< Job 21 >

1 Jobu wá dáhùn, ó sì wí pé,
Därefter tog Job till orda och sade:
2 “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀ dáradára sì àwọn ọ̀rọ̀ mi, kí èyí kí ó jásí ìtùnú fún mi.
Hören åtminstone på mina ord; låten det vara den tröst som I given mig.
3 Ẹ jọ̀wọ́ mi ki èmi sọ̀rọ̀; lẹ́yìn ìgbà ìwọ le máa fi mi ṣẹ̀sín ń ṣo.
Haven fördrag med mig, så att jag får tala; sedan jag har talat, må du bespotta.
4 “Àròyé mi ha ṣe sí ènìyàn bí? Èétise tí ọkàn mi kì yóò fi ṣe àìbalẹ̀?
Är då min klagan, såsom när människor eljest klaga? Eller huru skulle jag kunna vara annat än otålig?
5 Ẹ wò mí fín, kí ẹnu kí ó sì yà yín, kí ẹ sì fi ọwọ́ lé ẹnu yín.
Akten på mig, så skolen I häpna och nödgas lägga handen på munnen.
6 Àní nígbà tí mo rántí, ẹ̀rù bà mí, ìwárìrì sì mú mi lára.
Ja, när jag tänker därpå, då förskräckes jag själv, och förfäran griper mitt kött.
7 Nítorí kí ní ènìyàn búburú fi wà ní ayé, tí wọ́n gbó, àní tí wọ́n di alágbára ní ipa?
Varför få de ogudaktiga leva, ja, med åldern växa till i rikedom?
8 Irú-ọmọ wọn fi ìdí kalẹ̀ ní ojú wọn pẹ̀lú wọn, àti ọmọ ọmọ wọn ní ojú wọn.
De se sina barn leva kvar hos sig, och sin avkomma hava de inför sina ögon.
9 Ilé wọn wà láìní ewu àti ẹ̀rù, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá ìbínú Ọlọ́run kò sí lára wọn.
Deras hus stå trygga, ej hemsökta av förskräckelse; Gud låter sitt ris icke komma vid dem.
10 Akọ màlúù wọn a máa gùn, kì í sì tàsé; abo màlúù wọn a máa bí, kì í sì í ṣẹ́yun.
När deras boskap parar sig, är det icke förgäves; lätt kalva deras kor, och icke i otid.
11 Wọn a máa rán àwọn ọmọ wọn wẹ́wẹ́ jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa jo kiri.
Sina barn släppa de ut såsom en hjord, deras piltar hoppa lustigt omkring.
12 Wọ́n mú ohun ọ̀nà orin, ìlù àti haapu; wọ́n sì ń yọ̀ sí ohùn fèrè.
De stämma upp med pukor och harpor, och glädja sig vid pipors ljud.
13 Wọ́n n lo ọjọ́ wọn nínú ọrọ̀; wọn sì lọ sí ipò òkú ní àlàáfíà. (Sheol h7585)
De förnöta sina dagar i lust, och ned till dödsriket fara de i frid. (Sheol h7585)
14 Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa!’ Nítorí pé wọn kò fẹ́ ìmọ̀ ipa ọ̀nà rẹ.
Och de sade dock till Gud: »Vik ifrån oss, dina vägar vilja vi icke veta av.
15 Kí ni Olódùmarè tí àwa ó fi máa sìn in? Èrè kí ni a ó sì jẹ bí àwa ba gbàdúrà sí i?
Vad är den Allsmäktige, att vi skulle tjäna honom? och vad skulle det hjälpa oss att åkalla honom?»
16 Kíyèsi i, àlàáfíà wọn kò sí nípa ọwọ́ wọn; ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi réré.
Det är sant, i deras egen hand står ej deras lycka, och de ogudaktigas rådslag vare fjärran ifrån mig!
17 “Ìgbà mélòó mélòó ní a ń pa fìtílà ènìyàn búburú kú? Ìgbà mélòó mélòó ní ìparun wọn dé bá wọn, tí Ọlọ́run sì í máa pín ìbìnújẹ́ nínú ìbínú rẹ̀?
Men huru ofta utslocknar väl de ogudaktigas lampa, huru ofta händer det att ofärd kommer över dem, och att han tillskiftar dem lotter i vrede?
