< Job 29 >
1 Pẹ̀lúpẹ̀lú, Jobu sì tún tẹ̀síwájú nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé,
Jób pedig folytatá az ő beszédét, és monda:
2 “Háà! ìbá ṣe pé èmi wà bí ìgbà oṣù tí ó kọjá, bí ọjọ́ tí Ọlọ́run pa mí mọ́,
Oh, vajha olyan volnék, mint a hajdani hónapokban, a mikor Isten őrzött engem!
3 nígbà tí fìtílà rẹ tàn sí mi ní orí, àti nípa ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ èmi rìn nínú òkùnkùn já.
Mikor az ő szövétneke fénylett fejem fölött, s világánál jártam a setétet;
4 Bí mo ti rí nígbà ọ̀dọ́ mi, nígbà tí ọ̀rẹ́ Ọlọ́run tímọ́tímọ́ bùkún ilé mi,
A mint java-korom napjaiban valék, a mikor Isten gondossága borult sátoromra!
5 nígbà tí Olódùmarè wà pẹ̀lú mi, nígbà tí àwọn ọmọ mi wà yí mi ká;
Mikor még a Mindenható velem volt, és körültem voltak gyermekeim;
6 nígbà tí èmi fi òrí-àmọ́ n wẹ ìṣísẹ̀ mi, àti tí àpáta ń tú ìṣàn òróró jáde fún mi wá.
Mikor lábaimat édes tejben mostam, és mellettem a szikla olajpatakokat ontott;
7 “Nígbà tí mo jáde la àárín ìlú lọ sí ẹnu ibodè, nígbà tí mo tẹ́ ìtẹ́ mi ní ìgboro,
Mikor a kapuhoz mentem, fel a városon; a köztéren székemet fölállítám:
8 nígbà náà ni àwọn ọmọkùnrin rí mi, wọ́n sì sá pamọ́, àwọn àgbà dìde dúró ní ẹsẹ̀ wọn,
Ha megláttak az ifjak, félrevonultak, az öregek is fölkeltek és állottak.
9 àwọn ọmọ-aládé dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ, wọn a sì fi ọwọ́ wọn lé ẹnu.
A fejedelmek abbahagyták a beszédet, és tenyeröket szájukra tették.
10 Àwọn ọlọ́lá dákẹ́, ahọ́n wọn sì lẹ̀ mọ́ èrìgì ẹnu wọn.
A főemberek szava elnémult, és nyelvök az ínyökhöz ragadt.
11 Nígbà tí etí gbọ́, ó sì súre fún mi, àti nígbà tí ojú sì rí mi, ó jẹ́rìí mi,
Mert a mely fül hallott, boldognak mondott engem, és a mely szem látott, bizonyságot tett én felőlem.
12 nítorí mo gbà tálákà tí n fẹ́ ìrànlọ́wọ́, àti aláìní baba tí kò sí olùrànlọ́wọ́ fún un.
Mert megmentém a kiáltozó szegényt, és az árvát, a kinek nem volt segítsége.
13 Ẹni tí ó ń kìlọ̀ súre fún mi, èmi sì mú àyà opó kọrin fún ayọ̀.
A veszni indultnak áldása szállt reám, az özvegynek szívét megörvendeztetém.
14 Èmi sì mú òdodo wọ̀ bí aṣọ, ẹ̀tọ́ mi dàbí aṣọ ìgúnwà àti adé ọba.
Az igazságot magamra öltém és az is magára ölte engem; palást és süveg gyanánt volt az én ítéletem.
15 Mo ṣe ojú fún afọ́jú mo sì ṣe ẹsẹ̀ fún amúnkùn ún.
A vaknak én szeme valék, és a sántának lába.
16 Mo ṣe baba fún tálákà; mo ṣe ìwádìí ọ̀ràn àjèjì tí èmi kò mọ̀ rí.
A szűkölködőknek én atyjok valék, az ismeretlennek ügyét is jól meghányám-vetém.
17 Mo sì ká eyín ẹ̀rẹ̀kẹ́ ènìyàn búburú, mo sì já ohun ọdẹ náà kúrò ní eyín rẹ̀.
Az álnoknak zápfogait kitördösém, és fogai közül a prédát kiütém vala.
18 “Nígbà náà ni mo rò pé, ‘Èmi yóò kú nínú ilé mi, èmi yóò sì mú ọjọ́ mi pọ̀ sí i bí iyanrìn.
Azt gondoltam azért: fészkemmel veszek el, és mint a homok, megsokasodnak napjaim.
19 Gbòǹgbò mi yóò ta kan omi, ìrì yóò sì sẹ̀ ní gbogbo òru sí ara ẹ̀ka mi.
Gyökerem a víznek nyitva lesz, és ágamon hál meg a harmat.
20 Ògo mi yóò wà ní ọ̀tún ní ọ̀dọ̀ mi, ọrun mi sì padà di tuntun ní ọwọ́ mi.’
Dicsőségem megújul velem, és kézívem erősebbé lesz kezemben.
21 “Èmi ni ènìyàn ń dẹtí sílẹ̀ sí, wọn a sì dúró, wọn a sì dákẹ́ rọ́rọ́ ní ìmọ̀ràn mi.
Hallgattak és figyeltek reám, és elnémultak az én tanácsomra.
22 Lẹ́yìn ọ̀rọ̀ mi, wọn kò tún sọ̀rọ̀ mọ́; ọ̀rọ̀ mi wọ̀ wọ́n ní etí ṣinṣin.
Az én szavaim után nem szóltak többet, s harmatként hullt rájok beszédem.
23 Wọn a sì dúró dè mí bí ẹni wí pé wọ́n dúró fún ọ̀wọ́ òjò; wọn a sì mu nínú ọ̀rọ̀ mi bí ẹní mu nínú òjò àrọ̀kúrò.
Mint az esőre, úgy vártak rám, és szájukat tátották, mint tavaszi záporra.
24 Èmi sì rẹ́rìn-ín sí wọn nígbà tí wọn kò bá gbà á gbọ́; ìmọ́lẹ̀ ojú mi jẹ́ iyebíye sí wọn.
Ha rájok mosolyogtam, nem bizakodtak el, és arczom derüjét nem sötétíték be.
25 Mo la ọ̀nà sílẹ̀ fún wọn, mo sì jókòó bí olóyè wọn. Mo jókòó bí ọba ní àárín ológun rẹ, mo sì rí bí ẹni tí ń tu ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú.
Örömest választottam útjokat, mint főember ültem ott; úgy laktam ott, mint király a hadseregben, mint a ki bánkódókat vigasztal.