< Job 22 >

1 Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé,
Then Eliphaz replied,
2 “Ènìyàn lè è ṣe rere fún Ọlọ́run? Bí ọlọ́gbọ́n ti í ṣe rere fún ara rẹ̀?
“(Can anyone be useful to God?/Certainly no one can be useful to God.) [RHQ] Even people who are wise cannot be helpful to God.
3 Ohun ayọ̀ ha ni fún Olódùmarè pé olódodo ni ìwọ? Tàbí èrè kí ni fún un ti ìwọ mú ọ̀nà rẹ̀ pé?
If you were righteous, (would that benefit Almighty [God]?/that certainly would not benefit Almighty [God].) [RHQ] If you had (lived a perfect life/never done anything that is wrong), would that help him?
4 “Yóò ha bá ọ wí bí, nítorí ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ? Yóò ha bá ọ lọ sínú ìdájọ́ bí?
“Is it because you have an awesome respect for God that he punishes you? Is that the reason that he puts you on trial?
5 Ìwà búburú rẹ kò ha tóbi, àti ẹ̀ṣẹ̀ rẹ láìníye?
No, it certainly must be [RHQ] because you are extremely wicked. It must be that the evil things that you have done are so many that no one can count them!
6 Nítòótọ́ ìwọ béèrè fún ààbò ni ọwọ́ arákùnrin rẹ láìnídìí, ìwọ sì tú oníhòhò ní aṣọ wọn.
You must have lent money to others and wrongly forced them to give you things to guarantee that they would pay that money back to you; you must have taken all their clothes and left them with nothing to wear.
7 Ìwọ kò fi omi fún aláàárẹ̀ mu, ìwọ sì háwọ́ oúnjẹ fún ẹni tí ebi ń pa.
You must not have given water to those who were thirsty, and you must have refused to give food to those who were hungry.
8 Bí ó ṣe ti alágbára nì, òun ni ó ní ilẹ̀, ọlọ́lá sì tẹ̀dó sínú rẹ̀.
Because you were very powerful, you [must have] taken over all the people’s land, and then, being very respected, you have begun to live on that land.
9 Ìwọ ti rán àwọn opó padà lọ ní ọwọ́ òfo, apá àwọn ọmọ aláìní baba ti di ṣiṣẹ́.
[When] widows [came to you for help], you [must have] sent [them] away without giving them anything, and you must have oppressed orphans.
10 Nítorí náà ni ìdẹ̀kùn ṣe yí ọ káàkiri, àti ìbẹ̀rù òjijì ń yọ ọ́ lẹ́nu.
Because of all that, now there are pits around you for you to fall into, and suddenly there are things that terrify you and cause you to tremble.
11 Èéṣe tí òkùnkùn fi pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ kò fi lè ríran. Èéṣe tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi sì bò ọ́ mọ́lẹ̀.
[It is as though] it has become very dark, with the result that you cannot see anything, and [it is as though] [MET] a flood covers you.
12 “Ọlọ́run kò ha jẹ́ ẹni gíga ọ̀run? Sá wo orí àwọn ìràwọ̀ bí wọ́n ti ga tó!
“[But consider this, Job]: God lives [RHQ] high up in the heavens. From there he [RHQ] looks down on the highest stars.
13 Ìwọ sì wí pé, Ọlọ́run ti ṣe mọ̀? Òun ha lè ṣe ìdájọ́ láti inú òkùnkùn wá bí?
So why do you say, ‘What does God know [about what we are doing]? [He is hidden from us by] dark clouds, so ([how] can he judge us?/he certainly cannot judge us.) [RHQ]’
14 Ǹjẹ́ àwọsánmọ̀ tí ó nípọn jẹ ìbora fún un, tí kò fi lè ríran; ó sì ń rìn nínú àyíká ọ̀run.
[Do you think that] while he walks on the dome that covers the sky, there are thick clouds around him, with the result that he cannot see [what we do]?
15 Ǹjẹ́ ìwọ fẹ́ rin ipa ọ̀nà ìgbàanì tí àwọn ènìyàn búburú tí rìn?
Will you continue to conduct your life the old way that evil people have done [for many years]?