18 Wọ́n dàbí àgékù koríko níwájú afẹ́fẹ́, àti bí ìyàngbò, tí ẹ̀fúùfù ńlá fẹ́ lọ.
De borde ju bliva såsom halm för vinden, lika agnar som stormen rycker bort.
19 Ẹ̀yin wí pé, ‘Ọlọ́run to ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jọ fún àwọn ọmọ rẹ̀.’ Jẹ́ kí ó san án fún un, yóò sì mọ̀ ọ́n.
»Gud spar åt hans barn att lida för hans ondska.» Ja, men honom själv borde han vedergälla, så att han finge känna det.
20 Ojú rẹ̀ yóò rí ìparun ara rẹ̀, yóò sì máa mu nínú ríru ìbínú Olódùmarè.
Med egna ögon borde han se sitt fall, och av den Allsmäktiges vrede borde han få dricka.
21 Nítorí pé àlàáfíà kí ni ó ní nínú ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí a bá ké iye oṣù rẹ̀ kúrò ní agbede-méjì?
Ty vad frågar han efter sitt hus, när han själv är borta, när hans månaders antal har nått sin ände?
22 “Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni le kọ Ọlọ́run ní ìmọ̀? Òun ní í sá à ń ṣe ìdájọ́ ẹni ibi gíga.
»Skall man då lära Gud förstånd, honom som dömer över de högsta?»
23 Ẹnìkan a kú nínú pípé agbára rẹ̀, ó wà nínú ìrora àti ìdákẹ́ pátápátá.
Ja, den ene får dö i sin välmaktstid, där han sitter i allsköns frid och ro;
24 Ọpọ́n rẹ̀ kún fún omi ọmú, egungun rẹ̀ sì tutù fún ọ̀rá.
hans stävor hava fått stå fulla med mjölk, och märgen i hans ben har bevarat sin saft.
25 Ẹlòmíràn a sì kú nínú kíkorò ọkàn rẹ̀, tí kò sì fi inú dídùn jẹun.
Den andre måste dö med bedrövad själ, och aldrig fick han njuta av någon lycka.
26 Wọ́n o dùbúlẹ̀ bákan náà nínú erùpẹ̀, kòkòrò yóò sì ṣùbò wọ́n.
Tillsammans ligga de så i stoftet, och förruttnelsens maskar övertäcka dem.
27 “Kíyèsi i, èmi mọ̀ èrò inú yín àti àrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.
Se, jag känner väl edra tankar och de funder med vilka I viljen nedslå mig.
28 Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní ilé ọmọ-aládé, àti níbo ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’
I spörjen ju: »Vad har blivit av de höga herrarnas hus, av hyddorna när de ogudaktiga bodde?»
29 Ẹ̀yin kò béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ń kọjá lọ ní ọ̀nà? Ẹ̀yin kò mọ̀ àmì wọn,
Haven I då ej frågat dem som vida foro, och akten I ej på deras vittnesbörd:
30 pé ènìyàn búburú ní a fi pamọ́ fún ọjọ́ ìparun. A ó sì mú wọn jáde ní ọjọ́ ríru ìbínú.
att den onde bliver sparad på ofärdens dag och bärgad undan på vredens dag?
31 Ta ni yóò tako ipa ọ̀nà rẹ̀ lójúkojú, ta ni yóò sì san án padà fún un ní èyí tí ó ti ṣe?
Vem vågar ens förehålla en sådan hans väg? Vem vedergäller honom, vad han än må göra?
32 Síbẹ̀ a ó sì sin ín ní ọ̀nà ipò òkú, a ó sì máa ṣọ́ ibojì òkú.
Och när han har blivit bortförd till graven, så vakar man sedan där vid kullen.
33 Ògúlùtu àfonífojì yóò dùn mọ́ ọn. Gbogbo ènìyàn yóò sì máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, bí ènìyàn àìníye ti lọ síwájú rẹ̀.
Ljuvligt får han vilja under dalens torvor. I hans spår drager hela världen fram; före honom har och otaliga gått.
34 “Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin fi ń tù mí nínú lásán, bí ò ṣe pé ní ìdáhùn yín, àrékérekè wa níbẹ̀!”
Huru kunnen I då bjuda mig så fåfänglig tröst? Av edra svar står allenast trolösheten kvar.

< Job 21 >