< Job 21 >

1 Jobu wá dáhùn, ó sì wí pé,
Then Job replied,
2 “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀ dáradára sì àwọn ọ̀rọ̀ mi, kí èyí kí ó jásí ìtùnú fún mi.
“Listen to what I say, all [three] of you; that is the only thing that you can do that will comfort me.
3 Ẹ jọ̀wọ́ mi ki èmi sọ̀rọ̀; lẹ́yìn ìgbà ìwọ le máa fi mi ṣẹ̀sín ń ṣo.
Be patient with me, and allow me to speak. Then, after I am finished speaking, you can continue to make fun of me.
4 “Àròyé mi ha ṣe sí ènìyàn bí? Èétise tí ọkàn mi kì yóò fi ṣe àìbalẹ̀?
“It is certainly not [RHQ] people against whom I am complaining, [but God] And it is certainly [RHQ] right for me to be impatient!
5 Ẹ wò mí fín, kí ẹnu kí ó sì yà yín, kí ẹ sì fi ọwọ́ lé ẹnu yín.
Look at me! Does what you see not cause you to be appalled and to put your hands over your mouths [and say no more]?
6 Àní nígbà tí mo rántí, ẹ̀rù bà mí, ìwárìrì sì mú mi lára.
When I think about [what has happened to me], I am frightened and my entire body shakes.
7 Nítorí kí ní ènìyàn búburú fi wà ní ayé, tí wọ́n gbó, àní tí wọ́n di alágbára ní ipa?
“[But let me ask this: ] ‘Why do wicked people continue to live, and become prosperous, and not die until they are very old?’
8 Irú-ọmọ wọn fi ìdí kalẹ̀ ní ojú wọn pẹ̀lú wọn, àti ọmọ ọmọ wọn ní ojú wọn.
They have their children around them, and they watch them while they [grow up and] start to live in their own houses, and they enjoy their grandchildren.
9 Ilé wọn wà láìní ewu àti ẹ̀rù, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá ìbínú Ọlọ́run kò sí lára wọn.
Wicked people live in their own houses without being afraid, and God does not punish [MTY] them.
10 Akọ màlúù wọn a máa gùn, kì í sì tàsé; abo màlúù wọn a máa bí, kì í sì í ṣẹ́yun.
Their bulls always mate with the cows successfully, and the cows give birth to calves and never miscarry.
11 Wọn a máa rán àwọn ọmọ wọn wẹ́wẹ́ jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa jo kiri.
Wicked people send their young children outside [to play], and the children play [happily] like [SIM] lambs [in a pasture].
12 Wọ́n mú ohun ọ̀nà orin, ìlù àti haapu; wọ́n sì ń yọ̀ sí ohùn fèrè.
Some children dance and sing, while others shake tambourines and play lyres, and they are happy when they hear people playing flutes.
13 Wọ́n n lo ọjọ́ wọn nínú ọrọ̀; wọn sì lọ sí ipò òkú ní àlàáfíà. (Sheol h7585)
Wicked people enjoy having good things all the time that they are alive, and they die quietly/peacefully and go down to the place of the dead. (Sheol h7585)
14 Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa!’ Nítorí pé wọn kò fẹ́ ìmọ̀ ipa ọ̀nà rẹ.
While they are alive, they say to God, ‘Do not bother us; we do not want to know how you want us to conduct our lives!
15 Kí ni Olódùmarè tí àwa ó fi máa sìn in? Èrè kí ni a ó sì jẹ bí àwa ba gbàdúrà sí i?
Why do you, Almighty God, think that we should serve you? (What advantage do we get if we pray to you?/It is useless for us to pray to you.) [RHQ]’
16 Kíyèsi i, àlàáfíà wọn kò sí nípa ọwọ́ wọn; ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi réré.
Think about it: Wicked people think that it is because of what they have done that they have become prosperous, but I do not understand why they think like that.
17 “Ìgbà mélòó mélòó ní a ń pa fìtílà ènìyàn búburú kú? Ìgbà mélòó mélòó ní ìparun wọn dé bá wọn, tí Ọlọ́run sì í máa pín ìbìnújẹ́ nínú ìbínú rẹ̀?
(“How often does it happen that wicked people die [MET] before they are old?/Very seldom do wicked people die [MET] before they are old.) [RHQ] (Do they ever experience disasters?/They seldom experience disasters.) [RHQ] (Does God ever punish them because of being very angry with them?/God never punishes them because of being very angry with them.) [RHQ]
18 Wọ́n dàbí àgékù koríko níwájú afẹ́fẹ́, àti bí ìyàngbò, tí ẹ̀fúùfù ńlá fẹ́ lọ.
[He does not blow] them away like wind blows away straw; they are never carried off by a whirlwind.
