< Job 25 >

1 Nígbà náà ní Bilidadi, ará Ṣuhi, dáhùn wí pé,
Et Bildad, le Shuhite, prit la parole,
2 “Ìjọba àti ẹ̀rù ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀, òun ní i ṣe ìlàjà ní ibi gíga gíga ọ̀run.
« La domination et la crainte sont avec lui. Il fait la paix dans ses hauts lieux.
3 Àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ha ní ìyè bí, tàbí ara ta ni ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ kò tàn sí?
Peut-on compter ses armées? Sur qui sa lumière ne se lève-t-elle pas?
4 Èéha ti ṣe tí a ó fi dá ènìyàn láre lọ́dọ̀ Ọlọ́run? Tàbí ẹni tí a bí láti inú obìnrin wá yóò ha ṣe mọ́?
Comment donc l'homme peut-il être juste avec Dieu? Ou comment celui qui est né d'une femme peut-il être pur?
5 Kíyèsi i, òṣùpá kò sì lè tàn ìmọ́lẹ̀, àní àwọn ìràwọ̀ kò mọ́lẹ̀ ní ojú rẹ̀,
Voici, même la lune n'a pas d'éclat, et les étoiles ne sont pas pures à ses yeux;
6 kí a má sọ ènìyàn tí i ṣe ìdin, àti ọmọ ènìyàn tí í ṣe kòkòrò!”
Combien moins l'homme, qui est un ver, et le fils de l'homme, qui est un ver! »

< Job 25 >