< Job 21 >

1 Jobu wá dáhùn, ó sì wí pé,
UJobe wasephendula wathi:
2 “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀ dáradára sì àwọn ọ̀rọ̀ mi, kí èyí kí ó jásí ìtùnú fún mi.
“Lalelani kuhle amazwi ami; lokhu akube yinduduzo elingipha yona.
3 Ẹ jọ̀wọ́ mi ki èmi sọ̀rọ̀; lẹ́yìn ìgbà ìwọ le máa fi mi ṣẹ̀sín ń ṣo.
Ake lingibekezelele nxa ngisakhuluma, ngithi nxa sengikhulumile liklolode.
4 “Àròyé mi ha ṣe sí ènìyàn bí? Èétise tí ọkàn mi kì yóò fi ṣe àìbalẹ̀?
Ukusola kwami kuqonde umuntu yini? Ngingayekelelani ukucunuka pho?
5 Ẹ wò mí fín, kí ẹnu kí ó sì yà yín, kí ẹ sì fi ọwọ́ lé ẹnu yín.
Ngikhangelani, lizamangala; vulani imilomo yenu ngezandla.
6 Àní nígbà tí mo rántí, ẹ̀rù bà mí, ìwárìrì sì mú mi lára.
Nxa ngikhumbula ngalokhu ngitshaywa luvalo; ngizwa umzimba wami uqhaqhazela.
7 Nítorí kí ní ènìyàn búburú fi wà ní ayé, tí wọ́n gbó, àní tí wọ́n di alágbára ní ipa?
Kungani ababi bephila impilo ende, baluphale nje amandla abo esanda?
8 Irú-ọmọ wọn fi ìdí kalẹ̀ ní ojú wọn pẹ̀lú wọn, àti ọmọ ọmọ wọn ní ojú wọn.
Babona abantwababo bezinza benamile, inzalo yabo layo beyikhangele.
9 Ilé wọn wà láìní ewu àti ẹ̀rù, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá ìbínú Ọlọ́run kò sí lára wọn.
Imizi yabo ihlezi kayilakwesaba; induku kaNkulunkulu kayikho phezu kwabo.
10 Akọ màlúù wọn a máa gùn, kì í sì tàsé; abo màlúù wọn a máa bí, kì í sì í ṣẹ́yun.
Inkunzi zabo zikhuthele ziyazala; amankomokazi abo azala kuhle kawaphunzi.
11 Wọn a máa rán àwọn ọmọ wọn wẹ́wẹ́ jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa jo kiri.
Abantwababo bayazihambela njengomhlambi; izingane zabo ziyazigidela zichelesile.
12 Wọ́n mú ohun ọ̀nà orin, ìlù àti haapu; wọ́n sì ń yọ̀ sí ohùn fèrè.
Bayahlabela betshaya izigubhu lamachacho; bayazithokozisa ngomsindo wemiqangala.
13 Wọ́n n lo ọjọ́ wọn nínú ọrọ̀; wọn sì lọ sí ipò òkú ní àlàáfíà. (Sheol h7585)
Yonke iminyaka yabo ngeyokuphumelela baze bayongena egodini belokuthula. (Sheol h7585)
14 Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa!’ Nítorí pé wọn kò fẹ́ ìmọ̀ ipa ọ̀nà rẹ.
Kodwa bathi kuNkulunkulu, ‘Tshiyana lathi! Kasifisi ukuzazi izindlela zakho.
15 Kí ni Olódùmarè tí àwa ó fi máa sìn in? Èrè kí ni a ó sì jẹ bí àwa ba gbàdúrà sí i?
Ungubani yena uSomandla ofuna ukuthi simkhonze na? Sizazuzani nxa sikhuleka kuye na?’
16 Kíyèsi i, àlàáfíà wọn kò sí nípa ọwọ́ wọn; ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi réré.
Kodwa ukuphumelela kwabo kakukho ezandleni zabo, ngakho kangisondeli ezelulekweni zababi.
17 “Ìgbà mélòó mélòó ní a ń pa fìtílà ènìyàn búburú kú? Ìgbà mélòó mélòó ní ìparun wọn dé bá wọn, tí Ọlọ́run sì í máa pín ìbìnújẹ́ nínú ìbínú rẹ̀?
Kodwa kukangaki na isibane sababi sicinywa? Kukangaki besehlelwa ngamabhadi na, abawabelwa nguNkulunkulu ezondile?
18 Wọ́n dàbí àgékù koríko níwájú afẹ́fẹ́, àti bí ìyàngbò, tí ẹ̀fúùfù ńlá fẹ́ lọ.
Kukangaki besiba njengomule emoyeni na, njengamakhoba ephetshulwa yisivunguzane?
