< Job 29 >

1 Pẹ̀lúpẹ̀lú, Jobu sì tún tẹ̀síwájú nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé,
UJobe wasebuya ephakamisa isaga sakhe wathi:
2 “Háà! ìbá ṣe pé èmi wà bí ìgbà oṣù tí ó kọjá, bí ọjọ́ tí Ọlọ́run pa mí mọ́,
Kungathi ngabe nginjengenyangeni zamandulo, njengensukwini uNkulunkulu angigcine ngazo,
3 nígbà tí fìtílà rẹ tàn sí mi ní orí, àti nípa ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ èmi rìn nínú òkùnkùn já.
lapho isibane sakhe sakhanya phezu kwekhanda lami; ngahamba emnyameni ngokukhanya kwakhe!
4 Bí mo ti rí nígbà ọ̀dọ́ mi, nígbà tí ọ̀rẹ́ Ọlọ́run tímọ́tímọ́ bùkún ilé mi,
Njengoba nganginjalo ensukwini zokuvuthwa kwami, lapho iseluleko sikaNkulunkulu sasiphezu kwethente lami,
5 nígbà tí Olódùmarè wà pẹ̀lú mi, nígbà tí àwọn ọmọ mi wà yí mi ká;
lapho uSomandla wayeseselami, labantwana bami bengiphahlile,
6 nígbà tí èmi fi òrí-àmọ́ n wẹ ìṣísẹ̀ mi, àti tí àpáta ń tú ìṣàn òróró jáde fún mi wá.
lapho ngagezisa izinyathelo zami ngolaza, ledwala langithululela imifula yamafutha!
7 “Nígbà tí mo jáde la àárín ìlú lọ sí ẹnu ibodè, nígbà tí mo tẹ́ ìtẹ́ mi ní ìgboro,
Lapho ngaphuma ngaya esangweni ngidabula umuzi, ngalungisa isihlalo sami emdangeni;
8 nígbà náà ni àwọn ọmọkùnrin rí mi, wọ́n sì sá pamọ́, àwọn àgbà dìde dúró ní ẹsẹ̀ wọn,
amajaha angibona, acatsha; lamaxhegu asukuma ema;
9 àwọn ọmọ-aládé dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ, wọn a sì fi ọwọ́ wọn lé ẹnu.
iziphathamandla zayekela ukukhuluma, zabeka isandla phezu komlomo wazo;
10 Àwọn ọlọ́lá dákẹ́, ahọ́n wọn sì lẹ̀ mọ́ èrìgì ẹnu wọn.
ilizwi labakhulu lacatsha, lolimi lwabo lwanamathela elwangeni lwabo.
11 Nígbà tí etí gbọ́, ó sì súre fún mi, àti nígbà tí ojú sì rí mi, ó jẹ́rìí mi,
Lapho indlebe isizwa yangibusisa, lelihlo libona langifakazela,
12 nítorí mo gbà tálákà tí n fẹ́ ìrànlọ́wọ́, àti aláìní baba tí kò sí olùrànlọ́wọ́ fún un.
ngoba ngakhulula umyanga okhalayo, lentandane, longelamsizi.
13 Ẹni tí ó ń kìlọ̀ súre fún mi, èmi sì mú àyà opó kọrin fún ayọ̀.
Isibusiso sobhubhayo sehlele phezu kwami, njalo ngenza inhliziyo yomfelokazi ihlabele ngentokozo.
14 Èmi sì mú òdodo wọ̀ bí aṣọ, ẹ̀tọ́ mi dàbí aṣọ ìgúnwà àti adé ọba.
Ngembatha ukulunga, kwangembesa; isahlulelo sami saba njengesembatho lomqhele.
15 Mo ṣe ojú fún afọ́jú mo sì ṣe ẹsẹ̀ fún amúnkùn ún.
Ngangingamehlo koyisiphofu, ngangizinyawo kusiqhuli.
16 Mo ṣe baba fún tálákà; mo ṣe ìwádìí ọ̀ràn àjèjì tí èmi kò mọ̀ rí.
Nganginguyise wabayanga, lendaba engingayaziyo ngayihlolisisa.
17 Mo sì ká eyín ẹ̀rẹ̀kẹ́ ènìyàn búburú, mo sì já ohun ọdẹ náà kúrò ní eyín rẹ̀.
Ngasengisephula umhlathi womubi, ngamenza alahle impango emazinyweni akhe.
18 “Nígbà náà ni mo rò pé, ‘Èmi yóò kú nínú ilé mi, èmi yóò sì mú ọjọ́ mi pọ̀ sí i bí iyanrìn.
Ngasengisithi: Ngizaphela lesidleke sami, ngandise insuku njengetshebetshebe.
19 Gbòǹgbò mi yóò ta kan omi, ìrì yóò sì sẹ̀ ní gbogbo òru sí ara ẹ̀ka mi.
Impande zami zinabele emanzini, lamazolo alale ubusuku ogatsheni lwami.
20 Ògo mi yóò wà ní ọ̀tún ní ọ̀dọ̀ mi, ọrun mi sì padà di tuntun ní ọwọ́ mi.’
Udumo lwami lutsha kimi, ledandili lami laguquka esandleni sami.
21 “Èmi ni ènìyàn ń dẹtí sílẹ̀ sí, wọn a sì dúró, wọn a sì dákẹ́ rọ́rọ́ ní ìmọ̀ràn mi.
Bangilalela, belindele, bathulela iseluleko sami.
22 Lẹ́yìn ọ̀rọ̀ mi, wọn kò tún sọ̀rọ̀ mọ́; ọ̀rọ̀ mi wọ̀ wọ́n ní etí ṣinṣin.
Emva kwelizwi lami kabaphendulanga, lelizwi lami lathontela phezu kwabo.
23 Wọn a sì dúró dè mí bí ẹni wí pé wọ́n dúró fún ọ̀wọ́ òjò; wọn a sì mu nínú ọ̀rọ̀ mi bí ẹní mu nínú òjò àrọ̀kúrò.
Bangilindela njengezulu, lomlomo wabo bawukhamisela izulu lokucina.
24 Èmi sì rẹ́rìn-ín sí wọn nígbà tí wọn kò bá gbà á gbọ́; ìmọ́lẹ̀ ojú mi jẹ́ iyebíye sí wọn.
Lapho ngibahlekela, kabakholwanga, lokukhanya kobuso bami kabakuwiselanga phansi.
25 Mo la ọ̀nà sílẹ̀ fún wọn, mo sì jókòó bí olóyè wọn. Mo jókòó bí ọba ní àárín ológun rẹ, mo sì rí bí ẹni tí ń tu ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú.
Ngakhetha indlela yabo ngahlala ngiyinhloko, ngahlala njengenkosi phakathi kweviyo, njengoduduza abalilayo.

< Job 29 >