< Job 20 >

1 Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé,
Alors, répondant, Sophar, le Naamathite, dit:
2 “Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn, àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.
C’est pour cela que mes différentes pensées se succèdent, et que mon esprit est entraîné dans des sentiments divers.
3 Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òye mi sì dá mi lóhùn.
J’écouterai la doctrine en vertu de laquelle tu m’accuses, et l’esprit de mon intelligence répondra pour moi.
4 “Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́, láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,
Ce que je sais être dès le principe, depuis que l’homme a été placé sur la terre,
5 pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni, àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?
C’est que la gloire des impies a été courte et la joie de l’hypocrite comme un moment.
6 Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run, ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;
Si son orgueil s’élève jusqu’au ciel, et que sa tête touche les nues,
7 ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀; àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’
Il périra à la fin comme un fumier, et ceux qui l’avaient vu diront: Où est-il?
8 Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i, àní a ó lé e lọ bi ìran òru.
Comme un songe qui s’envole, on ne le verra plus; il passera comme une vision de nuit.
9 Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.
L’œil qui l’avait vu ne le verra pas; et son lieu ne le regardera plus.
10 Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà, ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.
Ses enfants dépériront par l’indigence, et ses mains lui rendront la douleur qu’il a faite aux autres.
11 Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀, tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.
Ses os seront remplis des vices de sa jeunesse, et ces vices dormiront avec lui dans la poussière,
12 “Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀, bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,
Car, comme le mal est doux à sa bouche, il le cachera sous sa langue.
13 bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀, tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,
Il le ménagera, et il ne le laissera pas, mais il le tiendra caché dans sa gorge.
14 ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà, ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;
Son pain dans ses entrailles, au dedans de lui, se changera en fiel d’aspic.
15 Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde; Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.
Il vomira les richesses qu’il a dévorées, et Dieu les arrachera de ses entrailles.
16 Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú; ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.
Il sucera la tête des aspics, et la langue d’une vipère le tuera.
17 Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì, ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.
(Qu’il ne voie point couler les ruisseaux d’un fleuve, et les torrents de miel et de beurre).
18 Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì; gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.
Il expiera tout ce qu’il a fait, et cependant il ne sera pas consumé; c’est selon les richesses qu’il a acquises qu’il aura à souffrir,
19 Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti pẹ̀yìndà si wọ́n; nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.
Parce qu’en les brisant, il a dépouillé les pauvres; il a ravi une maison qu’il n’a pas bâtie.
20 “Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀, kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.
Son ventre n’a pas été rassasié; et lorsqu’il aura eu ce qu’il avait convoité, il ne pourra pas le posséder.
21 Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀; nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.
Il n’est rien resté de ses vivres; et à cause de cela rien ne lui demeurera de ses biens.
22 Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a; àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.
Lorsqu’il se sera rassasié, il sera oppressé et étouffé de chaleur, et toute sorte de douleurs fondront sur lui.
23 Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun, Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́, yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.
Puisse son ventre être rempli, en sorte que Dieu envoie contre lui la colère de sa fureur, et qu’il fasse pleuvoir sur lui ses foudres!
24 Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn; ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.
Il échappera à des armes de fer, mais il sera transpercé par un arc d’airain.
25 O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára; idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá. Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;
Un glaive tiré et sortant de son fourreau étincellera dans son amertume; d’horribles spectres iront et viendront sur lui.
26 òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀. Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.
Toutes sortes de ténèbres sont fermées à ses caches; un feu qui ne s’allume point le dévorera; il sera affligé, se trouvant délaissé dans son tabernacle.
27 Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn, ayé yóò sì dìde dúró sí i.
Les cieux révéleront son iniquité, et la terre s’élèvera contre lui.
28 Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ, àti ohun ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.
Les rejetons de sa maison seront exposés à la violence; ils seront enlevés au jour de la fureur de Dieu.
29 Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
Voilà la part d’un homme impie, faite par Dieu, et l’héritage réservé à ses paroles par le Seigneur.

< Job 20 >