< Job 25 >
1 Nígbà náà ní Bilidadi, ará Ṣuhi, dáhùn wí pé,
そこでシュヒびとビルダデは答えて言った、
2 “Ìjọba àti ẹ̀rù ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀, òun ní i ṣe ìlàjà ní ibi gíga gíga ọ̀run.
「大権と恐れとは神と共にある。彼は高き所で平和を施される。
3 Àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ha ní ìyè bí, tàbí ara ta ni ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ kò tàn sí?
その軍勢は数えることができるか。何物かその光に浴さないものがあるか。
4 Èéha ti ṣe tí a ó fi dá ènìyàn láre lọ́dọ̀ Ọlọ́run? Tàbí ẹni tí a bí láti inú obìnrin wá yóò ha ṣe mọ́?
それで人はどうして神の前に正しくありえようか。女から生れた者がどうして清くありえようか。
5 Kíyèsi i, òṣùpá kò sì lè tàn ìmọ́lẹ̀, àní àwọn ìràwọ̀ kò mọ́lẹ̀ ní ojú rẹ̀,
見よ、月さえも輝かず、星も彼の目には清くない。
6 kí a má sọ ènìyàn tí i ṣe ìdin, àti ọmọ ènìyàn tí í ṣe kòkòrò!”
うじのような人、虫のような人の子はなおさらである」。