< Job 29 >

1 Pẹ̀lúpẹ̀lú, Jobu sì tún tẹ̀síwájú nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé,
And Job continued to take up his parable, and said,
2 “Háà! ìbá ṣe pé èmi wà bí ìgbà oṣù tí ó kọjá, bí ọjọ́ tí Ọlọ́run pa mí mọ́,
Who will give me back months like those which are past, days like those when God guarded me;
3 nígbà tí fìtílà rẹ tàn sí mi ní orí, àti nípa ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ èmi rìn nínú òkùnkùn já.
When his lamp shone over my head, when by his light I could walk in darkness;
4 Bí mo ti rí nígbà ọ̀dọ́ mi, nígbà tí ọ̀rẹ́ Ọlọ́run tímọ́tímọ́ bùkún ilé mi,
As I was in the days of my abundance, when the confidence of God was upon my tent:
5 nígbà tí Olódùmarè wà pẹ̀lú mi, nígbà tí àwọn ọmọ mi wà yí mi ká;
When the Almighty was yet with me, when my servants stood round about me;
6 nígbà tí èmi fi òrí-àmọ́ n wẹ ìṣísẹ̀ mi, àti tí àpáta ń tú ìṣàn òróró jáde fún mi wá.
When I bathed my steps in cream, and the rock poured out near me streamlets of oil!
7 “Nígbà tí mo jáde la àárín ìlú lọ sí ẹnu ibodè, nígbà tí mo tẹ́ ìtẹ́ mi ní ìgboro,
When I went out to the gate close by the city, when in the open place I established my seat:
8 nígbà náà ni àwọn ọmọkùnrin rí mi, wọ́n sì sá pamọ́, àwọn àgbà dìde dúró ní ẹsẹ̀ wọn,
Young men saw me, and hid themselves; and the aged rose up, and remained standing;
9 àwọn ọmọ-aládé dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ, wọn a sì fi ọwọ́ wọn lé ẹnu.
Princes stopped in the midst of [their] words, and laid their hand on their mouth:
10 Àwọn ọlọ́lá dákẹ́, ahọ́n wọn sì lẹ̀ mọ́ èrìgì ẹnu wọn.
The voice of nobles was arrested, and their tongue cleaved to their palate.
11 Nígbà tí etí gbọ́, ó sì súre fún mi, àti nígbà tí ojú sì rí mi, ó jẹ́rìí mi,
For the ear that heard me called me happy; and the eye that saw me bore witness for me;
12 nítorí mo gbà tálákà tí n fẹ́ ìrànlọ́wọ́, àti aláìní baba tí kò sí olùrànlọ́wọ́ fún un.
Because I delivered the poor that cried, and the fatherless, yea, that had none to help him.
13 Ẹni tí ó ń kìlọ̀ súre fún mi, èmi sì mú àyà opó kọrin fún ayọ̀.
The blessing of him that was ready to perish came upon me; and the heart of the widow I caused to sing for joy.
14 Èmi sì mú òdodo wọ̀ bí aṣọ, ẹ̀tọ́ mi dàbí aṣọ ìgúnwà àti adé ọba.
I took righteousness as my garment, and it clothed me: as a robe and a mitre was justice unto me.
15 Mo ṣe ojú fún afọ́jú mo sì ṣe ẹsẹ̀ fún amúnkùn ún.
Eyes was I to the blind; and feet to the lame was I.
16 Mo ṣe baba fún tálákà; mo ṣe ìwádìí ọ̀ràn àjèjì tí èmi kò mọ̀ rí.
A father was I to the needy; and the cause of him I knew not I used to investigate.
17 Mo sì ká eyín ẹ̀rẹ̀kẹ́ ènìyàn búburú, mo sì já ohun ọdẹ náà kúrò ní eyín rẹ̀.
And I broke the cutting-teeth of the wrong-doer, and out of his teeth I cast down his prey.
18 “Nígbà náà ni mo rò pé, ‘Èmi yóò kú nínú ilé mi, èmi yóò sì mú ọjọ́ mi pọ̀ sí i bí iyanrìn.
And I said then, “In the midst of my nest shall I depart hence, and like the sand shall I have many days.
19 Gbòǹgbò mi yóò ta kan omi, ìrì yóò sì sẹ̀ ní gbogbo òru sí ara ẹ̀ka mi.
My root will stand open for the water, and the dew will lodge on my boughs.
20 Ògo mi yóò wà ní ọ̀tún ní ọ̀dọ̀ mi, ọrun mi sì padà di tuntun ní ọwọ́ mi.’
My glory will ever be new with me, and my bow will acquire fresh strength in my hand.”
21 “Èmi ni ènìyàn ń dẹtí sílẹ̀ sí, wọn a sì dúró, wọn a sì dákẹ́ rọ́rọ́ ní ìmọ̀ràn mi.
Unto me men listened, and waited, and watched in silence for my counsel
22 Lẹ́yìn ọ̀rọ̀ mi, wọn kò tún sọ̀rọ̀ mọ́; ọ̀rọ̀ mi wọ̀ wọ́n ní etí ṣinṣin.
After my words they made no reply, and my speech dropped on them [like dew].
23 Wọn a sì dúró dè mí bí ẹni wí pé wọ́n dúró fún ọ̀wọ́ òjò; wọn a sì mu nínú ọ̀rọ̀ mi bí ẹní mu nínú òjò àrọ̀kúrò.
And they waited for me as for the rain, and they opened wide their mouth as for the latter rain.
24 Èmi sì rẹ́rìn-ín sí wọn nígbà tí wọn kò bá gbà á gbọ́; ìmọ́lẹ̀ ojú mi jẹ́ iyebíye sí wọn.
I smiled on those that had lost their confidence; and the light of my countenance they never cast down.
25 Mo la ọ̀nà sílẹ̀ fún wọn, mo sì jókòó bí olóyè wọn. Mo jókòó bí ọba ní àárín ológun rẹ, mo sì rí bí ẹni tí ń tu ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú.
I chose their way for them, and I sat as chief, and dwelt as king in his army, as one that comforteth mourners.

< Job 29 >