< Job 21 >

1 Jobu wá dáhùn, ó sì wí pé,
A odpovídaje Job, řekl:
2 “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀ dáradára sì àwọn ọ̀rọ̀ mi, kí èyí kí ó jásí ìtùnú fún mi.
Poslouchejte pilně řeči mé, a bude mi to za potěšení od vás.
3 Ẹ jọ̀wọ́ mi ki èmi sọ̀rọ̀; lẹ́yìn ìgbà ìwọ le máa fi mi ṣẹ̀sín ń ṣo.
Postrpte mne, abych i já mluvil, a když odmluvím, posmívejž se.
4 “Àròyé mi ha ṣe sí ènìyàn bí? Èétise tí ọkàn mi kì yóò fi ṣe àìbalẹ̀?
Zdaliž já před člověkem naříkám? A poněvadž jest proč, jakž nemá býti ssoužen duch můj?
5 Ẹ wò mí fín, kí ẹnu kí ó sì yà yín, kí ẹ sì fi ọwọ́ lé ẹnu yín.
Pohleďte na mne, a užasněte se, a položte prst na ústa.
6 Àní nígbà tí mo rántí, ẹ̀rù bà mí, ìwárìrì sì mú mi lára.
Ano já sám, když rozvažuji své bídy, tedy se děsím, a spopadá tělo mé hrůza.
7 Nítorí kí ní ènìyàn búburú fi wà ní ayé, tí wọ́n gbó, àní tí wọ́n di alágbára ní ipa?
Proč bezbožní živi jsou, k věku starému přicházejí, též i bohatnou?
8 Irú-ọmọ wọn fi ìdí kalẹ̀ ní ojú wọn pẹ̀lú wọn, àti ọmọ ọmọ wọn ní ojú wọn.
Símě jejich stálé jest před oblíčejem jejich s nimi, a rodina jejich před očima jejich.
9 Ilé wọn wà láìní ewu àti ẹ̀rù, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá ìbínú Ọlọ́run kò sí lára wọn.
Domové jejich bezpečni jsou před strachem, aniž metla Boží na nich.
10 Akọ màlúù wọn a máa gùn, kì í sì tàsé; abo màlúù wọn a máa bí, kì í sì í ṣẹ́yun.
Býk jejich připouštín bývá, ale ne na prázdno; kráva jejich rodí, a nepotracuje plodu.
11 Wọn a máa rán àwọn ọmọ wọn wẹ́wẹ́ jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa jo kiri.
Vypouštějí jako stádo maličké své, a synové jejich poskakují.
12 Wọ́n mú ohun ọ̀nà orin, ìlù àti haapu; wọ́n sì ń yọ̀ sí ohùn fèrè.
Povyšují hlasu při bubnu a harfě, a veselí se k zvuku muziky.
13 Wọ́n n lo ọjọ́ wọn nínú ọrọ̀; wọn sì lọ sí ipò òkú ní àlàáfíà. (Sheol h7585)
Tráví v štěstí dny své, a v okamžení do hrobu sstupují. (Sheol h7585)
14 Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa!’ Nítorí pé wọn kò fẹ́ ìmọ̀ ipa ọ̀nà rẹ.
Kteříž říkají Bohu silnému: Odejdi od nás, nebo známosti cest tvých neoblibujeme.
15 Kí ni Olódùmarè tí àwa ó fi máa sìn in? Èrè kí ni a ó sì jẹ bí àwa ba gbàdúrà sí i?
Kdo jest Všemohoucí, abychom sloužili jemu? A jaký toho zisk, že bychom se modlili jemu?
16 Kíyèsi i, àlàáfíà wọn kò sí nípa ọwọ́ wọn; ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi réré.
Ale pohleď, že není v moci jejich štěstí jejich, pročež rada bezbožných vzdálena jest ode mne.
17 “Ìgbà mélòó mélòó ní a ń pa fìtílà ènìyàn búburú kú? Ìgbà mélòó mélòó ní ìparun wọn dé bá wọn, tí Ọlọ́run sì í máa pín ìbìnújẹ́ nínú ìbínú rẹ̀?
Èasto-liž svíce bezbožných hasne? Přichází-liž na ně bída jejich? Poděluje-liž je bolestmi Bůh v hněvě svém?
