< Job 21 >

1 Jobu wá dáhùn, ó sì wí pé,
Ningĩ Ayubu agĩcookia atĩrĩ:
2 “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀ dáradára sì àwọn ọ̀rọ̀ mi, kí èyí kí ó jásí ìtùnú fún mi.
“Thikĩrĩriai wega ciugo ciakwa; rekei ũndũ ũyũ ũtuĩke nĩguo mũkũũhooreria naguo.
3 Ẹ jọ̀wọ́ mi ki èmi sọ̀rọ̀; lẹ́yìn ìgbà ìwọ le máa fi mi ṣẹ̀sín ń ṣo.
Ngirĩrĩriai na niĩ njarie, na ndaarĩkia kwaria-rĩ, mũgĩcooke mũũnyũrũrie.
4 “Àròyé mi ha ṣe sí ènìyàn bí? Èétise tí ọkàn mi kì yóò fi ṣe àìbalẹ̀?
“Niĩ-rĩ, kaĩ mateta makwa meerekeirio mũndũ? Ngũkĩaga kũremwo nĩ gũkirĩrĩria nĩkĩ?
5 Ẹ wò mí fín, kí ẹnu kí ó sì yà yín, kí ẹ sì fi ọwọ́ lé ẹnu yín.
Ta ndorai mũgege; mwĩnyiite tũnua twanyu na moko nĩ kũmaka.
6 Àní nígbà tí mo rántí, ẹ̀rù bà mí, ìwárìrì sì mú mi lára.
Ndĩciiragia ũhoro ũyũ ngamaka mũno; ngethithimũkwo nĩ mwĩrĩ, ngambĩrĩria kũinaina.
7 Nítorí kí ní ènìyàn búburú fi wà ní ayé, tí wọ́n gbó, àní tí wọ́n di alágbára ní ipa?
Atĩrĩ, andũ arĩa aaganu marekagwo matũũre muoyo nĩkĩ, magakũra o na magakĩrĩrĩria kũgĩa na ũhoti?
8 Irú-ọmọ wọn fi ìdí kalẹ̀ ní ojú wọn pẹ̀lú wọn, àti ọmọ ọmọ wọn ní ojú wọn.
Nĩmeonagĩra ciana ciao ikĩgaacĩra kũu marĩ, makoona rũciaro rwao rũkĩĩhaanda mbere ya maitho mao.
9 Ilé wọn wà láìní ewu àti ẹ̀rù, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá ìbínú Ọlọ́run kò sí lára wọn.
Mĩciĩ yao ĩikaraga ĩgitĩirwo na ĩtarĩ na guoya; naruo rũthanju rwa Ngai rũtimahũũraga.
10 Akọ màlúù wọn a máa gùn, kì í sì tàsé; abo màlúù wọn a máa bí, kì í sì í ṣẹ́yun.
Ndegwa ciao itiagaga kũgwatia; ngʼombe ciao iciaraga, na itihunaga.
11 Wọn a máa rán àwọn ọmọ wọn wẹ́wẹ́ jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa jo kiri.
Moimagaragia twana twao tũingĩ o ta rũũru; ciana icio ciao ikaina igĩtũrũhaga.
12 Wọ́n mú ohun ọ̀nà orin, ìlù àti haapu; wọ́n sì ń yọ̀ sí ohùn fèrè.
Nao o ene mainaga makĩhũũraga tũhembe na inanda cia mũgeeto; mekenagia na mũgambo wa mũtũrirũ.
13 Wọ́n n lo ọjọ́ wọn nínú ọrọ̀; wọn sì lọ sí ipò òkú ní àlàáfíà. (Sheol h7585)
Matũũraga mĩaka yao magaacĩire, na magathiĩ mbĩrĩra-inĩ marĩ na thayũ. (Sheol h7585)
14 Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa!’ Nítorí pé wọn kò fẹ́ ìmọ̀ ipa ọ̀nà rẹ.
Na no-o meeraga Mũrungu atĩrĩ, ‘Thiĩ! Tigana na ithuĩ! Tũtikwenda kũmenya njĩra ciaku.
15 Kí ni Olódùmarè tí àwa ó fi máa sìn in? Èrè kí ni a ó sì jẹ bí àwa ba gbàdúrà sí i?
Mwene-Hinya-Wothe nĩwe ũ, atĩ nĩguo tũmũtungatagĩre? Tũkũgunĩka nakĩ tũngĩmũhooya?’
16 Kíyèsi i, àlàáfíà wọn kò sí nípa ọwọ́ wọn; ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi réré.
No rĩrĩ, kũgaacĩra kwao gũtirĩ moko-inĩ mao ene, nĩ ũndũ ũcio niĩ njikaraga haraaya na kĩrĩra kĩa andũ arĩa aaganu.
17 “Ìgbà mélòó mélòó ní a ń pa fìtílà ènìyàn búburú kú? Ìgbà mélòó mélòó ní ìparun wọn dé bá wọn, tí Ọlọ́run sì í máa pín ìbìnújẹ́ nínú ìbínú rẹ̀?
“Na rĩrĩ, nĩ maita maigana tawa wa arĩa aaganu ũhoragio? Nĩ maita maigana makoragwo nĩ mũtino, na nĩ maita maigana Ngai amagayagĩra ruo nĩ kũmarakarĩra?
18 Wọ́n dàbí àgékù koríko níwájú afẹ́fẹ́, àti bí ìyàngbò, tí ẹ̀fúùfù ńlá fẹ́ lọ.
Nĩ maita maigana matuĩkaga ta nyeki nyũmũ ĩkũhurutwo nĩ rũhuho, o na kana ta maragara marĩa mombũragwo nĩ kĩhuhũkanio?
