< Job 20 >
1 Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé,
Atunci a răspuns Țofar naamatitul și a zis:
2 “Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn, àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.
De aceea mă fac gândurile mele să răspund și pentru aceasta mă grăbesc.
3 Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òye mi sì dá mi lóhùn.
Am auzit mustrarea ocării mele și duhul înțelegerii mele mă face să răspund.
4 “Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́, láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,
Nu știi aceasta din vechime, de când a fost pus omul pe pământ,
5 pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni, àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?
Că triumfarea celui stricat este scurtă și bucuria fățarnicului este doar pentru un moment?
6 Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run, ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;
Deși măreția lui se ridică la ceruri și capul său atinge norii,
7 ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀; àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’
Totuși va pieri pentru totdeauna asemenea propriului său gunoi; cei ce l-au văzut vor spune: Unde este el?
8 Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i, àní a ó lé e lọ bi ìran òru.
El va zbura ca un vis și nu va fi găsit; da, va fi alungat precum o viziune a nopții.
9 Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.
De asemenea ochiul care l-a văzut nu îl va mai vedea; nici locul său nu îl va mai privi.
10 Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà, ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.
Copiii lui vor căuta să mulțumească pe sărac și mâinile lui vor înapoia averile lor.
11 Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀, tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.
Oasele lui sunt pline de păcatul tinereții sale, care se va culca cu el în țărână.
12 “Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀, bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,
Deși stricăciunea este dulce în gura lui, deși el o ascunde sub limba sa,
13 bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀, tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,
Deși o cruță și nu o părăsește, ci o ține înăuntrul gurii sale;
14 ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà, ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;
Totuși mâncarea lui în pântecele său este preschimbată, este veninul aspidelor înăuntrul lui.
15 Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde; Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.
A înghițit bogății și le va vomita din nou; Dumnezeu le va arunca afară din stomacul său.
16 Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú; ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.
El va suge otrava aspidelor; limba viperei îl va ucide.
17 Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì, ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.
El nu va vedea râurile, potopurile, pâraiele de miere și unt.
18 Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì; gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.
El va da înapoi rodul muncii sale și nu îl va înghiți, conform cu averea sa va fi restituirea și el nu se va bucura în aceasta.
19 Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti pẹ̀yìndà si wọ́n; nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.
Pentru că a oprimat [și] a părăsit pe sărac, pentru [că] el cu violență a luat o casă pe care nu a zidit-o;
20 “Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀, kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.
Cu siguranță nu va simți liniște în stomacul său, el nu va salva din ceea ce a dorit.
21 Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀; nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.
Nimic din mâncarea lui nu va rămâne; de aceea niciun om nu va îngriji de bunurile lui.
22 Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a; àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.
În plinătatea abundenței sale va fi în strâmtorări, fiecare mână a celor stricați va veni peste el.
23 Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun, Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́, yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.
Când este gata să își umple stomacul, Dumnezeu va arunca aprinderea furiei sale asupra lui și va ploua cu ea asupra lui în timp ce mănâncă.
24 Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn; ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.
El va fugi de arma de fier și arcul de oțel îl va străpunge.
25 O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára; idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá. Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;
Este scoasă și îi iese din trup; da, sabia scânteietoare iese din fierea lui, groazele sunt asupra lui.
26 òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀. Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.
Tot întunericul se va ascunde în locurile lui tainice, un foc neațâțat îl va mistui; îi va merge rău celui care este lăsat în cortul lui.
27 Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn, ayé yóò sì dìde dúró sí i.
Cerul va arăta nelegiuirea lui, și pământul se va ridica împotriva lui.
28 Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ, àti ohun ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.
Venitul casei lui se va depărta și bunurile sale se vor scurge în ziua furiei lui.
29 Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
Aceasta este partea de la Dumnezeu unui om stricat și moștenirea rânduită lui de Dumnezeu.