< Job 27 >

1 Pẹ̀lúpẹ̀lú Jobu sì tún sọkún ọ̀rọ̀ òwe rẹ̀, ó sì wí pé,
Hiob ciągnął dalej swoją odpowiedź:
2 “Bí Ọlọ́run ti ń bẹ, ẹni tí ó gba ìdájọ́ mi lọ, àti Olódùmarè tí ó bà mi ní ọkàn jẹ́,
Jak żyje Bóg, [który] odrzucił mój sąd, i Wszechmocny, [który] rozgoryczył moją duszę;
3 níwọ́n ìgbà tí ẹ̀mí mi ń bẹ nínú mi, àti tí ẹ̀mí Ọlọ́run ń bẹ nínú ihò imú mi.
Dopóki jest we mnie tchnienie i duch Boży w moich nozdrzach;
4 Ètè mi kì yóò sọ̀rọ̀ èké, bẹ́ẹ̀ ni ahọ́n mi kì yóò sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
Moje wargi nie będą mówiły niegodziwości, a mój język nie wypowie fałszu.
5 Kí a má rí i pé èmi ń dá yín láre; títí èmi ó fi kú, èmi kì yóò ṣí ìwà òtítọ́ mi kúrò lọ́dọ̀ mi.
Nie daj Boże, abym miał was usprawiedliwiać; do śmierci nie odstąpię od swej niewinności.
6 Òdodo mi ni èmi dìímú ṣinṣin, èmi kì yóò sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́; àyà mi kì yóò sì gan ọjọ́ kan nínú ọjọ́ ayé mi.
Będę trzymał się swojej sprawiedliwości i nie puszczę jej; moje serce nie oskarży mnie, póki żyję.
7 “Kí ọ̀tá mi kí ó dàbí ènìyàn búburú, àti ẹni tí ń dìde sí mi kí ó dàbí ẹni aláìṣòdodo.
Niech mój wróg będzie jak niegodziwiec, a ten, który powstaje przeciwko mnie, jak niesprawiedliwy.
8 Nítorí kí ni ìrètí àgàbàgebè, nígbà tí Ọlọ́run bá ké ẹ̀mí rẹ̀ kúrò, nígbà tí ó sì fà á jáde?
Jaka bowiem jest nadzieja obłudnika, choćby zysk osiągnął, gdy Bóg zabiera mu duszę?
9 Ọlọ́run yóò ha gbọ́ àdúrà rẹ̀, nígbà tí ìpọ́njú bá dé sí i?
Czy Bóg usłyszy jego wołanie, gdy spadnie na niego nieszczęście?
10 Òun ha le ní inú dídùn sí Olódùmarè? Òun ha lé máa ké pe Ọlọ́run nígbà gbogbo?
Czy będzie się rozkoszować Wszechmocnym? Czy będzie wciąż wzywał Boga?
11 “Èmi ó kọ́ yín ní ẹ̀kọ́ ní ti ọwọ́ Ọlọ́run: ọ̀nà tí ń bẹ lọ́dọ̀ Olódùmarè ni èmi kì yóò fi pamọ́.
Pouczę was, [będąc] w ręce Boga, nie zataję niczego o Wszechmocnym.
12 Kíyèsi i, gbogbo yín ni ó ti rí i; kín ni ìdí ọ̀rọ̀ asán yín?
Oto wy wszyscy [to] widzicie; po co więc te próżne słowa?
13 “Ẹ̀yin ni ìpín ènìyàn búburú lọ́dọ̀ Ọlọ́run, àti ogún àwọn aninilára, tí wọ́n ó gbà lọ́wọ́ Olódùmarè.
Taki jest dział niegodziwca u Boga i takie dziedzictwo, które otrzymają od Wszechmocnego ciemięzcy.
14 Bí àwọn ọmọ rẹ bá di púpọ̀, fún idà ni; àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ kì yóò yó fún oúnjẹ.
Jeśli rozmnożą się jego synowie, [pójdą] pod miecz; a jego potomstwo nie nasyci się chlebem.
15 Àwọn tí ó kù nínú tirẹ̀ ni a ó sìnkú nínú àjàkálẹ̀-ààrùn: àwọn opó rẹ̀ kì yóò sì sọkún fún wọn.
Ci, którzy po nim pozostaną, będą pogrzebani w śmierci, a jego wdowy nie będą [go] opłakiwały;
16 Bí ó tilẹ̀ kó fàdákà jọ bí erùpẹ̀, tí ó sì dá aṣọ jọ bí amọ̀;
Choćby nagromadził srebra jak prochu i przygotował sobie szat jak gliny;
17 àwọn ohun tí ó tò jọ àwọn olóòtítọ́ ni yóò lò ó; àwọn aláìṣẹ̀ ni yóò sì pín fàdákà rẹ̀.
To choć je przygotuje, włoży je sprawiedliwy, a niewinny będzie dzielić srebro.
18 Òun kọ́ ilé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí kòkòrò aṣọ, àti bí ahéré tí olùṣọ́ kọ́.
Zbuduje swój dom jak mól, jak szałas, który stawia stróż.
19 Ọlọ́rọ̀ yóò dùbúlẹ̀, ṣùgbọ́n òun kì yóò túnṣe bẹ́ẹ̀ mọ́, nígbà tí ó bá la ojú rẹ̀, gbogbo rẹ̀ a lọ.
Bogaty zaśnie, a nie będzie pogrzebany; otworzy oczy, ale [już] go nie ma.
20 Ẹ̀rù ńlá bà á bí omi ṣíṣàn; ẹ̀fúùfù ńlá jí gbé lọ ní òru.
Ogarnie go strach jak wody, w nocy porwie go wicher.
21 Ẹ̀fúùfù ìlà-oòrùn gbé e lọ, òun sì lọ; àti bí ìjì ńlá ó sì fà á kúrò ní ipò rẹ̀.
Uniesie go wiatr wschodni, a odejdzie; bo wicher wyrwie go z jego miejsca.
22 Nítorí pé Olódùmarè yóò kọlù ú, kì yóò sì dá sí; òun ìbá yọ̀ láti sá kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
To bowiem [Bóg] rzuci na niego i nie oszczędzi [go], choć bardzo chciał uciekać przed jego ręką.
23 Àwọn ènìyàn yóò sì ṣápẹ́ sí i lórí, wọn yóò sì ṣe síọ̀ sí i kúrò ní ipò rẹ̀.”
Będą klaskać nad nim w dłonie i wygwizdywać go z jego miejsca.

< Job 27 >