16 A ké wọn lulẹ̀ kúrò nínú ayé láìpé ọjọ́ wọn, ìpìlẹ̀ wọn ti da bí odò ṣíṣàn.
They suddenly died while they were still young; they disappeared [like everything disappears when there is] a flood [MET].
17 Àwọn ẹni tí ó wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa! Kí ni Olódùmarè yóò ṣe fún wọn?’
They kept saying to God, ‘Do not bother us,’ and they also said [defiantly], ‘Almighty [God] can do nothing [RHQ] to [harm] us!’
18 Síbẹ̀ ó fi ohun rere kún ilé wọn! Ṣùgbọ́n ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi!
But it was God who filled their houses with good things, so I cannot at all understand why wicked people think like they do.
19 Àwọn olódodo rí ìparun wọn, wọ́n sì yọ̀, àwọn aláìlẹ́ṣẹ̀ sì fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà pé,
“But when God punishes wicked people, and righteous people see that, they are glad, and they laugh, ridiculing the wicked people.
20 ‘Lóòtítọ́ àwọn ọ̀tá wa ni a ké kúrò, iná yóò sì jó oró wọn run.’
They say, ‘Now our enemies have been destroyed, and all [their possessions] that were left have been burned in a fire.’
21 “Fa ara rẹ súnmọ́ Ọlọ́run, ìwọ ó sì rí àlàáfíà; nípa èyí ni rere yóò wá bá ọ.
“So, [Job, ] be reconciled to God and make peace with him; if you do that, good things will happen to you.
22 Èmi bẹ̀ ọ́, gba òfin láti ẹnu rẹ̀ wá, kí o sì to ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí àyà rẹ.
Allow him to teach you, and keep thinking about what he has told you.
23 Bí ìwọ bá yípadà sọ́dọ̀ Olódùmarè, a sì gbé ọ ró. Bí ìwọ bá sì mú ẹ̀ṣẹ̀ jìnnà réré kúrò nínú àgọ́ rẹ,
If you humble yourself and return to God, if you stop doing all the evil things that you have been doing in your house,
24 tí ìwọ bá tẹ́ wúrà dáradára sílẹ̀, lórí erùpẹ̀ àti wúrà Ofiri lábẹ́ òkúta odò,
if you throw away your gold, even the fine gold from the dry stream beds in Ophir [land],
25 nígbà náà ní Olódùmarè yóò jẹ́ wúrà rẹ, àní yóò sì jẹ́ fàdákà fún ọ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
and if you allow Almighty [God] to be [as precious to you as] your gold and your silver [have been],
26 Lóòtítọ́ nígbà náà ní ìwọ ó ní inú dídùn nínú Olódùmarè, ìwọ ó sì gbé ojú rẹ sókè sọ́dọ̀ Ọlọ́run.
you will be happy because of your close relationship with God, and you will be able to approach him [IDM] [confidently].
27 Bí ìwọ bá gbàdúrà rẹ sọ́dọ̀ rẹ̀, yóò sì gbọ́ tìrẹ, ìwọ ó sì san ẹ̀jẹ́ rẹ.
You will pray to him, and he will do what you request him to do; you will do the things that you promised him that you would do.
28 Ìwọ ó sì gbìmọ̀ ohun kan pẹ̀lú, yóò sì fi ìdí múlẹ̀ fún ọ; ìmọ́lẹ̀ yóò sì mọ́ sípa ọ̀nà rẹ.
Everything that you decide to do will be successful; [it] will [be as though] a light [is] shining on the road in front of you.
29 Nígbà tí ipa ọ̀nà rẹ bá lọ sísàlẹ̀, nígbà náà ni ìwọ o wí pé, ‘Ìgbésókè ń bẹ!’ Ọlọ́run yóò sì gba onírẹ̀lẹ̀ là!
God humbles those who are proud, but he saves those who are downcast/discouraged.
30 Yóò gba ẹni tí kì í ṣe aláìjẹ̀bi là, a ó sì gbà á nípa mímọ́ ọwọ́ rẹ̀.”
God rescues those who (are innocent/have not done things that are wrong), so he will rescue you if you (start doing things that are right/are not guilty [IDM] of doing things that are wrong).”

< Job 22 >