19 Ẹ̀yin wí pé, ‘Ọlọ́run to ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jọ fún àwọn ọmọ rẹ̀.’ Jẹ́ kí ó san án fún un, yóò sì mọ̀ ọ́n.
You say, ‘When people have committed sins, God waits and punishes their children because of those sins;’ but [I say that] God should punish those who sin, [not their children, ] in order that the sinners will know [that it is because of their own sins that they are being punished].
20 Ojú rẹ̀ yóò rí ìparun ara rẹ̀, yóò sì máa mu nínú ríru ìbínú Olódùmarè.
I hope/wish that wicked people will experience themselves being destroyed, that they will experience being punished by an angry Almighty God.
21 Nítorí pé àlàáfíà kí ni ó ní nínú ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí a bá ké iye oṣù rẹ̀ kúrò ní agbede-méjì?
After wicked people are dead, they are not at all concerned [RHQ] about what happens to their families [MTY].
22 “Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni le kọ Ọlọ́run ní ìmọ̀? Òun ní í sá à ń ṣe ìdájọ́ ẹni ibi gíga.
“Since God judges [everyone, ] even those that are in heaven, (who can teach God anything?/certainly no one can teach God anything.) [RHQ]
23 Ẹnìkan a kú nínú pípé agbára rẹ̀, ó wà nínú ìrora àti ìdákẹ́ pátápátá.
Some people die while they are very healthy, while they are peaceful, when they are not afraid of anything.
24 Ọpọ́n rẹ̀ kún fún omi ọmú, egungun rẹ̀ sì tutù fún ọ̀rá.
Their bodies are fat; their bones are strong.
25 Ẹlòmíràn a sì kú nínú kíkorò ọkàn rẹ̀, tí kò sì fi inú dídùn jẹun.
Other people die being very miserable; they have never experienced good things happening to them.
26 Wọ́n o dùbúlẹ̀ bákan náà nínú erùpẹ̀, kòkòrò yóò sì ṣùbò wọ́n.
But both rich and poor people die and are buried, and maggots eat their bodies. [Everyone dies, so it is clear that dying is not always the punishment for being wicked].
27 “Kíyèsi i, èmi mọ̀ èrò inú yín àti àrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.
“Listen, I know what you [three] are thinking. I know the evil things that you plan to do to me.
28 Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní ilé ọmọ-aládé, àti níbo ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’
You say, ‘What happened to the tents in which wicked people were living? The houses of evil rulers have been destroyed!’
29 Ẹ̀yin kò béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ń kọjá lọ ní ọ̀nà? Ẹ̀yin kò mọ̀ àmì wọn,
But have you never inquired of people who travel much? Do you not believe their reports about what they have seen,
30 pé ènìyàn búburú ní a fi pamọ́ fún ọjọ́ ìparun. A ó sì mú wọn jáde ní ọjọ́ ríru ìbínú.
that wicked people usually do not suffer at the time when there are great disasters; that wicked people are the ones who are rescued when God is angry [and punishes people] [MTY]?
31 Ta ni yóò tako ipa ọ̀nà rẹ̀ lójúkojú, ta ni yóò sì san án padà fún un ní èyí tí ó ti ṣe?
There is no one [RHQ] who accuses wicked people, and there is no one who (pays them back/gives them the punishment that they deserve) for all the evil things that they have done.
32 Síbẹ̀ a ó sì sin ín ní ọ̀nà ipò òkú, a ó sì máa ṣọ́ ibojì òkú.
The corpses of wicked people are carried to their graves, and people are put there to guard those graves.
33 Ògúlùtu àfonífojì yóò dùn mọ́ ọn. Gbogbo ènìyàn yóò sì máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, bí ènìyàn àìníye ti lọ síwájú rẹ̀.
A huge number [HYP] of people go to the grave site. Some go in front of the procession and some come behind. And the clods of dirt thrown on the graves of those wicked people who have died are like a nice blanket.
34 “Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin fi ń tù mí nínú lásán, bí ò ṣe pé ní ìdáhùn yín, àrékérekè wa níbẹ̀!”
“So how can you console me by talking nonsense? Every reply that you make is full of lies!”

< Job 21 >