ́ ìbí rẹ̀ ré
Après cela, Job ouvrit la bouche et maudit le jour de sa naissance.
2 Jobu sọ, ó sì wí pé,
Job répondit:
3 “Kí ọjọ́ tí a bí mi kí ó di ìgbàgbé, àti òru ni, nínú èyí tí a wí pé, ‘A lóyún ọmọkùnrin kan!’
« Que périsse le jour où je suis né! la nuit qui a dit: « Un garçon a été conçu.
4 Kí ọjọ́ náà kí ó já si òkùnkùn, kí Ọlọ́run kí ó má ṣe kà á sí láti ọ̀run wá; bẹ́ẹ̀ ni kí ìmọ́lẹ̀ kí ó má ṣe mọ́ sí i.
Que ce jour soit ténèbres. Ne laissez pas le Dieu d'en haut le chercher, ni laisser la lumière l'éclairer.
5 Kí òkùnkùn àti òjìji ikú fi ṣe ti ara wọn; kí àwọsánmọ̀ kí ó bà lé e; kí ìṣúdudu ọjọ́ kí ó pa láyà.
Que les ténèbres et l'ombre de la mort le revendiquent pour eux. Qu'un nuage s'y attarde. Que tout ce qui rend le jour noir le terrifie.
6 Kí òkùnkùn kí ó ṣú bo òru náà biribiri, kí ó má ṣe yọ pẹ̀lú ọjọ́ ọdún náà: kí a má ṣe kà a mọ́ iye ọjọ́ oṣù.
Quant à cette nuit, que d'épaisses ténèbres la saisissent. Qu'il ne se réjouisse pas parmi les jours de l'année. Qu'il n'entre pas dans le nombre des mois.
7 Kí òru náà kí ó yàgàn; kí ohun ayọ̀ kan kí ó má ṣe wọ inú rẹ̀ lọ.
Voici, que cette nuit soit stérile. Qu'aucune voix joyeuse n'y parvienne.
8 Kí àwọn tí í fi ọjọ́ gégùn ún kí o fi gégùn ún, tí wọ́n mura tán láti ru Lefitani sókè.
Qu'ils le maudissent, ceux qui maudissent le jour! qui sont prêts à réveiller le Léviathan.
9 Kí ìràwọ̀ òwúrọ̀ ọjọ́ rẹ̀ kí ó ṣókùnkùn; kí ó má wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó máa mọ́ sí i, bẹ́ẹ̀ ni kí ó má ṣe rí àfẹ̀mọ́júmọ́
Que les étoiles de son crépuscule soient sombres. Qu'il cherche de la lumière, mais n'en a pas, ni ne le laisse voir les paupières du matin,
10 nítorí tí kò sé ìlẹ̀kùn inú ìyá mi, láti pa ìbànújẹ́ rẹ́ ní ojú mi.
parce qu'il n'a pas fermé les portes du ventre de ma mère, et n'a pas caché les problèmes à mes yeux.
11 “Èéṣe tí èmi kò fi kú láti inú wá, tàbí tí èmi kò kú ní ìgbà tí mo ti inú jáde wá?
« Pourquoi ne suis-je pas mort dès le ventre de ma mère? Pourquoi n'ai-je pas renoncé à l'esprit quand ma mère m'a mis au monde?
12 Èéṣe tí orúnkún wá pàdé mi, tàbí ọmú tí èmi yóò mu?
Pourquoi les genoux m'ont-ils reçu? Ou pourquoi le sein, que je devrais allaiter?
13 Ǹjẹ́ nísinsin yìí èmi ìbá ti dùbúlẹ̀ jẹ́ẹ́; èmi ìbá ti sùn, èmi ìbá ti sinmi
Pour l'instant, j'aurais dû me coucher et me taire. J'aurais dû dormir, alors j'aurais été en paix,
14 pẹ̀lú àwọn ọba àti ìgbìmọ̀ ayé tí wọ́n mọ ilé fún ara wọn wá dùbúlẹ̀ nínú ìsọdahoro.
avec les rois et les conseillers de la terre, qui se sont construits des décharges pour eux-mêmes;
15 Tàbí pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé tí ó ní wúrà, tí wọ́n sì fi fàdákà kun ilé wọn.
ou avec des princes qui avaient de l'or, qui ont rempli leurs maisons d'argent;
16 Tàbí bí ọlẹ̀ tí a sin, èmi kì bá ti sí: bí ọmọ ìṣunú tí kò rí ìmọ́lẹ̀?
ou comme une naissance prématurée cachée, je n'avais pas été, comme des enfants qui n'ont jamais vu la lumière.
17 Níbẹ̀ ni ẹni búburú ṣíwọ́ ìyọnilẹ́nu, níbẹ̀ ni ẹni àárẹ̀ wà nínú ìsinmi.
Là, les méchants cessent de s'inquiéter. Les personnes fatiguées y trouvent le repos.
18 Níbẹ̀ ni àwọn ìgbèkùn sinmi pọ̀, wọn kò gbóhùn amúnisìn mọ́.
Là, les prisonniers sont à l'aise ensemble. Ils n'entendent pas la voix du maître d'œuvre.
19 Àti èwe àti àgbà wà níbẹ̀, ẹrú sì di òmìnira kúrò lọ́wọ́ olówó rẹ̀.
Le petit et le grand sont là. Le serviteur est libre de son maître.
20 “Nítorí kí ni a ṣe fi ìmọ́lẹ̀ fún òtòṣì, àti ìyè fún ọlọ́kàn kíkorò,
« Pourquoi la lumière est-elle donnée à celui qui est dans la misère, la vie jusqu'à l'amertume de l'âme,
21 tí wọ́n dúró de ikú, ṣùgbọ́n òun kò wá, tí wọ́n wá a jù ìṣúra tí a bò mọ́lẹ̀ pamọ́ lọ.
qui aspirent à la mort, mais elle ne vient pas; et creuser pour elle plus que pour des trésors cachés,
22 Ẹni tí ó yọ̀ gidigidi, tí inú wọ́n sì dùn nígbà tí wọ́n wá ibojì òkú rí?
qui se réjouissent à l'excès, et sont heureux, quand ils peuvent trouver la tombe?
23 Kí ni a fi ìmọ́lẹ̀ fún ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ fi ara pamọ́ fún, tí Ọlọ́run sì ṣọgbà dí mọ́ ká?
Pourquoi la lumière est-elle donnée à un homme dont le chemin est caché, que Dieu a mis à l'abri?
24 Nítorí pé èémí-ẹ̀dùn wà ṣáájú oúnjẹ mi; ìkérora mi sì tú jáde bí omi.
Car mes soupirs arrivent avant que je mange. Mes gémissements sont déversés comme de l'eau.
25 Nítorí pé ohun náà tí mo bẹ̀rù gidigidi ni ó dé bá mi yìí, àti ohun tí mo fòyà rẹ̀ bá mi ó sì ṣubú lù mí.
Car la chose que je crains vient sur moi, ce dont j'ai peur vient à moi.
26 Èmi wà láìní àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ní ìsinmi; bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ni ìfàyàbalẹ̀, bí kò ṣe ìdààmú.”
Je ne suis pas tranquille, je ne suis pas tranquille, je n'ai pas de repos; mais les problèmes arrivent. »

< Job 3 >