18 Wọ́n dàbí àgékù koríko níwájú afẹ́fẹ́, àti bí ìyàngbò, tí ẹ̀fúùfù ńlá fẹ́ lọ.
Bývají-liž jako plevy před větrem, a jako drtiny, kteréž zachvacuje vicher?
19 Ẹ̀yin wí pé, ‘Ọlọ́run to ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jọ fún àwọn ọmọ rẹ̀.’ Jẹ́ kí ó san án fún un, yóò sì mọ̀ ọ́n.
Odkládá-liž Bůh synům bezbožníka nepravost jeho? Odplacuje-liž jemu tak, aby to znáti mohl,
20 Ojú rẹ̀ yóò rí ìparun ara rẹ̀, yóò sì máa mu nínú ríru ìbínú Olódùmarè.
A aby viděly oči jeho neštěstí jeho, a prchlivost Všemohoucího že by pil?
21 Nítorí pé àlàáfíà kí ni ó ní nínú ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí a bá ké iye oṣù rẹ̀ kúrò ní agbede-méjì?
O dům pak jeho po něm jaká jest péče jeho, když počet měsíců jeho bude umenšen?
22 “Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni le kọ Ọlọ́run ní ìmọ̀? Òun ní í sá à ń ṣe ìdájọ́ ẹni ibi gíga.
Zdali Boha silného kdo učiti bude umění, kterýž sám vysokosti soudí?
23 Ẹnìkan a kú nínú pípé agbára rẹ̀, ó wà nínú ìrora àti ìdákẹ́ pátápátá.
Tento umírá v síle dokonalosti své, všelijak bezpečný a pokojný.
24 Ọpọ́n rẹ̀ kún fún omi ọmú, egungun rẹ̀ sì tutù fún ọ̀rá.
Prsy jeho plné jsou mléka, a mozk kostí jeho svlažován bývá.
25 Ẹlòmíràn a sì kú nínú kíkorò ọkàn rẹ̀, tí kò sì fi inú dídùn jẹun.
Jiný pak umírá v hořkosti ducha, kterýž nikdy nejídal s potěšením.
26 Wọ́n o dùbúlẹ̀ bákan náà nínú erùpẹ̀, kòkòrò yóò sì ṣùbò wọ́n.
Jednostejně v prachu lehnou, a červy se rozlezou.
27 “Kíyèsi i, èmi mọ̀ èrò inú yín àti àrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.
Aj, známť myšlení vaše, a chytrosti, kteréž proti mně neprávě vymýšlíte.
28 Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní ilé ọmọ-aládé, àti níbo ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’
Nebo pravíte: Kde jest dům urozeného? A kde stánek příbytků bezbožných?
29 Ẹ̀yin kò béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ń kọjá lọ ní ọ̀nà? Ẹ̀yin kò mọ̀ àmì wọn,
Což jste se netázali jdoucích cestou? Zkušení-liž aspoň jejich nepovolíte,
30 pé ènìyàn búburú ní a fi pamọ́ fún ọjọ́ ìparun. A ó sì mú wọn jáde ní ọjọ́ ríru ìbínú.
Že v den neštěstí ochranu mívá bezbožný, v den, pravím, rozhněvání přistřín bývá?
31 Ta ni yóò tako ipa ọ̀nà rẹ̀ lójúkojú, ta ni yóò sì san án padà fún un ní èyí tí ó ti ṣe?
Kdo jemu oznámí zjevně cestu jeho? Aneb za to, co činil, kdo jemu odplatí?
32 Síbẹ̀ a ó sì sin ín ní ọ̀nà ipò òkú, a ó sì máa ṣọ́ ibojì òkú.
A však i on k hrobu vyprovozen bude, a tam zůstane.
33 Ògúlùtu àfonífojì yóò dùn mọ́ ọn. Gbogbo ènìyàn yóò sì máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, bí ènìyàn àìníye ti lọ síwájú rẹ̀.
Sladnou jemu hrudy údolí, nadto za sebou všecky lidi táhne, těch pak, kteříž ho předešli, není počtu.
34 “Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin fi ń tù mí nínú lásán, bí ò ṣe pé ní ìdáhùn yín, àrékérekè wa níbẹ̀!”
Hle, jak vy mne marně troštujete, nebo v odpovědech vašich nezůstává než faleš.

< Job 21 >