19 Ẹ̀yin wí pé, ‘Ọlọ́run to ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jọ fún àwọn ọmọ rẹ̀.’ Jẹ́ kí ó san án fún un, yóò sì mọ̀ ọ́n.
Kuthiwa, ‘UNkulunkulu ulomba isijeziso somuntu asibekele amadodana akhe.’ Kajezise yena umuntu ngokwakhe ukuze akwazi!
20 Ojú rẹ̀ yóò rí ìparun ara rẹ̀, yóò sì máa mu nínú ríru ìbínú Olódùmarè.
Amehlo akhe kawakubone ukuchithwa kwakhe; kalunathe ulaka lukaSomandla.
21 Nítorí pé àlàáfíà kí ni ó ní nínú ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí a bá ké iye oṣù rẹ̀ kúrò ní agbede-méjì?
Ngoba uvele uzihlupha ngani ngemuli avele ezayitshiya nxa izinyanga zakhe azabelweyo seziphelile na?
22 “Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni le kọ Ọlọ́run ní ìmọ̀? Òun ní í sá à ń ṣe ìdájọ́ ẹni ibi gíga.
Kambe ukhona ongafundisa uNkulunkulu ulwazi, njengoba yena esahlulela labaphezulu na?
23 Ẹnìkan a kú nínú pípé agbára rẹ̀, ó wà nínú ìrora àti ìdákẹ́ pátápátá.
Umuntu uyafa ephilile kuhle, kukuhle konke ekhululekile,
24 Ọpọ́n rẹ̀ kún fún omi ọmú, egungun rẹ̀ sì tutù fún ọ̀rá.
umzimba wakhe uzimukile, amathambo akhe egcwele umnkantsho.
25 Ẹlòmíràn a sì kú nínú kíkorò ọkàn rẹ̀, tí kò sì fi inú dídùn jẹun.
Omunye ufa elobuhlungu emphefumulweni wakhe, evele engakaze akholise lutho oluhle.
26 Wọ́n o dùbúlẹ̀ bákan náà nínú erùpẹ̀, kòkòrò yóò sì ṣùbò wọ́n.
Bobabili balaliswe ndawonye eceleni komunye othulini, impethu zinyakaze phezu kwabo bobabili.
27 “Kíyèsi i, èmi mọ̀ èrò inú yín àti àrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.
Ngiyazi kamhlophe ukuthi licabangani, amacebo elidinga ukungilimaza ngawo.
28 Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní ilé ọmọ-aládé, àti níbo ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’
Lithi, ‘Ingaphi-ke manje indlu yesikhulu, amathente okwakuhlala kuwo abantu ababi?’
29 Ẹ̀yin kò béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ń kọjá lọ ní ọ̀nà? Ẹ̀yin kò mọ̀ àmì wọn,
Kalikaze libuze labo abahambayo na? Kalize lananzelela izinto abazilandisayo,
30 pé ènìyàn búburú ní a fi pamọ́ fún ọjọ́ ìparun. A ó sì mú wọn jáde ní ọjọ́ ríru ìbínú.
ukuthi umuntu omubi uyaphepha ngosuku lokubhujiswa na, ukuthi uyakhululwa ngosuku lwesiphithiphithi?
31 Ta ni yóò tako ipa ọ̀nà rẹ̀ lójúkojú, ta ni yóò sì san án padà fún un ní èyí tí ó ti ṣe?
Kambe ngubani omtshela ngobubi bakhe ebusweni bakhe na? Ngubani ophindiselayo ngalokho akwenzileyo na?
32 Síbẹ̀ a ó sì sin ín ní ọ̀nà ipò òkú, a ó sì máa ṣọ́ ibojì òkú.
Uthwalelwa engcwabeni, lilindwe ingcwaba lakhe ngemfanelo.
33 Ògúlùtu àfonífojì yóò dùn mọ́ ọn. Gbogbo ènìyàn yóò sì máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, bí ènìyàn àìníye ti lọ síwájú rẹ̀.
Inhlabathi esigodini leso imnandi kuye; bonke abantu bayamlandela, banengi kakhulu njalo abahamba kuqala kulaye.
34 “Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin fi ń tù mí nínú lásán, bí ò ṣe pé ní ìdáhùn yín, àrékérekè wa níbẹ̀!”
Pho-ke lingangiduduza njani likhuluma ize nje? Akusalanga lutho elilutshoyo ngaphandle kwenkohliso.”

< Job 21 >