< Job 21 >

1 Jobu wá dáhùn, ó sì wí pé,
Eyüp şöyle yanıtladı:
2 “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀ dáradára sì àwọn ọ̀rọ̀ mi, kí èyí kí ó jásí ìtùnú fún mi.
“Sözümü dikkatle dinleyin, Bana verdiğiniz avuntu bu olsun.
3 Ẹ jọ̀wọ́ mi ki èmi sọ̀rọ̀; lẹ́yìn ìgbà ìwọ le máa fi mi ṣẹ̀sín ń ṣo.
Bırakın ben de konuşayım, Ben konuştuktan sonra alay edin.
4 “Àròyé mi ha ṣe sí ènìyàn bí? Èétise tí ọkàn mi kì yóò fi ṣe àìbalẹ̀?
“Yakınmam insana mı karşı? Niçin sabırsızlanmayayım?
5 Ẹ wò mí fín, kí ẹnu kí ó sì yà yín, kí ẹ sì fi ọwọ́ lé ẹnu yín.
Bana bakın da şaşın, Elinizi ağzınıza koyun.
6 Àní nígbà tí mo rántí, ẹ̀rù bà mí, ìwárìrì sì mú mi lára.
Bunu düşündükçe içimi korku sarıyor, Bedenimi titreme alıyor.
7 Nítorí kí ní ènìyàn búburú fi wà ní ayé, tí wọ́n gbó, àní tí wọ́n di alágbára ní ipa?
Kötüler niçin yaşıyor, Yaşlandıkça güçleri artıyor?
8 Irú-ọmọ wọn fi ìdí kalẹ̀ ní ojú wọn pẹ̀lú wọn, àti ọmọ ọmọ wọn ní ojú wọn.
Çocukları sapasağlam çevrelerinde, Soyları gözlerinin önünde.
9 Ilé wọn wà láìní ewu àti ẹ̀rù, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá ìbínú Ọlọ́run kò sí lára wọn.
Evleri güvenlik içinde, korkudan uzak, Tanrı'nın sopası onlara dokunmuyor.
10 Akọ màlúù wọn a máa gùn, kì í sì tàsé; abo màlúù wọn a máa bí, kì í sì í ṣẹ́yun.
Boğalarının çiftleşmesi hiç boşa çıkmaz, İnekleri hep doğurur, hiç düşük yapmaz.
11 Wọn a máa rán àwọn ọmọ wọn wẹ́wẹ́ jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa jo kiri.
Çocuklarını sürü gibi salıverirler, Yavruları oynaşır.
12 Wọ́n mú ohun ọ̀nà orin, ìlù àti haapu; wọ́n sì ń yọ̀ sí ohùn fèrè.
Tef ve lir eşliğinde şarkı söyler, Ney sesiyle eğlenirler.
13 Wọ́n n lo ọjọ́ wọn nínú ọrọ̀; wọn sì lọ sí ipò òkú ní àlàáfíà. (Sheol h7585)
Ömürlerini bolluk içinde geçirir, Esenlik içinde ölüler diyarına inerler. (Sheol h7585)
14 Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa!’ Nítorí pé wọn kò fẹ́ ìmọ̀ ipa ọ̀nà rẹ.
Tanrı'ya, ‘Bizden uzak dur!’ derler, ‘Yolunu öğrenmek istemiyoruz.
15 Kí ni Olódùmarè tí àwa ó fi máa sìn in? Èrè kí ni a ó sì jẹ bí àwa ba gbàdúrà sí i?
Her Şeye Gücü Yeten kim ki, O'na kulluk edelim? Ne kazancımız olur O'na dua etsek?’
16 Kíyèsi i, àlàáfíà wọn kò sí nípa ọwọ́ wọn; ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi réré.
Ama zenginlikleri kendi ellerinde değil. Kötülerin öğüdü benden uzak olsun.
17 “Ìgbà mélòó mélòó ní a ń pa fìtílà ènìyàn búburú kú? Ìgbà mélòó mélòó ní ìparun wọn dé bá wọn, tí Ọlọ́run sì í máa pín ìbìnújẹ́ nínú ìbínú rẹ̀?
“Kaç kez kötülerin kandili söndü, Başlarına felaket geldi, Tanrı öfkelendiğinde paylarına düşen kederi verdi?
