< Job 29 >

1 Pẹ̀lúpẹ̀lú, Jobu sì tún tẹ̀síwájú nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé,
Hiob ciągnął swoją przypowieść i mówił:
2 “Háà! ìbá ṣe pé èmi wà bí ìgbà oṣù tí ó kọjá, bí ọjọ́ tí Ọlọ́run pa mí mọ́,
Obym był taki jak za dawnych miesięcy, za [tych] dni, w których Bóg mnie strzegł;
3 nígbà tí fìtílà rẹ tàn sí mi ní orí, àti nípa ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ èmi rìn nínú òkùnkùn já.
Gdy jego pochodnia świeciła nad moją głową, a przy jego świetle przechodziłem w ciemności;
4 Bí mo ti rí nígbà ọ̀dọ́ mi, nígbà tí ọ̀rẹ́ Ọlọ́run tímọ́tímọ́ bùkún ilé mi,
Taki, jaki byłem za dni swojej młodości, gdy tajemnica Boga pozostawała nad moim namiotem;
5 nígbà tí Olódùmarè wà pẹ̀lú mi, nígbà tí àwọn ọmọ mi wà yí mi ká;
Gdy Wszechmocny był jeszcze ze mną i otaczały mnie moje dzieci;
6 nígbà tí èmi fi òrí-àmọ́ n wẹ ìṣísẹ̀ mi, àti tí àpáta ń tú ìṣàn òróró jáde fún mi wá.
Gdy moje ścieżki opływały w masło, a opoka wylewała mi źródła oliwy;
7 “Nígbà tí mo jáde la àárín ìlú lọ sí ẹnu ibodè, nígbà tí mo tẹ́ ìtẹ́ mi ní ìgboro,
Gdy wychodziłem do bramy przez miasto i na rynku przygotowałem sobie miejsce.
8 nígbà náà ni àwọn ọmọkùnrin rí mi, wọ́n sì sá pamọ́, àwọn àgbà dìde dúró ní ẹsẹ̀ wọn,
Widząc mnie, młodzi ukrywali się, a starcy podnosili się i stali.
9 àwọn ọmọ-aládé dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ, wọn a sì fi ọwọ́ wọn lé ẹnu.
Książęta przestawali mówić i kładli rękę na swoich ustach.
10 Àwọn ọlọ́lá dákẹ́, ahọ́n wọn sì lẹ̀ mọ́ èrìgì ẹnu wọn.
Głos dostojników cichł, a ich język przylegał im do podniebienia.
11 Nígbà tí etí gbọ́, ó sì súre fún mi, àti nígbà tí ojú sì rí mi, ó jẹ́rìí mi,
Ucho, które mnie słyszało, błogosławiło mnie, a oko, które mnie widziało, dawało o mnie świadectwo;
12 nítorí mo gbà tálákà tí n fẹ́ ìrànlọ́wọ́, àti aláìní baba tí kò sí olùrànlọ́wọ́ fún un.
Bo wybawiałem ubogiego, gdy wołał, sierotę oraz tego, który nie miał pomocnika.
13 Ẹni tí ó ń kìlọ̀ súre fún mi, èmi sì mú àyà opó kọrin fún ayọ̀.
Błogosławieństwo ginącego przychodziło do mnie, a serce wdowy radowałem.
14 Èmi sì mú òdodo wọ̀ bí aṣọ, ẹ̀tọ́ mi dàbí aṣọ ìgúnwà àti adé ọba.
Przyoblekłem się w sprawiedliwość i ona mnie okryła. Mój sąd był jak płaszcz i korona.
15 Mo ṣe ojú fún afọ́jú mo sì ṣe ẹsẹ̀ fún amúnkùn ún.
Byłem oczami dla ślepego, a nogami dla chromego.
16 Mo ṣe baba fún tálákà; mo ṣe ìwádìí ọ̀ràn àjèjì tí èmi kò mọ̀ rí.
Byłem ojcem ubogich, a sprawę, której nie znałem, badałem.
17 Mo sì ká eyín ẹ̀rẹ̀kẹ́ ènìyàn búburú, mo sì já ohun ọdẹ náà kúrò ní eyín rẹ̀.
I kruszyłem szczękę niegodziwca, a z jego zębów wydzierałem łup.
18 “Nígbà náà ni mo rò pé, ‘Èmi yóò kú nínú ilé mi, èmi yóò sì mú ọjọ́ mi pọ̀ sí i bí iyanrìn.
Dlatego powiedziałem: Umrę w swoim gnieździe, rozmnożę [swoje] dni jak piasek.
19 Gbòǹgbò mi yóò ta kan omi, ìrì yóò sì sẹ̀ ní gbogbo òru sí ara ẹ̀ka mi.
Mój korzeń rozciągnął się przy wodach, a rosa trwała całą noc na moich gałązkach.
20 Ògo mi yóò wà ní ọ̀tún ní ọ̀dọ̀ mi, ọrun mi sì padà di tuntun ní ọwọ́ mi.’
Moja chwała odświeżała się we mnie, a mój łuk odnowił się w mojej ręce.
21 “Èmi ni ènìyàn ń dẹtí sílẹ̀ sí, wọn a sì dúró, wọn a sì dákẹ́ rọ́rọ́ ní ìmọ̀ràn mi.
Słuchali mnie i oczekiwali, przyjmowali moją radę w milczeniu.
22 Lẹ́yìn ọ̀rọ̀ mi, wọn kò tún sọ̀rọ̀ mọ́; ọ̀rọ̀ mi wọ̀ wọ́n ní etí ṣinṣin.
Po moich słowach już nie mówili, moja mowa kropiła na nich.
23 Wọn a sì dúró dè mí bí ẹni wí pé wọ́n dúró fún ọ̀wọ́ òjò; wọn a sì mu nínú ọ̀rọ̀ mi bí ẹní mu nínú òjò àrọ̀kúrò.
Oczekiwali mnie jak deszczu, otwierali swe usta jak na późny deszcz.
24 Èmi sì rẹ́rìn-ín sí wọn nígbà tí wọn kò bá gbà á gbọ́; ìmọ́lẹ̀ ojú mi jẹ́ iyebíye sí wọn.
[Jeśli] się śmiałem do nich, nie wierzyli, a światła mojej twarzy nie odrzucali.
25 Mo la ọ̀nà sílẹ̀ fún wọn, mo sì jókòó bí olóyè wọn. Mo jókòó bí ọba ní àárín ológun rẹ, mo sì rí bí ẹni tí ń tu ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú.
Wytyczałem im drogę, siadałem na czele i przybywałem jak król wśród wojska, jak [ten], który smutnych pociesza.

< Job 29 >