< Job 21 >

1 Jobu wá dáhùn, ó sì wí pé,
Job svarade och sade:
2 “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀ dáradára sì àwọn ọ̀rọ̀ mi, kí èyí kí ó jásí ìtùnú fún mi.
Hörer dock till min ord, och låter säga eder;
3 Ẹ jọ̀wọ́ mi ki èmi sọ̀rọ̀; lẹ́yìn ìgbà ìwọ le máa fi mi ṣẹ̀sín ń ṣo.
Hafver tålamod med mig, att jag ock må tala; och görer sedan spott af mig.
4 “Àròyé mi ha ṣe sí ènìyàn bí? Èétise tí ọkàn mi kì yóò fi ṣe àìbalẹ̀?
Månn jag handla med en mennisko, att min ande icke skulle härutinnan ångse varda?
5 Ẹ wò mí fín, kí ẹnu kí ó sì yà yín, kí ẹ sì fi ọwọ́ lé ẹnu yín.
Vänder eder hit till mig; I skolen förundra eder, och måsten lägga handena på munnen.
6 Àní nígbà tí mo rántí, ẹ̀rù bà mí, ìwárìrì sì mú mi lára.
När jag tänker deruppå, så förskräckes jag; och ett bäfvande kommer uppå mitt kött.
7 Nítorí kí ní ènìyàn búburú fi wà ní ayé, tí wọ́n gbó, àní tí wọ́n di alágbára ní ipa?
Hvi lefva då de ogudaktige, varda gamle, och växa till i ägodelar?
8 Irú-ọmọ wọn fi ìdí kalẹ̀ ní ojú wọn pẹ̀lú wọn, àti ọmọ ọmọ wọn ní ojú wọn.
Deras säd är säker omkring dem, och deras afföda är när dem.
9 Ilé wọn wà láìní ewu àti ẹ̀rù, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá ìbínú Ọlọ́run kò sí lára wọn.
Deras hus hafver frid för räddhåga, och Guds ris är icke öfver dem.
10 Akọ màlúù wọn a máa gùn, kì í sì tàsé; abo màlúù wọn a máa bí, kì í sì í ṣẹ́yun.
Deras oxa släpper man till, ock missgår icke; deras ko kalfvar, och är icke ofruktsam.
11 Wọn a máa rán àwọn ọmọ wọn wẹ́wẹ́ jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa jo kiri.
Deras unga barn gå ut såsom en hjord, och deras barn springa.
12 Wọ́n mú ohun ọ̀nà orin, ìlù àti haapu; wọ́n sì ń yọ̀ sí ohùn fèrè.
De fröjda sig med trummor och harpor, och äro glade med pipande;
13 Wọ́n n lo ọjọ́ wọn nínú ọrọ̀; wọn sì lọ sí ipò òkú ní àlàáfíà. (Sheol h7585)
De varda gamle med göda dagar, och förskräckas som nogast ett ögnablick för helvetet; (Sheol h7585)
14 Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa!’ Nítorí pé wọn kò fẹ́ ìmọ̀ ipa ọ̀nà rẹ.
De dock säga till Gud: Gack bort ifrån oss; vi vilje intet veta af dina vägar;
15 Kí ni Olódùmarè tí àwa ó fi máa sìn in? Èrè kí ni a ó sì jẹ bí àwa ba gbàdúrà sí i?
Ho är den Allsmägtige, att vi honom tjena skole? Eller hvad kan det båta oss, om vi löpe emot honom?
16 Kíyèsi i, àlàáfíà wọn kò sí nípa ọwọ́ wọn; ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi réré.
Men si, deras ägodelar stå icke uti deras händer; derföre skall de ogudaktigas sinne vara långt ifrå mig.
17 “Ìgbà mélòó mélòó ní a ń pa fìtílà ènìyàn búburú kú? Ìgbà mélòó mélòó ní ìparun wọn dé bá wọn, tí Ọlọ́run sì í máa pín ìbìnújẹ́ nínú ìbínú rẹ̀?
Huru varder de ogudaktigas lykta utsläckt; och deras förderf kommer öfver dem? Han skall utskifta jämmer i sine vrede.