18 Wọ́n dàbí àgékù koríko níwájú afẹ́fẹ́, àti bí ìyàngbò, tí ẹ̀fúùfù ńlá fẹ́ lọ.
Kaç kez rüzgarın sürüklediği saman gibi, Kasırganın uçurduğu saman çöpü gibi oldular?
19 Ẹ̀yin wí pé, ‘Ọlọ́run to ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jọ fún àwọn ọmọ rẹ̀.’ Jẹ́ kí ó san án fún un, yóò sì mọ̀ ọ́n.
‘Tanrı babaların cezasını çocuklarına çektirir’ diyorsunuz, Kendilerine çektirsin de bilsinler nasıl olduğunu.
20 Ojú rẹ̀ yóò rí ìparun ara rẹ̀, yóò sì máa mu nínú ríru ìbínú Olódùmarè.
Yıkımlarını kendi gözleriyle görsünler, Her Şeye Gücü Yeten'in gazabını içsinler.
21 Nítorí pé àlàáfíà kí ni ó ní nínú ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí a bá ké iye oṣù rẹ̀ kúrò ní agbede-méjì?
Çünkü sayılı ayları sona erince Geride bıraktıkları aileleri için niye kaygı çeksinler?
22 “Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni le kọ Ọlọ́run ní ìmọ̀? Òun ní í sá à ń ṣe ìdájọ́ ẹni ibi gíga.
“En yüksektekileri bile yargılayan Tanrı'ya Kim akıl öğretebilir?
23 Ẹnìkan a kú nínú pípé agbára rẹ̀, ó wà nínú ìrora àti ìdákẹ́ pátápátá.
Biri gücünün doruğunda ölür, Büsbütün rahat ve kaygısız.
24 Ọpọ́n rẹ̀ kún fún omi ọmú, egungun rẹ̀ sì tutù fún ọ̀rá.
Bedeni iyi beslenmiş, İlikleri dolu.
25 Ẹlòmíràn a sì kú nínú kíkorò ọkàn rẹ̀, tí kò sì fi inú dídùn jẹun.
Ötekiyse acı içinde ölür, İyilik nedir hiç tatmamıştır.
26 Wọ́n o dùbúlẹ̀ bákan náà nínú erùpẹ̀, kòkòrò yóò sì ṣùbò wọ́n.
Toprakta birlikte yatarlar, Üzerlerini kurt kaplar.
27 “Kíyèsi i, èmi mọ̀ èrò inú yín àti àrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.
“Bakın, düşüncelerinizi, Bana zarar vermek için kurduğunuz düzenleri biliyorum.
28 Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní ilé ọmọ-aládé, àti níbo ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’
‘Büyük adamın evi nerede?’ diyorsunuz, ‘Kötülerin çadırları nerede?’
29 Ẹ̀yin kò béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ń kọjá lọ ní ọ̀nà? Ẹ̀yin kò mọ̀ àmì wọn,
Yolculara hiç sormadınız mı? Anlattıklarına kulak asmadınız mı?
30 pé ènìyàn búburú ní a fi pamọ́ fún ọjọ́ ìparun. A ó sì mú wọn jáde ní ọjọ́ ríru ìbínú.
Felaket günü kötü insan esirgenir, Gazap günü ona kurtuluş yolu gösterilir.
31 Ta ni yóò tako ipa ọ̀nà rẹ̀ lójúkojú, ta ni yóò sì san án padà fún un ní èyí tí ó ti ṣe?
Kim davranışını onun yüzüne vurur? Kim yaptığının karşılığını ona ödetir?
32 Síbẹ̀ a ó sì sin ín ní ọ̀nà ipò òkú, a ó sì máa ṣọ́ ibojì òkú.
Mezarlığa taşınır, Kabri başında nöbet tutulur.
33 Ògúlùtu àfonífojì yóò dùn mọ́ ọn. Gbogbo ènìyàn yóò sì máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, bí ènìyàn àìníye ti lọ síwájú rẹ̀.
Vadi toprağı tatlı gelir ona, Herkes ardından gider, Önüsıra gidenlerse sayısızdır.
34 “Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin fi ń tù mí nínú lásán, bí ò ṣe pé ní ìdáhùn yín, àrékérekè wa níbẹ̀!”
“Boş laflarla beni nasıl avutursunuz? Yanıtlarınızdan çıkan tek sonuç yalandır.”

< Job 21 >