< Job 29 >

1 Pẹ̀lúpẹ̀lú, Jobu sì tún tẹ̀síwájú nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé,
Йов а луат дин ноу кувынтул ын пилде ши а зис:
2 “Háà! ìbá ṣe pé èmi wà bí ìgbà oṣù tí ó kọjá, bí ọjọ́ tí Ọlọ́run pa mí mọ́,
„О, кум ну пот сэ фиу ка ын луниле трекуте, ка ын зилеле кынд мэ пэзя Думнезеу,
3 nígbà tí fìtílà rẹ tàn sí mi ní orí, àti nípa ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ èmi rìn nínú òkùnkùn já.
кынд кандела Луй стрэлучя дясупра капулуй меу ши лумина Луй мэ кэлэузя ын ынтунерик!
4 Bí mo ti rí nígbà ọ̀dọ́ mi, nígbà tí ọ̀rẹ́ Ọlọ́run tímọ́tímọ́ bùkún ilé mi,
Кум ну сунт ка ын зилеле путерий меле, кынд Думнезеу вегя ка ун приетен песте кортул меу,
5 nígbà tí Olódùmarè wà pẹ̀lú mi, nígbà tí àwọn ọmọ mi wà yí mi ká;
кынд Чел Атотпутерник ынкэ ера ку мине ши кынд копиий мей стэтяу ын журул меу;
6 nígbà tí èmi fi òrí-àmọ́ n wẹ ìṣísẹ̀ mi, àti tí àpáta ń tú ìṣàn òróró jáde fún mi wá.
кынд ми се скэлдау паший ын смынтынэ ши стынка вэрса лынгэ мине пырае де унтделемн!
7 “Nígbà tí mo jáde la àárín ìlú lọ sí ẹnu ibodè, nígbà tí mo tẹ́ ìtẹ́ mi ní ìgboro,
Дакэ ешям сэ мэ дук ла поарта четэций ши дакэ ымь прегэтям ун скаун ын пяцэ,
8 nígbà náà ni àwọn ọmọkùnrin rí mi, wọ́n sì sá pamọ́, àwọn àgbà dìde dúró ní ẹsẹ̀ wọn,
тинерий се трэӂяу ынапой ла апропиеря мя, бэтрыний се скулау ши стэтяу ын пичоаре.
9 àwọn ọmọ-aládé dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ, wọn a sì fi ọwọ́ wọn lé ẹnu.
Май-марий ышь опряу кувынтэриле ши ышь пуняу мына ла гурэ.
10 Àwọn ọlọ́lá dákẹ́, ahọ́n wọn sì lẹ̀ mọ́ èrìgì ẹnu wọn.
Гласул кэпетениилор тэчя ши ли се липя лимба де черул гурий.
11 Nígbà tí etí gbọ́, ó sì súre fún mi, àti nígbà tí ojú sì rí mi, ó jẹ́rìí mi,
Урекя каре мэ аузя мэ нумя феричит, окюл каре мэ ведя мэ лэуда.
12 nítorí mo gbà tálákà tí n fẹ́ ìrànlọ́wọ́, àti aláìní baba tí kò sí olùrànlọ́wọ́ fún un.
Кэч скэпам пе сэракул каре черя ажутор ши пе орфанул липсит де сприжин.
13 Ẹni tí ó ń kìlọ̀ súre fún mi, èmi sì mú àyà opó kọrin fún ayọ̀.
Бинекувынтаря ненорочитулуй веня песте мине, умплям де букурие инима вэдувей.
14 Èmi sì mú òdodo wọ̀ bí aṣọ, ẹ̀tọ́ mi dàbí aṣọ ìgúnwà àti adé ọba.
Мэ ымбрэкам ку дрептатя ши-й служям де ымбрэкэминте, неприхэниря ымь ера манта ши турбан.
15 Mo ṣe ojú fún afọ́jú mo sì ṣe ẹsẹ̀ fún amúnkùn ún.
Орбулуй ый ерам окь ши шкьопулуй, пичор.
16 Mo ṣe baba fún tálákà; mo ṣe ìwádìí ọ̀ràn àjèjì tí èmi kò mọ̀ rí.
Челор ненорочиць ле ерам татэ ши черчетам причина челуй некуноскут.
17 Mo sì ká eyín ẹ̀rẹ̀kẹ́ ènìyàn búburú, mo sì já ohun ọdẹ náà kúrò ní eyín rẹ̀.
Рупям фалка челуй недрепт ши-й смулӂям прада дин динць.
18 “Nígbà náà ni mo rò pé, ‘Èmi yóò kú nínú ilé mi, èmi yóò sì mú ọjọ́ mi pọ̀ sí i bí iyanrìn.
Атунч зичям: ‘Ын куйбул меу вой мури, зилеле меле вор фи мулте ка нисипул.
19 Gbòǹgbò mi yóò ta kan omi, ìrì yóò sì sẹ̀ ní gbogbo òru sí ara ẹ̀ka mi.
Апа ва пэтрунде ын рэдэчиниле меле, роуа ва ста тоатэ ноаптя песте рамуриле меле.
20 Ògo mi yóò wà ní ọ̀tún ní ọ̀dọ̀ mi, ọrun mi sì padà di tuntun ní ọwọ́ mi.’
Слава мя ва ынверзи неынчетат ши аркул ымь ва ынтинери ын мынэ.’
21 “Èmi ni ènìyàn ń dẹtí sílẹ̀ sí, wọn a sì dúró, wọn a sì dákẹ́ rọ́rọ́ ní ìmọ̀ràn mi.
Оамений мэ аскултау ши аштептау, тэчяу ынаинтя сфатурилор меле.
22 Lẹ́yìn ọ̀rọ̀ mi, wọn kò tún sọ̀rọ̀ mọ́; ọ̀rọ̀ mi wọ̀ wọ́n ní etí ṣinṣin.
Дупэ кувынтэриле меле, ничунул ну рэспундя ши кувынтул меу ера пентру тоць о роуэ бинефэкэтоаре.
23 Wọn a sì dúró dè mí bí ẹni wí pé wọ́n dúró fún ọ̀wọ́ òjò; wọn a sì mu nínú ọ̀rọ̀ mi bí ẹní mu nínú òjò àrọ̀kúrò.
Мэ аштептау ка пе плоае, кэскау гура ка дупэ плоая де примэварэ.
24 Èmi sì rẹ́rìn-ín sí wọn nígbà tí wọn kò bá gbà á gbọ́; ìmọ́lẹ̀ ojú mi jẹ́ iyebíye sí wọn.
Кынд ли се ынмуя инима, ле зымбям ши ну путяу изгони сенинэтатя де пе фрунтя мя.
25 Mo la ọ̀nà sílẹ̀ fún wọn, mo sì jókòó bí olóyè wọn. Mo jókòó bí ọba ní àárín ológun rẹ, mo sì rí bí ẹni tí ń tu ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú.
Ымь плэчя сэ мэ дук ла ей ши мэ ашезам ын фрунтя лор; ерам ка ун ымпэрат ын мижлокул уней оштирь, ка ун мынгыетор лынгэ ниште ынтристаць.

< Job 29 >