< Job 20 >

1 Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé,
Nake Zofaru ũrĩa Mũnaamathi agĩcookia atĩrĩ:
2 “Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn, àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.
“Meciiria makwa nĩ mathĩĩnĩku, na nĩkĩo ngũcookia, nĩ ũndũ nĩndangĩkĩte mũno.
3 Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òye mi sì dá mi lóhùn.
Ndĩraigua irũithia rĩa kũnjonorithia, naguo ũmenyo wakwa nĩũranjĩkĩra hinya wa gũcookia.
4 “Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́, láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,
“Ti-itherũ nĩũũĩ ũrĩa gũtũire kuuma tene rĩrĩa mũndũ aigirwo gũkũ thĩ ĩno,
5 pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni, àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?
atĩ kũrũũhia kwa arĩa aaganu no gwa kahinda, o nakĩo gĩkeno kĩa andũ arĩa matooĩ Ngai no gĩa kahinda kanini.
6 Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run, ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;
O na gũtuĩka mwĩtĩĩo wake nĩ ũkinyaga o igũrũ, naguo mũtwe wake ũkahutia matu-rĩ,
7 ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀; àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’
agaathira nginya tene o ta mai make mwene; arĩa manamuona mooragie atĩrĩ, ‘Kaĩ aathiire kũ?’
8 Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i, àní a ó lé e lọ bi ìran òru.
Airagĩria ta kĩroto, akaaga kuoneka rĩngĩ, akaingatwo ta kĩoneki kĩa ũtukũ.
9 Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.
Riitho rĩrĩa rĩamuonaga rĩtikamuona rĩngĩ; harĩa aaikaraga hatikamuona rĩngĩ.
10 Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà, ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.
Ciana ciake ikaageragia kwĩiguithania na athĩĩni; moko make mwene no nginya magaacookia ũtonga wake kũrĩa aaũrutire.
11 Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀, tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.
Hinya wa wĩthĩ ũrĩa ũiyũrĩte mahĩndĩ-inĩ make ũgaakoma hamwe nake rũkũngũ-inĩ.
12 “Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀, bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,
“O na gũtuĩka ũũru ũrĩ mũrĩo ũrĩ kanua gake, na nĩaũhithaga rungu rwa rũrĩmĩ rwake,
13 bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀, tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,
o na gũtuĩka ndangĩhota kũũrekia na aũigaga kanua gake-rĩ,
14 ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà, ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;
irio ciake nĩikarũra irĩ nda yake; igaatuĩka ũrũrũ wa nduĩra thĩinĩ wake.
15 Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde; Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.
Nĩagatahĩka ũtonga ũrĩa ameretie; Mũrungu nĩagatũma aũtahĩke.
16 Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú; ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.
Nĩakoonga thumu wa nyoka; magego ma nyoka nĩmo makaamũũraga.
17 Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì, ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.
Ndagakenera tũrũũĩ, njũũĩ iria ithereraga ũũkĩ na ngorono.
18 Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì; gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.
Kĩndũ kĩrĩa anogeire no nginya agagĩcookia atakĩrĩte; ndagakenera uumithio wa wonjoria wake.
19 Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti pẹ̀yìndà si wọ́n; nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.
Nĩgũkorwo nĩahinyĩrĩirie athĩĩni, akamatiga matarĩ na kĩndũ; nĩatunyanĩte nyũmba iria ataakire.
20 “Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀, kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.
“Ti-itherũ merirĩria make matingĩthira; ndangĩĩhonokia na indo iria eigĩire.
21 Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀; nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.
Gũtirĩ kĩndũ atigĩirio gĩa kũrĩa; ũtonga wake ndũgatũũra.
22 Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a; àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.
Hĩndĩ ĩrĩa aiganĩire nĩ ũndũ wa kũingĩhia indo, mĩnyamaro nĩĩkamũnyiita; ũkĩa nĩũkamũkora na nditi nene.
23 Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun, Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́, yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.
Hĩndĩ ĩrĩa aiyũrĩtie nda yake-rĩ, nĩguo Ngai akaarekereria marakara make mahiũ mamũkore na amuurĩrie mahũũra make.
24 Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn; ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.
O na angĩũrĩra indo cia mbaara cia kĩgera, akaarathwo na mũguĩ wa gĩcango.
25 O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára; idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá. Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;
Aũcomoraga kuuma ngʼongʼo wake, mũtheece ũcio mũkengu akaũcomora kuuma ini-inĩ rĩake. Imakania nĩikamũkorerera;
26 òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀. Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.
nduma nene nĩyetereire igĩĩna ciake. Mwaki ũtarĩ mũhurutĩre nĩũkamũcina, na ũniine kĩrĩa gĩtigaire thĩinĩ wa hema yake.
27 Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn, ayé yóò sì dìde dúró sí i.
Igũrũ nĩrĩkaguũria wĩhia wake; thĩ nayo nĩĩkarahũka ĩmũũkĩrĩre.
28 Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ, àti ohun ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.
Kĩguũ nĩgĩgathereria nyũmba yake, indo cia nyũmba yake ithererio nĩ kĩguũ mũthenya ũcio wa mangʼũrĩ ma Ngai.
29 Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
Ũcio nĩguo ũndũ ũrĩa Ngai agayagĩra arĩa aaganu, igai rĩrĩa maathĩrĩirwo nĩ Mũrungu.”

< Job 20 >