< Job 29 >
1 Pẹ̀lúpẹ̀lú, Jobu sì tún tẹ̀síwájú nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé,
Og Job blev ved at fremføre sit Billedsprog og sagde:
2 “Háà! ìbá ṣe pé èmi wà bí ìgbà oṣù tí ó kọjá, bí ọjọ́ tí Ọlọ́run pa mí mọ́,
Gid jeg var som i de forrige Maaneder, som i de Dage, da Gud bevarede mig,
3 nígbà tí fìtílà rẹ tàn sí mi ní orí, àti nípa ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ èmi rìn nínú òkùnkùn já.
da hans Lampe lyste over mit Hoved, da jeg gik igennem Mørket ved hans Lys;
4 Bí mo ti rí nígbà ọ̀dọ́ mi, nígbà tí ọ̀rẹ́ Ọlọ́run tímọ́tímọ́ bùkún ilé mi,
som det var med mig i min Høsts Dage, der Guds Fortrolighed var over mit Telt;
5 nígbà tí Olódùmarè wà pẹ̀lú mi, nígbà tí àwọn ọmọ mi wà yí mi ká;
da den Almægtige endnu var med mig, da mine Drenge vare omkring mig;
6 nígbà tí èmi fi òrí-àmọ́ n wẹ ìṣísẹ̀ mi, àti tí àpáta ń tú ìṣàn òróró jáde fún mi wá.
da mine Trin badede sig i Mælk, og Klippen hos mig udgød Oliebække;
7 “Nígbà tí mo jáde la àárín ìlú lọ sí ẹnu ibodè, nígbà tí mo tẹ́ ìtẹ́ mi ní ìgboro,
da jeg gik ud til Porten op til Staden, da jeg lod berede mit Sæde paa Torvet.
8 nígbà náà ni àwọn ọmọkùnrin rí mi, wọ́n sì sá pamọ́, àwọn àgbà dìde dúró ní ẹsẹ̀ wọn,
De unge saa mig og trak sig tilbage, og de gamle stode op og bleve staaende.
9 àwọn ọmọ-aládé dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ, wọn a sì fi ọwọ́ wọn lé ẹnu.
De Øverste holdt op at tale, og de lagde Haanden paa deres Mund.
10 Àwọn ọlọ́lá dákẹ́, ahọ́n wọn sì lẹ̀ mọ́ èrìgì ẹnu wọn.
Fyrsternes Røst forstummede, og deres Tunge hang ved deres Gane.
11 Nígbà tí etí gbọ́, ó sì súre fún mi, àti nígbà tí ojú sì rí mi, ó jẹ́rìí mi,
Thi det Øre, som hørte, priste mig salig, og det Øje, som saa mig, gav mig Vidnesbyrd.
12 nítorí mo gbà tálákà tí n fẹ́ ìrànlọ́wọ́, àti aláìní baba tí kò sí olùrànlọ́wọ́ fún un.
Thi jeg reddede den fattige, som skreg, og den faderløse, som ingen Hjælper havde.
13 Ẹni tí ó ń kìlọ̀ súre fún mi, èmi sì mú àyà opó kọrin fún ayọ̀.
Dens Velsignelse, som ellers maatte omkommet, kom over mig, og jeg frydede Enkens Hjerte.
14 Èmi sì mú òdodo wọ̀ bí aṣọ, ẹ̀tọ́ mi dàbí aṣọ ìgúnwà àti adé ọba.
Jeg iførte mig Retfærdighed, og den klædte sig i mig; min Dom var mig som en Kappe og et Hovedsmykke.
15 Mo ṣe ojú fún afọ́jú mo sì ṣe ẹsẹ̀ fún amúnkùn ún.
Jeg var den blindes Øje, og jeg var den lammes Fod.
16 Mo ṣe baba fún tálákà; mo ṣe ìwádìí ọ̀ràn àjèjì tí èmi kò mọ̀ rí.
Jeg var de fattiges Fader, og den mig ubekendtes Retssag undersøgte jeg.
17 Mo sì ká eyín ẹ̀rẹ̀kẹ́ ènìyàn búburú, mo sì já ohun ọdẹ náà kúrò ní eyín rẹ̀.
Og jeg sønderbrød den uretfærdiges Kindtænder, og jeg gjorde, at han maatte slippe Rovet af sine Tænder.
18 “Nígbà náà ni mo rò pé, ‘Èmi yóò kú nínú ilé mi, èmi yóò sì mú ọjọ́ mi pọ̀ sí i bí iyanrìn.
Og jeg sagde: I min Rede vil jeg opgive Aanden og have Dage mangfoldige som Sand.
19 Gbòǹgbò mi yóò ta kan omi, ìrì yóò sì sẹ̀ ní gbogbo òru sí ara ẹ̀ka mi.
Min Rod skal aabne sig for Vandet, og Duggen skal blive om Natten paa mine Grene.
20 Ògo mi yóò wà ní ọ̀tún ní ọ̀dọ̀ mi, ọrun mi sì padà di tuntun ní ọwọ́ mi.’
Min Herlighed skal blive ny hos mig, og min Bue skal forynges i min Haand.
21 “Èmi ni ènìyàn ń dẹtí sílẹ̀ sí, wọn a sì dúró, wọn a sì dákẹ́ rọ́rọ́ ní ìmọ̀ràn mi.
De hørte paa mig og ventede, og de tav til mit Raad.
22 Lẹ́yìn ọ̀rọ̀ mi, wọn kò tún sọ̀rọ̀ mọ́; ọ̀rọ̀ mi wọ̀ wọ́n ní etí ṣinṣin.
Havde jeg talt, toge de ikke igen til Orde, og min Tale faldt som Draaber over dem;
23 Wọn a sì dúró dè mí bí ẹni wí pé wọ́n dúró fún ọ̀wọ́ òjò; wọn a sì mu nínú ọ̀rọ̀ mi bí ẹní mu nínú òjò àrọ̀kúrò.
de ventede paa mig som paa en Regn, og de aabnede Munden vidt som efter den sildige Regn.
24 Èmi sì rẹ́rìn-ín sí wọn nígbà tí wọn kò bá gbà á gbọ́; ìmọ́lẹ̀ ojú mi jẹ́ iyebíye sí wọn.
Jeg smilte til dem, der vare mistrøstige; og de bragte ikke mit Ansigts Lys til at svinde.
25 Mo la ọ̀nà sílẹ̀ fún wọn, mo sì jókòó bí olóyè wọn. Mo jókòó bí ọba ní àárín ológun rẹ, mo sì rí bí ẹni tí ń tu ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú.
Jeg udvalgte deres Vej og sad øverst, og jeg boede som en Konge iblandt Hærskaren, som den, der trøster de sørgende.