19 Ẹ̀yin wí pé, ‘Ọlọ́run to ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jọ fún àwọn ọmọ rẹ̀.’ Jẹ́ kí ó san án fún un, yóò sì mọ̀ ọ́n.
Kuugagwo atĩrĩ, ‘Ngai aigagĩra ciana iherithia rĩa ithe wao.’ No rĩrĩ, nĩ kaba Ngai aherithie mũndũ ũcio we mwene, nĩguo amenye nĩehĩtie!
20 Ojú rẹ̀ yóò rí ìparun ara rẹ̀, yóò sì máa mu nínú ríru ìbínú Olódùmarè.
Maitho make nĩmeyonere mwanangĩko wake mwene; nĩarekwo akunde mangʼũrĩ ma Mwene-Hinya-Wothe.
21 Nítorí pé àlàáfíà kí ni ó ní nínú ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí a bá ké iye oṣù rẹ̀ kúrò ní agbede-méjì?
Nĩ ũndũ-rĩ, anga no eetangaga ha ũhoro wa andũ ake arĩa agaatiga na thuutha, matukũ make maathira?
22 “Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni le kọ Ọlọ́run ní ìmọ̀? Òun ní í sá à ń ṣe ìdájọ́ ẹni ibi gíga.
“Nĩ kũrĩ mũndũ o na ũmwe ũngĩhota kũruta Mũrungu atĩ nĩguo agĩe na ũmenyo, kuona atĩ Mũrungu nĩwe ũtuanagĩra ciira, o na agatuĩra arĩa atũũgĩirie mũno?
23 Ẹnìkan a kú nínú pípé agbára rẹ̀, ó wà nínú ìrora àti ìdákẹ́ pátápátá.
Nĩ kũrĩ mũndũ ũkuuaga arĩ na hinya wake wothe, arĩ mũgitĩre wega biũ, na arĩ na thayũ,
24 Ọpọ́n rẹ̀ kún fún omi ọmú, egungun rẹ̀ sì tutù fún ọ̀rá.
mwĩrĩ wake ũheetwo irio wega, na mahĩndĩ ma mĩthiimo yake marĩ o maigũ.
25 Ẹlòmíràn a sì kú nínú kíkorò ọkàn rẹ̀, tí kò sì fi inú dídùn jẹun.
Mũndũ ũngĩ agakua arĩ na marũrũ ma ngoro, atarĩ aakenera kĩndũ kĩega o na kĩ.
26 Wọ́n o dùbúlẹ̀ bákan náà nínú erùpẹ̀, kòkòrò yóò sì ṣùbò wọ́n.
Makomaga o ro ũndũ ũmwe tĩĩri-inĩ, na eerĩ-rĩ, igunyũ ikamahumbĩra.
27 “Kíyèsi i, èmi mọ̀ èrò inú yín àti àrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.
“Niĩ nĩnjũũĩ wega ũrĩa mũreciiria, ngamenya mathugunda manyu maakũhĩtĩria namo.
28 Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní ilé ọmọ-aládé, àti níbo ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’
Mũrooria atĩrĩ, ‘Rĩu nyũmba ya mũndũ ũrĩa mũnene ĩkĩrĩ ha, na hema ĩrĩa andũ aaganu maratũũraga-rĩ, ĩkĩrĩ ha?’
29 Ẹ̀yin kò béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ń kọjá lọ ní ọ̀nà? Ẹ̀yin kò mọ̀ àmì wọn,
Kaĩ mũtarĩ muoria andũ arĩa mathiiaga ngʼendo? Kaĩ mũtarũmbũyagia ũrĩa mamwĩraga:
30 pé ènìyàn búburú ní a fi pamọ́ fún ọjọ́ ìparun. A ó sì mú wọn jáde ní ọjọ́ ríru ìbínú.
atĩ mũndũ ũrĩa mwaganu nĩ aiguagĩrwo tha mũthenya wa mũtino, atĩ nĩahonokagio mũthenya wa mangʼũrĩ?
31 Ta ni yóò tako ipa ọ̀nà rẹ̀ lójúkojú, ta ni yóò sì san án padà fún un ní èyí tí ó ti ṣe?
Nũũ ũreganaga na mĩtugo ya mũndũ mwaganu maitho-inĩ make? Nũũ ũmũrĩhagia kũringana na maũndũ marĩa aaneka?
32 Síbẹ̀ a ó sì sin ín ní ọ̀nà ipò òkú, a ó sì máa ṣọ́ ibojì òkú.
Atwaragwo mbĩrĩra-inĩ, nayo mbĩrĩra yake ĩkarangagĩrwo.
33 Ògúlùtu àfonífojì yóò dùn mọ́ ọn. Gbogbo ènìyàn yóò sì máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, bí ènìyàn àìníye ti lọ síwájú rẹ̀.
Tĩĩri wa gĩtuamba nĩũrĩ mũrĩo harĩ we; andũ othe nĩwe marũmagĩrĩra, na kĩrĩndĩ gĩtangĩtarĩka gĩgathiiaga mbere yake.
34 “Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin fi ń tù mí nínú lásán, bí ò ṣe pé ní ìdáhùn yín, àrékérekè wa níbẹ̀!”
“Mwakĩhota atĩa kũũhooreria na ndeto cia tũhũ? Hatirĩ kĩndũ gĩtigaru harĩ macookio manyu tiga o maheeni!”

< Job 21 >