< Job 28 >

1 Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ, àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.
He rua hoki to te hiriwa e puta mai ai, he wahi ano to te koura e whakarewaina ai.
2 Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin, bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.
He mea tango mai te rino no roto i te whenua; no te kamaka te parahi, he mea whakarewa.
3 Ènìyàn ni ó fi òpin si òkùnkùn, ó sì ṣe àwárí ìṣúra láti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.
E whakatakotoria ana e te tangata he mutunga mai mo te pouri, e rapua ana e ia ki te tino tutukitanga atu nga kohatu o te pouri, o te atarangi o te mate.
4 Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jì sí àwọn tí ń gbé òkè, àwọn tí ẹsẹ̀ ènìyàn gbàgbé wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀, wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.
E pakaruhia mai ana e ia he rua i ko ake o nga nohoanga tangata; kua wareware ratou i te waewae e haere ana; he tawhiti i te tangata to ratou tarenga, e piu atu ana, e piu ana mai.
5 Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá, àti ohun tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni ó yí padà bi iná;
Ko te whenua, e puta mai ana he taro i roto i a ia: a e hurihia ake ana a raro iho ano he ahi.
6 òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta safire, o sì ní erùpẹ̀ wúrà.
Hei wahi mo nga hapira ona kohatu, he puehu koura ano tona.
7 Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀, àti ojú gúnnugún kò rí i rí.
He ara tena kahore i mohiotia e te manu, kiano i kitea e te kanohi o te whatura.
8 Àwọn ẹranko agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.
Kahore nga kirehe whakahi kia takahi i taua ara kahore hoki a reira kia haerea e te raiona tutu.
9 Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta, ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.
E pa atu ana tona ringa ki te kiripaka; hurihia ake e ia nga take o nga maunga.
10 Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta, ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.
E tapahia ana e ia he awa i roto i nga kamaka, a e kite ana tona kanohi i nga mea utu nui katoa.
11 Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún àkúnya, ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.
E herea ana e ia nga awa kei maturuturu; e whakaputa mai ana hoki i nga mea ngaro ki te marama.
12 Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí, níbo sì ni òye ń gbe?
E kitea ia ki hea te whakaaro nui? kei hea hoki te wahi o te mohio?
13 Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
E kore te tangata e mohio ki tona utu, e kore ano taua hanga e kitea ki te whenua o te ora.
14 Ọ̀gbun wí pé, “Kò sí nínú mi”; omi òkun sì wí pé, “Kò si nínú mi.”
E ki ake ana te rire, Kahore i ahau; e ki mai ana hoki te moana, Kahore i ahau.
15 A kò le è fi wúrà rà á, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òsùwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.
E kore e hokona ki te koura, e kore ano hoki e taea te pauna te hiriwa hei utu mona.
16 A kò le è fi wúrà Ofiri, tàbí òkúta óníkìsì iyebíye, tàbí òkúta safire díye lé e.
E kore e taea te whakarite ki te koura o Opira, ki te onika utu nui, ki te hapira.
17 Wúrà àti òkúta kristali kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èlò wúrà ṣe pàṣípàrọ̀ rẹ̀.
E kore e rite te koura, te kohatu piata ki a ia: e kore e hokona ki nga oko koura parakore.
18 A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta jasperi; iye ọgbọ́n sì ju iyùn lọ.
E kore e whakahuatia te kaoa, nga peara ranei; hira ake hoki te utu o te whakaaro nui i to te rupi.
19 Òkúta topasi ti Kuṣi kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.
E kore te topaha o Etiopia e rite ki a ia, e kore e tau te koura parakore hei utu.
20 Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá? Tàbí níbo ni òye ń gbé?
Ka haere mai ra i hea te whakaaro nui? Kei hea te wahi o te matau?
21 A rí i pé, ó fi ara sinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo, ó sì fi ara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
He mea huna atu na hoki i nga kanohi o nga mea ora katoa, ngaro rawa i nga manu o te rangi.
22 Ibi ìparun àti ikú wí pé, àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.
E ki ake ana te whakangaromanga raua ko te mate, i hakiri o maua taringa ki tona rongo.
23 Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀, òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé.
E mohio ana te Atua ki tona ara, kua kite ano ia i tona wahi.
24 Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé, ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,
E titiro ana hoki ia ki nga pito o te whenua, e kite ana ia i nga mea i raro i te rangi, a puta noa;
25 láti dà òsùwọ̀n fún afẹ́fẹ́, ó sì fi òsùwọ̀n wọ́n omi.
E mea ana i te whakataimaha mo te hau; ae, e mehua ana ia i nga wai ki te mehua.
26 Nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò, tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
I a ia e whakatakoto ana i te tikanga mo te ua, i te huarahi mo te uira o te whatitiri,
27 nígbà náà ni ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde; ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.
Ka kitea e ia i reira, a whakapuakina mai ana; i whakaukia e ia, a ata rapua ana e ia.
28 Àti fún ènìyàn ni ó wí pé, “Kíyèsi i, ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n, àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.”
A ka mea ia ki te tangata, Na, ko te wehi ki te Ariki, ko te whakaaro nui tena; a ko te mawehe atu i te kino, koia te matauranga.

< Job 28 >