18 Wọ́n dàbí àgékù koríko níwájú afẹ́fẹ́, àti bí ìyàngbò, tí ẹ̀fúùfù ńlá fẹ́ lọ.
De skola varda såsom strå för vädret, och såsom agnar, hvilka stormen bortförer.
19 Ẹ̀yin wí pé, ‘Ọlọ́run to ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jọ fún àwọn ọmọ rẹ̀.’ Jẹ́ kí ó san án fún un, yóò sì mọ̀ ọ́n.
Gud förvarar hans barnom bedröfvelse; när han skall löna honom, då skall man förnimmat,
20 Ojú rẹ̀ yóò rí ìparun ara rẹ̀, yóò sì máa mu nínú ríru ìbínú Olódùmarè.
Hans ögon skola se hans förderf, och af dens Allsmägtigas vrede skall han dricka.
21 Nítorí pé àlàáfíà kí ni ó ní nínú ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí a bá ké iye oṣù rẹ̀ kúrò ní agbede-méjì?
Ty ho skall hafva behag till hans hus efter honom? Och hans månaders tal skall näppliga halft blifva.
22 “Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni le kọ Ọlọ́run ní ìmọ̀? Òun ní í sá à ń ṣe ìdájọ́ ẹni ibi gíga.
Ho vill lära Gud, den ock dömer de höga?
23 Ẹnìkan a kú nínú pípé agbára rẹ̀, ó wà nínú ìrora àti ìdákẹ́ pátápátá.
Denne dör frisk och helbregda, rik och säll.
24 Ọpọ́n rẹ̀ kún fún omi ọmú, egungun rẹ̀ sì tutù fún ọ̀rá.
Hans mjölkekar äro full med mjölk, och hans ben varda full med märg.
25 Ẹlòmíràn a sì kú nínú kíkorò ọkàn rẹ̀, tí kò sì fi inú dídùn jẹun.
Men en annan dör med bedröfvada själ, och hafver aldrig ätit i glädje.
26 Wọ́n o dùbúlẹ̀ bákan náà nínú erùpẹ̀, kòkòrò yóò sì ṣùbò wọ́n.
Och de ligga tillhopa med hvarannan i jordene, och matkar öfvertäcka dem.
27 “Kíyèsi i, èmi mọ̀ èrò inú yín àti àrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.
Si, jag känner väl edra tankar, och edor vrånga anslag emot mig.
28 Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní ilé ọmọ-aládé, àti níbo ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’
Ty I sägen: Hvar är Förstans hus? Och hvar äro hyddorna, der de ogudaktige bodde?
29 Ẹ̀yin kò béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ń kọjá lọ ní ọ̀nà? Ẹ̀yin kò mọ̀ àmì wọn,
Talen I dock derom såsom meniga folket; och veten icke hvad de andras väsende betyder?
30 pé ènìyàn búburú ní a fi pamọ́ fún ọjọ́ ìparun. A ó sì mú wọn jáde ní ọjọ́ ríru ìbínú.
Ty den onde varder behållen intill förderfvelsens dag, och intill vredenes dag blifver han.
31 Ta ni yóò tako ipa ọ̀nà rẹ̀ lójúkojú, ta ni yóò sì san án padà fún un ní èyí tí ó ti ṣe?
Ho vill säga hvad han förtjenar, när man det utvärtes anser? Ho vill vedergälla honom hvad han gör?
32 Síbẹ̀ a ó sì sin ín ní ọ̀nà ipò òkú, a ó sì máa ṣọ́ ibojì òkú.
Men han varder bortdragen till grafvena, och man vaktar efter honom i högomen.
33 Ògúlùtu àfonífojì yóò dùn mọ́ ọn. Gbogbo ènìyàn yóò sì máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, bí ènìyàn àìníye ti lọ síwájú rẹ̀.
Bäckaslem behagar honom väl, och alla menniskor varda dragna efter honom; och uppå dem, som för honom varit hafva, är intet tal.
34 “Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin fi ń tù mí nínú lásán, bí ò ṣe pé ní ìdáhùn yín, àrékérekè wa níbẹ̀!”
Huru trösten I mig så fåfängt, och edor svar finnas dock orätt?

< Job 21 >