< Job 22 >

1 Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé,
Alors Éliphaz, le Thémanite, prit la parole,
2 “Ènìyàn lè è ṣe rere fún Ọlọ́run? Bí ọlọ́gbọ́n ti í ṣe rere fún ara rẹ̀?
« Un homme peut-il être utile à Dieu? Certes, celui qui est sage est profitable à lui-même.
3 Ohun ayọ̀ ha ni fún Olódùmarè pé olódodo ni ìwọ? Tàbí èrè kí ni fún un ti ìwọ mú ọ̀nà rẹ̀ pé?
Est-ce un plaisir pour le Tout-Puissant que vous soyez justes? Ou est-ce que ça lui profite que vous rendiez vos voies parfaites?
4 “Yóò ha bá ọ wí bí, nítorí ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ? Yóò ha bá ọ lọ sínú ìdájọ́ bí?
Est-ce pour votre piété qu'il vous réprimande, qu'il entre avec vous dans le jugement?
5 Ìwà búburú rẹ kò ha tóbi, àti ẹ̀ṣẹ̀ rẹ láìníye?
Votre méchanceté n'est-elle pas grande? Il n'y a pas non plus de fin à vos iniquités.
6 Nítòótọ́ ìwọ béèrè fún ààbò ni ọwọ́ arákùnrin rẹ láìnídìí, ìwọ sì tú oníhòhò ní aṣọ wọn.
Car tu as pris des gages de ton frère pour rien, et ont dépouillé les nus de leurs vêtements.
7 Ìwọ kò fi omi fún aláàárẹ̀ mu, ìwọ sì háwọ́ oúnjẹ fún ẹni tí ebi ń pa.
Vous n'avez pas donné d'eau à boire à ceux qui sont fatigués, et vous avez refusé du pain aux affamés.
8 Bí ó ṣe ti alágbára nì, òun ni ó ní ilẹ̀, ọlọ́lá sì tẹ̀dó sínú rẹ̀.
Mais le puissant, lui, avait la terre. L'homme honorable, il y a vécu.
9 Ìwọ ti rán àwọn opó padà lọ ní ọwọ́ òfo, apá àwọn ọmọ aláìní baba ti di ṣiṣẹ́.
Tu as renvoyé les veuves à vide, et les bras de l'orphelin ont été brisés.
10 Nítorí náà ni ìdẹ̀kùn ṣe yí ọ káàkiri, àti ìbẹ̀rù òjijì ń yọ ọ́ lẹ́nu.
C'est pourquoi il y a des pièges autour de toi. Une peur soudaine vous trouble,
11 Èéṣe tí òkùnkùn fi pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ kò fi lè ríran. Èéṣe tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi sì bò ọ́ mọ́lẹ̀.
ou l'obscurité, de sorte que vous ne pouvez pas voir, et des flots d'eaux te couvrent.
12 “Ọlọ́run kò ha jẹ́ ẹni gíga ọ̀run? Sá wo orí àwọn ìràwọ̀ bí wọ́n ti ga tó!
« Dieu n'est-il pas dans les hauteurs du ciel? Voyez la hauteur des étoiles, comme elles sont hautes!
13 Ìwọ sì wí pé, Ọlọ́run ti ṣe mọ̀? Òun ha lè ṣe ìdájọ́ láti inú òkùnkùn wá bí?
Vous dites: « Que sait Dieu? Peut-il juger à travers l'obscurité épaisse?
14 Ǹjẹ́ àwọsánmọ̀ tí ó nípọn jẹ ìbora fún un, tí kò fi lè ríran; ó sì ń rìn nínú àyíká ọ̀run.
Des nuages épais le couvrent, de sorte qu'il ne voit pas. Il marche sur la voûte du ciel.
15 Ǹjẹ́ ìwọ fẹ́ rin ipa ọ̀nà ìgbàanì tí àwọn ènìyàn búburú tí rìn?
