< Job 25 >
1 Nígbà náà ní Bilidadi, ará Ṣuhi, dáhùn wí pé,
Então respondeu Bildad o suhita, e disse:
2 “Ìjọba àti ẹ̀rù ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀, òun ní i ṣe ìlàjà ní ibi gíga gíga ọ̀run.
Com ele estão domínio e temor; ele faz paz nas suas alturas.
3 Àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ha ní ìyè bí, tàbí ara ta ni ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ kò tàn sí?
Porventura tem número as suas tropas? e sobre quem não surge a sua luz?
4 Èéha ti ṣe tí a ó fi dá ènìyàn láre lọ́dọ̀ Ọlọ́run? Tàbí ẹni tí a bí láti inú obìnrin wá yóò ha ṣe mọ́?
Como pois seria justo o homem para com Deus? e como seria puro aquele que nasce da mulher?
5 Kíyèsi i, òṣùpá kò sì lè tàn ìmọ́lẹ̀, àní àwọn ìràwọ̀ kò mọ́lẹ̀ ní ojú rẹ̀,
Olha, até a lua não resplandece, e as estrelas não são puras aos seus olhos.
6 kí a má sọ ènìyàn tí i ṣe ìdin, àti ọmọ ènìyàn tí í ṣe kòkòrò!”
E quanto menos o homem, que é um verme, e o filho do homem, que é um bicho.