< Job 20 >

1 Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé,
Katahi ka whakautua e Topara Naamati; i mea ia,
2 “Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn, àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.
Na kona oku whakaaro i whakahoki kupu ake ai i roto i ahau; na reira ano ahau i hohoro ai.
3 Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òye mi sì dá mi lóhùn.
Kua rongo ahau i te whakahe moku, e pa ai te whakama ki ahau, a na te wairua o toku ngakau mahara te kupu whakahoki ki ahau.
4 “Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́, láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,
Kahore ranei koe i mohio ki tenei i mua noa atu, i te wa ra ano i whakanohoia ai te tangata ki runga ki te whenua;
5 pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni, àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?
He poto te wa e whakamanamana ai te tangata kino, a ko te hari o te tangata atuakore he wheriko kau?
6 Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run, ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;
Ahakoa eke noa tona nui ki nga rangi, a pa atu tona mahunga ki nga kapua;
7 ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀; àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’
Ka memeha atu ano ia a ake ake, ka pera ano me tona paru: ko te hunga kua kite i a ia, ka mea, Kei hea ia?
8 Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i, àní a ó lé e lọ bi ìran òru.
Ka rere atu ia ano he moemoea, e kore ano hoki e kitea: ae ka aia atu ia, ano he rekanga kanohi no te po.
9 Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.
Ko te kanohi i kite i a ia e kore e kite ano; a heoi ano tirohanga a tona wahi ki a ia.
10 Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà, ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.
E whakamanawareka ana tamariki i nga rawakore, ma ona ringa ano e whakahoki ona rawa.
11 Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀, tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.
E ki ana ona wheua i te tamarikitanga; engari ka takoto tahi me ia i roto i te puehu.
12 “Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀, bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,
Ahakoa reka te kino i roto i tona mangai, ahakoa huna e ia i raro i tona arero;
13 bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀, tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,
Ahakoa manawapatia noatia e ia, a kahore e mahue i a ia, heoi pupuri tonu i roto i tona mangai;
14 ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà, ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;
Otira ka puta ke tana kai i roto i ona whekau, ko te au o nga ahipi i roto i a ia.
15 Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde; Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.
I horomia e ia te taonga, ka ruakina mai ano e ia; ma te Atua e akiri mai i roto i tona kopu.
16 Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú; ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.
Ka ngotea e ia te huware whakamate o nga ahipi; ka mate ano ia i te arero o te waipera.
17 Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì, ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.
E kore ia e kite i nga awa, i nga wai rere o te honi, o te pata.
18 Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì; gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.
Ko tana i uaua ai ka whakahokia e ia, e kore ano e horomia; ko tana utu ka rite ki ona taonga; e kore ano e koa ki reira.
19 Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti pẹ̀yìndà si wọ́n; nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.
Nana hoki i tukino nga rawakore, whakarerea iho; murua ana e ia he whare, a e kore e hanga ano e ia.
20 “Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀, kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.
I te mea kahore ia i kite i te tatutanga i roto i a ia, e kore ano etahi o nga mea e matea nuitia ana e ia e mau ki a ia.
21 Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀; nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.
Kahore tetahi mea i toe i kore te horomia e ia; no reira e kore tetahi mea pai ona e mau tonu.
22 Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a; àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.
I a ia e whiwhi nui nei i te rawa, e rawakore ano ia; ka tae mai ki a ia nga ringa katoa o te hunga kei roto i te mata.
23 Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun, Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́, yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.
I a ia ka mea ki te whakaki i tona kopu, ka maka mai e te Atua te kaha o tona riri ki runga ki a ia, a ka ringihia iho ki a ia, i a ia ano e kai ana.
24 Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn; ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.
Ka rere atu ia i te patu rino, ka tu ia i te kopere parahi, puta pu.
25 O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára; idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá. Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;
E unuhia ana, kua puta mai i roto i te tinana, ina, puta mai ana te mata wheriko i roto i tona au: kua tau nga wehi ki a ia.
26 òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀. Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.
Ko te pouri katoa kei te takoto mai mo ana taonga: ka kainga ia e te ahi, kihai i puhia e te tangata; ma reira e pau ai te toenga i roto i tona teneti.
27 Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn, ayé yóò sì dìde dúró sí i.
Ka whakakitea mai tona he e nga rangi ka whakatika mai ano te whenua ki a ia.
28 Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ, àti ohun ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.
Ko nga hua o tona whare ka riro: ka rere, ano he wai, ona mea i te ra e riri ai ia.
29 Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
Ko ta te Atua wahi tenei ma te tangata kino, ko te taonga tupu i kiia e te Atua mona.

< Job 20 >