Garderez-vous l'ancienne manière, que les hommes méchants ont foulés,
16 A ké wọn lulẹ̀ kúrò nínú ayé láìpé ọjọ́ wọn, ìpìlẹ̀ wọn ti da bí odò ṣíṣàn.
qui ont été enlevés avant leur heure, dont le fondement a été déversé comme un torrent,
17 Àwọn ẹni tí ó wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa! Kí ni Olódùmarè yóò ṣe fún wọn?’
qui ont dit à Dieu: « Eloigne-toi de nous ». et « Que peut faire le Tout-Puissant pour nous? ».
18 Síbẹ̀ ó fi ohun rere kún ilé wọn! Ṣùgbọ́n ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi!
Pourtant, il a rempli leurs maisons de bonnes choses, mais le conseil des méchants est loin de moi.
19 Àwọn olódodo rí ìparun wọn, wọ́n sì yọ̀, àwọn aláìlẹ́ṣẹ̀ sì fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà pé,
Les justes le voient et se réjouissent. Les innocents les ridiculisent,
20 ‘Lóòtítọ́ àwọn ọ̀tá wa ni a ké kúrò, iná yóò sì jó oró wọn run.’
en disant: « Ceux qui se sont élevés contre nous ont été exterminés. Le feu a consumé leur reste.
21 “Fa ara rẹ súnmọ́ Ọlọ́run, ìwọ ó sì rí àlàáfíà; nípa èyí ni rere yóò wá bá ọ.
« Fais connaissance avec lui maintenant, et sois en paix. Par elle, le bien viendra à toi.
22 Èmi bẹ̀ ọ́, gba òfin láti ẹnu rẹ̀ wá, kí o sì to ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí àyà rẹ.
Veuillez recevoir l'instruction de sa bouche, et déposez ses paroles dans votre cœur.
23 Bí ìwọ bá yípadà sọ́dọ̀ Olódùmarè, a sì gbé ọ ró. Bí ìwọ bá sì mú ẹ̀ṣẹ̀ jìnnà réré kúrò nínú àgọ́ rẹ,
Si vous revenez au Tout-Puissant, vous serez édifiés, si vous éloignez l'iniquité loin de vos tentes.
24 tí ìwọ bá tẹ́ wúrà dáradára sílẹ̀, lórí erùpẹ̀ àti wúrà Ofiri lábẹ́ òkúta odò,
Dépose ton trésor dans la poussière, l'or d'Ophir parmi les pierres des ruisseaux.
25 nígbà náà ní Olódùmarè yóò jẹ́ wúrà rẹ, àní yóò sì jẹ́ fàdákà fún ọ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Le Tout-Puissant sera ton trésor, et de l'argent précieux pour vous.
26 Lóòtítọ́ nígbà náà ní ìwọ ó ní inú dídùn nínú Olódùmarè, ìwọ ó sì gbé ojú rẹ sókè sọ́dọ̀ Ọlọ́run.
Car alors tu te complairas dans le Tout-Puissant, et tu lèveras ton visage vers Dieu.
27 Bí ìwọ bá gbàdúrà rẹ sọ́dọ̀ rẹ̀, yóò sì gbọ́ tìrẹ, ìwọ ó sì san ẹ̀jẹ́ rẹ.
Tu le prieras, et il t'écoutera. Tu paieras tes vœux.
28 Ìwọ ó sì gbìmọ̀ ohun kan pẹ̀lú, yóò sì fi ìdí múlẹ̀ fún ọ; ìmọ́lẹ̀ yóò sì mọ́ sípa ọ̀nà rẹ.
Tu décréteras aussi une chose, et elle sera établie pour toi. La lumière brillera sur vos chemins.
29 Nígbà tí ipa ọ̀nà rẹ bá lọ sísàlẹ̀, nígbà náà ni ìwọ o wí pé, ‘Ìgbésókè ń bẹ!’ Ọlọ́run yóò sì gba onírẹ̀lẹ̀ là!
Lorsqu'ils s'abaisseront, tu diras: « Relève-toi ». Il sauvera l'humble personne.
30 Yóò gba ẹni tí kì í ṣe aláìjẹ̀bi là, a ó sì gbà á nípa mímọ́ ọwọ́ rẹ̀.”
Ildélivrera même celui qui n'est pas innocent. Oui, il sera délivré par la propreté de vos mains. »

< Job 22 >