< Job 28 >
1 Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ, àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.
Bizony az ezüstnek bányája van, és helye az aranynak, a hol tisztítják.
2 Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin, bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.
A vasat a földből hozzák elő, a követ pedig érczczé olvasztják.
3 Ènìyàn ni ó fi òpin si òkùnkùn, ó sì ṣe àwárí ìṣúra láti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.
Határt vet az ember a setétségnek, és átkutatja egészen és végig a homálynak és a halál árnyékának kövét.
4 Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jì sí àwọn tí ń gbé òkè, àwọn tí ẹsẹ̀ ènìyàn gbàgbé wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀, wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.
Aknát tör távol a lakóktól: mintha lábukról is megfelejtkeznének, alámerülnek és lebegnek emberektől messze.
5 Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá, àti ohun tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni ó yí padà bi iná;
Van föld, a melyből kenyér terem, alant pedig fel van forgatva, mintegy tűz által;
6 òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta safire, o sì ní erùpẹ̀ wúrà.
Köveiben zafir található, göröngyeiben arany van.
7 Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀, àti ojú gúnnugún kò rí i rí.
Van ösvény, a melyet nem ismer a sas, sem a sólyom szeme nem látja azt.
8 Àwọn ẹranko agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.
Nem tudják azt büszke vadak, az oroszlán sem lépked azon.
9 Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta, ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.
Ráveti kezét az ember a kovakőre, a hegyeket tövükből kiforgatja.
10 Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta, ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.
A sziklákban tárnákat hasít, és minden drága dolgot meglát a szeme.
11 Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún àkúnya, ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.
Elköti a folyók szivárgását, az elrejtett dolgot pedig világosságra hozza.
12 Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí, níbo sì ni òye ń gbe?
De a bölcseség hol található, és az értelemnek hol van a helye?
13 Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
Halandó a hozzá vivő utat nem ismeri, az élők földén az nem található.
14 Ọ̀gbun wí pé, “Kò sí nínú mi”; omi òkun sì wí pé, “Kò si nínú mi.”
A mélység azt mondja: Nincsen az bennem; a tenger azt mondja: én nálam sincsen.
15 A kò le è fi wúrà rà á, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òsùwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.
Színaranyért meg nem szerezhető, ára ezüsttel meg nem fizethető.
16 A kò le è fi wúrà Ofiri, tàbí òkúta óníkìsì iyebíye, tàbí òkúta safire díye lé e.
Nem mérhető össze Ofir aranyával, nem drága onikszszal, sem zafirral.
17 Wúrà àti òkúta kristali kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èlò wúrà ṣe pàṣípàrọ̀ rẹ̀.
Nem ér fel vele az arany és gyémánt, aranyedényekért be nem cserélhető.
18 A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta jasperi; iye ọgbọ́n sì ju iyùn lọ.
Korall és kristály említni sem való; a bölcseség ára drágább a gyöngyöknél.
19 Òkúta topasi ti Kuṣi kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.
Nem ér fel vele Kúsnak topáza, színaranynyal sem mérhető össze.
20 Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá? Tàbí níbo ni òye ń gbé?
A bölcseség honnan jő tehát, és hol van helye az értelemnek?
21 A rí i pé, ó fi ara sinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo, ó sì fi ara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
Rejtve van az minden élő szemei előtt, az ég madarai elől is fedve van.
22 Ibi ìparun àti ikú wí pé, àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.
A pokol és halál azt mondják: Csak hírét hallottuk füleinkkel! ()
23 Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀, òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé.
Isten tudja annak útját, ő ismeri annak helyét.
24 Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé, ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,
Mert ő ellát a föld határira, ő lát mindent az ég alatt.
25 láti dà òsùwọ̀n fún afẹ́fẹ́, ó sì fi òsùwọ̀n wọ́n omi.
Mikor a szélnek súlyt szerzett, és a vizeket mértékre vette;
26 Nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò, tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
Mikor az esőnek határt szabott, és mennydörgő villámoknak útat:
27 nígbà náà ni ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde; ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.
Akkor látta és kijelentette azt, megalapította és meg is vizsgálta azt.
28 Àti fún ènìyàn ni ó wí pé, “Kíyèsi i, ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n, àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.”
Az embernek pedig mondá: Ímé az Úrnak félelme: az a bölcseség, és az értelem: a gonosztól való eltávozás.