< Job 28 >

1 Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ, àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.
Doprawdy, istnieją złoża, [z których pochodzi] srebro, i miejsca, [gdzie] złoto się oczyszcza.
2 Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin, bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.
Żelazo się wydobywa z ziemi, a miedź wytapia z kamienia.
3 Ènìyàn ni ó fi òpin si òkùnkùn, ó sì ṣe àwárí ìṣúra láti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.
Kładzie się kres ciemności i przeszukuje się wszystko dokładnie, kamienie [leżące] w ciemności i cieniu śmierci.
4 Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jì sí àwọn tí ń gbé òkè, àwọn tí ẹsẹ̀ ènìyàn gbàgbé wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀, wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.
Rzeka wyleje ze swego miejsca, tak że nie sposób ją przejść, zostaje [jednak] zahamowana przemysłem człowieka i odchodzi.
5 Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá, àti ohun tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni ó yí padà bi iná;
Z ziemi pochodzi chleb, lecz pod nią zamienia się jakby w ogień.
6 òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta safire, o sì ní erùpẹ̀ wúrà.
Jej kamienie zawierają szafiry i piasek złoty;
7 Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀, àti ojú gúnnugún kò rí i rí.
Ścieżki do nich nie zna ptak ani nie widziało jej oko sępa.
8 Àwọn ẹranko agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.
Nie kroczą po niej dzikie zwierzęta ani lew nią nie przeszedł.
9 Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta, ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.
Wyciąga swą rękę po krzemień, wywraca góry od korzenia;
10 Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta, ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.
Ze skał wykuwa strumienie, a jego oko wypatruje każdej kosztownej rzeczy.
11 Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún àkúnya, ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.
Nie pozwala rozlewać się rzekom, a ukryte rzeczy wywodzi [na] światło.
12 Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí, níbo sì ni òye ń gbe?
Ale gdzie można znaleźć mądrość? Gdzie znajduje się miejsce rozumu?
13 Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
Człowiek nie zna jej ceny ani nie można jej znaleźć w ziemi żyjących.
14 Ọ̀gbun wí pé, “Kò sí nínú mi”; omi òkun sì wí pé, “Kò si nínú mi.”
Głębia mówi: Nie ma jej we mnie. Morze powiada: U mnie też jej [nie ma].
15 A kò le è fi wúrà rà á, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òsùwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.
Nie nabywa się jej za szczere złoto ani nie odważa się zapłaty [za] nią w srebrze.
16 A kò le è fi wúrà Ofiri, tàbí òkúta óníkìsì iyebíye, tàbí òkúta safire díye lé e.
Nie można jej wycenić w złocie z Ofiru ani w onyksie drogocennym, ani w szafirze.
17 Wúrà àti òkúta kristali kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èlò wúrà ṣe pàṣípàrọ̀ rẹ̀.
Złoto i kryształ nie dorównają jej, nie można jej wymienić na klejnoty z czystego złota.
18 A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta jasperi; iye ọgbọ́n sì ju iyùn lọ.
Nie [wypada] wspominać o koralach i perłach, bo nabycie mądrości przewyższa perły.
19 Òkúta topasi ti Kuṣi kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.
Nie dorówna jej topaz z Etiopii i nie [można] jej wycenić w szczerym złocie.
20 Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá? Tàbí níbo ni òye ń gbé?
Skąd więc mądrość pochodzi? I gdzie znajduje się miejsce rozumu?
21 A rí i pé, ó fi ara sinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo, ó sì fi ara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
Przecież jest zakryta dla oczu wszystkich żyjących i utajona przed ptactwem niebieskim.
22 Ibi ìparun àti ikú wí pé, àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.
Zniszczenie i śmierć mówią: Własnymi uszami usłyszałyśmy o jej sławie.
23 Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀, òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé.
Bóg rozumie jej drogę, on zna jej miejsce.
24 Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé, ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,
On bowiem patrzy na krańce ziemi i widzi wszystko, co jest pod niebem.
25 láti dà òsùwọ̀n fún afẹ́fẹ́, ó sì fi òsùwọ̀n wọ́n omi.
Określił wagę wiatrom i odważył miarą wody.
26 Nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò, tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
Gdy ustanowił prawo dla deszczu i drogę dla błyskawicy gromu;
27 nígbà náà ni ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde; ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.
Wtedy ją widział i ogłosił; przygotował ją i przebadał.
28 Àti fún ènìyàn ni ó wí pé, “Kíyèsi i, ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n, àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.”
A do człowieka powiedział: Oto bojaźń Pana, ona jest mądrością, a odstąpienie od zła [jest] rozumem.

< Job 28 >