< Job 25 >
1 Nígbà náà ní Bilidadi, ará Ṣuhi, dáhùn wí pé,
Bildad de Chouha prit la parole et dit:
2 “Ìjọba àti ẹ̀rù ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀, òun ní i ṣe ìlàjà ní ibi gíga gíga ọ̀run.
A lui appartiennent l’empire et la redoutable puissance; IL établit la paix dans ses demeures sublimes.
3 Àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ha ní ìyè bí, tàbí ara ta ni ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ kò tàn sí?
Ses milices peuvent-elles se compter? Sur qui ne se lève pas sa lumière?
4 Èéha ti ṣe tí a ó fi dá ènìyàn láre lọ́dọ̀ Ọlọ́run? Tàbí ẹni tí a bí láti inú obìnrin wá yóò ha ṣe mọ́?
Comment donc le mortel serait-il juste devant Dieu? Comment le fils de la femme serait-il innocent?
5 Kíyèsi i, òṣùpá kò sì lè tàn ìmọ́lẹ̀, àní àwọn ìràwọ̀ kò mọ́lẹ̀ ní ojú rẹ̀,
Eh quoi! L’Éclat de la lune elle-même se ternit, et les étoiles ne sont pas sans tache à ses yeux.
6 kí a má sọ ènìyàn tí i ṣe ìdin, àti ọmọ ènìyàn tí í ṣe kòkòrò!”
A plus forte raison en est-il ainsi du mortel qui n’est que pourriture, du fils d’Adam qui n’est qu’un vermisseau!