< Job 20 >

1 Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé,
Naemalainen Soofar lausui ja sanoi:
2 “Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn, àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.
"Tuohon minun ajatukseni tuovat vastauksen, moisesta minun mieleni kuohuu.
3 Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òye mi sì dá mi lóhùn.
Häpäisevää nuhdetta täytyy minun kuulla, mutta minun ymmärrykseni henki antaa minulle vastauksen.
4 “Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́, láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,
Tuoko on sinulla tietoa ikiajoista asti, siitä saakka, kun ihminen maan päälle pantiin?
5 pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni, àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?
Ei, vaan jumalattomain riemu loppuu lyhyeen, ja riettaan ilo on vain silmänräpäys.
6 Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run, ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;
Vaikka hänen kopeutensa kohoaa taivaaseen ja hänen päänsä ulottuu pilviin asti,
7 ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀; àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’
katoaa hän kuitenkin ainiaaksi oman likansa lailla; jotka näkivät hänet, kysyivät: Missä hän on?
8 Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i, àní a ó lé e lọ bi ìran òru.
Niinkuin uni hän lentää pois, eikä häntä enää löydetä, ja hän häipyy kuin öinen näky.
9 Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.
Silmä, joka häntä katseli, ei katsele häntä enää, eikä hänen paikkansa häntä enää näe.
10 Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà, ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.
Hänen poikiensa täytyy hyvittää köyhät, hänen kättensä on annettava pois hänen omaisuutensa.
11 Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀, tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.
Nuoruuden voimaa olivat täynnä hänen luunsa, mutta sen täytyi mennä maata multaan hänen kanssansa.
12 “Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀, bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,
Vaikka paha onkin makeaa hänen suussaan, niin että hän kätkee sen kielensä alle,
13 bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀, tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,
säästää sitä eikä siitä luovu, vaan pidättää sitä keskellä suulakeansa,
14 ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà, ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;
niin muuttuu tämä ruoka hänen sisässään, tulee kyykäärmeiden kähyiksi hänen sisälmyksissänsä.
15 Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde; Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.
Hän nieli rikkautta, ja hänen täytyy se oksentaa pois, Jumala ajaa sen ulos hänen vatsastansa.
16 Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú; ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.
Kyykäärmeiden myrkkyä hän imi, kyyn kieli hänet tappaa.
17 Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì, ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.
Ei hän saa ilokseen katsella puroja, ei hunaja-ja kermajokia ja-virtoja.
18 Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì; gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.
Hänen on annettava pois hankkimansa, eikä hän saa sitä itse niellä; ei ole hänen ilonsa hänen voittamansa rikkauden veroinen.
19 Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti pẹ̀yìndà si wọ́n; nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.
Sillä hän teki vaivaisille väkivaltaa ja heitti heidät siihen, hän ryösti itselleen talon, eikä saa siinä rakennella.
20 “Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀, kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.
Sillä hän ei tuntenut vatsansa ikinä tyytyvän, mutta ei pelastu hän himotulla tavarallaan.
21 Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀; nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.
Ei mikään säilynyt hänen ahmailultaan, sentähden hänen onnensa ei kestä.
22 Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a; àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.
Yltäkylläisyytensä runsaudessa on hänellä hätä, häneen iskevät kaikki kurjien kourat.
23 Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun, Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́, yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.
Kun hän on täyttämässä vatsaansa, lähettää Jumala hänen kimppuunsa vihansa hehkun ja antaa sen sataa hänen päällensä hänen syödessään.
24 Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn; ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.
Jos hän pakenee rautavaruksia, niin lävistää hänet vaskijousi;
25 O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára; idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá. Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;
kun hän vetää ulos selästään nuolen, käy hänen sappensa lävitse miekan salama. Kauhut valtaavat hänet,
26 òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀. Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.
kaikki pimeys on varattu hänen aarteilleen. Hänet kuluttaa tuli, joka palaa lietsomatta, se syö, mitä on säilynyt hänen majassansa.
27 Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn, ayé yóò sì dìde dúró sí i.
Taivas paljastaa hänen pahat tekonsa, maa nousee häntä vastaan.
28 Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ, àti ohun ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.
Minkä hänen talonsa tuotti, menee menojaan vihan päivänä niinkuin tulvavedet.
29 Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
Tämä on jumalattoman ihmisen osa Jumalalta, perintöosa, jonka Jumala hänelle määrää."

< Job 20 >