< Job 28 >

1 Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ, àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.
Verdaderamente hay una mina de plata, y un lugar donde el oro es refinado.
2 Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin, bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.
El hierro es sacado de la tierra, y la piedra es convertida en bronce por el fuego.
3 Ènìyàn ni ó fi òpin si òkùnkùn, ó sì ṣe àwárí ìṣúra láti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.
El hombre pone fin a la oscuridad, buscando en el límite más profundo de las piedras, los lugares profundos de la oscuridad.
4 Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jì sí àwọn tí ń gbé òkè, àwọn tí ẹsẹ̀ ènìyàn gbàgbé wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀, wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.
Él hace una mina profunda lejos de aquellos que viven en la luz del día; cuando andan por la tierra, no tienen conocimiento de quienes están debajo de ellos, se secan luego, se van del hombre.
5 Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá, àti ohun tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni ó yí padà bi iná;
En cuanto a la tierra, de ella sale pan; pero debajo de ella se revuelve como por fuego.
6 òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta safire, o sì ní erùpẹ̀ wúrà.
Sus piedras son el lugar de los zafiros, y tiene polvo de oro.
7 Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀, àti ojú gúnnugún kò rí i rí.
Ningún pájaro lo sabe, y el ojo del halcón nunca lo ha visto.
8 Àwọn ẹranko agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.
Las grandes bestias no lo han revisado, y el cruel león no ha tomado ese camino.
9 Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta, ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.
El hombre extiende su mano sobre la roca dura, derribando montañas por las raíces.
10 Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta, ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.
Él hace caminos profundos, corta a través de la roca, y su ojo ve todo lo que tiene valor.
11 Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún àkúnya, ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.
Evita que las corrientes fluyan, y hace que las cosas secretas salgan a la luz.
12 Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí, níbo sì ni òye ń gbe?
Pero, ¿dónde se puede ver la sabiduría? ¿Y dónde está el lugar de descanso del conocimiento?
13 Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
El hombre no ha visto el camino, y no está en la tierra de los vivos.
14 Ọ̀gbun wí pé, “Kò sí nínú mi”; omi òkun sì wí pé, “Kò si nínú mi.”
Las aguas profundas dicen: No está en mí; Y el mar dice: No está conmigo.
15 A kò le è fi wúrà rà á, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òsùwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.
El oro no se puede dar por ello, o un peso de plata en pago por ello.
16 A kò le è fi wúrà Ofiri, tàbí òkúta óníkìsì iyebíye, tàbí òkúta safire díye lé e.
No puede ser valorado con el oro de Ofir, con el ónix de gran precio, o el zafiro.
17 Wúrà àti òkúta kristali kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èlò wúrà ṣe pàṣípàrọ̀ rẹ̀.
No puede evaluarse con oro y el vidrio, y no puede ser cambiado por joyas del mejor oro.
18 A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta jasperi; iye ọgbọ́n sì ju iyùn lọ.
No hay necesidad de decir nada acerca del coral o cristal; y el valor de la sabiduría es mayor que el de las perlas.
19 Òkúta topasi ti Kuṣi kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.
El topacio de Etiopía no es igual a él, y no puede ser valorado con el mejor oro.
20 Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá? Tàbí níbo ni òye ń gbé?
¿De dónde, entonces, viene la sabiduría y dónde está el lugar de descanso del conocimiento?
21 A rí i pé, ó fi ara sinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo, ó sì fi ara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
Porque está oculto a los ojos de todos los vivos, sin ser visto por las aves del aire.
22 Ibi ìparun àti ikú wí pé, àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.
Destrucción y muerte dicen, solo hemos tenido noticias con nuestros oídos.
23 Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀, òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé.
Dios tiene conocimiento del camino hacia la sabiduría y de su lugar;
24 Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé, ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,
Porque sus ojos van a los confines de la tierra, y él ve todo bajo el cielo.
25 láti dà òsùwọ̀n fún afẹ́fẹ́, ó sì fi òsùwọ̀n wọ́n omi.
Cuando fijó un peso para el viento, nivela la amplitud de las aguas;
26 Nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò, tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
Cuando hizo las leyes para la lluvia, y un camino para las truenos y relámpagos;
27 nígbà náà ni ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde; ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.
Entonces vio la sabiduría, y la puso en el registro; Él la estableció, y la escudriño también.
28 Àti fún ènìyàn ni ó wí pé, “Kíyèsi i, ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n, àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.”
Y dijo al hombre: En verdad, el temor del Señor es la sabiduría, y apartarse del mal es el camino a la inteligencia.

< Job 28 >