< Job 28 >

1 Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ, àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.
Surely there is a vein for the silver, and a place for gold [where] they fine [it].
2 Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin, bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.
Iron is taken out of the earth, and brass [is] melted [out of] the stone.
3 Ènìyàn ni ó fi òpin si òkùnkùn, ó sì ṣe àwárí ìṣúra láti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.
He setteth an end to darkness, and searcheth out all perfection: the stones of darkness, and the shades of death.
4 Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jì sí àwọn tí ń gbé òkè, àwọn tí ẹsẹ̀ ènìyàn gbàgbé wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀, wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.
The flood breaketh out from the inhabitant: [even the waters] forgotten by the foot: they are dried up, they have gone away from men.
5 Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá, àti ohun tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni ó yí padà bi iná;
[As for] the earth, out of it cometh bread: and under it is turned up as it were fire.
6 òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta safire, o sì ní erùpẹ̀ wúrà.
The stones of it [are] the place of sapphires: and it hath dust of gold.
7 Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀, àti ojú gúnnugún kò rí i rí.
[There is] a path which no fowl knoweth, and which the vultur's eye hath not seen:
8 Àwọn ẹranko agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.
The lion's whelps have not trodden it, nor the fierce lion passed by it.
9 Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta, ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.
He putteth forth his hand upon the rock; he overturneth the mountains by the roots.
10 Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta, ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.
He cutteth out rivers among the rocks; and his eye seeth every precious thing.
11 Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún àkúnya, ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.
He bindeth the floods from overflowing; and [the thing that is] hid he bringeth forth to light.
12 Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí, níbo sì ni òye ń gbe?
But where shall wisdom be found? and where [is] the place of understanding?
13 Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
Man knoweth not the price of it; neither is it found in the land of the living.
14 Ọ̀gbun wí pé, “Kò sí nínú mi”; omi òkun sì wí pé, “Kò si nínú mi.”
The depth saith, It [is] not in me: and the sea saith, [It is] not with me.
15 A kò le è fi wúrà rà á, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òsùwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.
It cannot be obtained for gold, neither shall silver be weighed [for] the price of it.
16 A kò le è fi wúrà Ofiri, tàbí òkúta óníkìsì iyebíye, tàbí òkúta safire díye lé e.
It cannot be valued with the gold of Ophir, with the precious onyx, or the sapphire.
17 Wúrà àti òkúta kristali kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èlò wúrà ṣe pàṣípàrọ̀ rẹ̀.
The gold and the crystal cannot equal it: and the exchange of it [shall not be for] jewels of fine gold.
18 A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta jasperi; iye ọgbọ́n sì ju iyùn lọ.
No mention shall be made of coral, or of pearls: for the price of wisdom [is] above rubies.
19 Òkúta topasi ti Kuṣi kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.
The topaz of Cush shall not equal it, neither shall it be valued with pure gold.
20 Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá? Tàbí níbo ni òye ń gbé?
Whence then cometh wisdom? and where [is] the place of understanding?
21 A rí i pé, ó fi ara sinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo, ó sì fi ara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
Seeing it is hid from the eyes of all living, and kept close from the fowls of the air.
22 Ibi ìparun àti ikú wí pé, àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.
Destruction and death say, We have heard the fame of it with our ears.
23 Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀, òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé.
God understandeth the way of it, and he knoweth its place.
24 Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé, ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,
For he looketh to the ends of the earth, [and] seeth under the whole heaven;
25 láti dà òsùwọ̀n fún afẹ́fẹ́, ó sì fi òsùwọ̀n wọ́n omi.
To make the weight for the winds; and he weigheth the waters by measure.
26 Nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò, tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
When he made a decree for the rain, and a way for the lightning of the thunder:
27 nígbà náà ni ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde; ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.
Then did he see it, and declare it; he prepared it, yea, and searched it out.
28 Àti fún ènìyàn ni ó wí pé, “Kíyèsi i, ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n, àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.”
And to man he said, Behold, the fear of the LORD, that [is] wisdom; and to depart from evil [is] understanding.

< Job 28 >