< Job 2 >

1 Ó sì tún di ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá síwájú Olúwa, Satani sì wá pẹ̀lú wọn láti pe níwájú Olúwa.
I stało się niektórego dnia, gdy przyszli synowie Boży, aby stanęli przed Panem, przyszedł też szatan między nich, aby stanął przed Panem.
2 Olúwa sì bi Satani pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Satani sì dá Olúwa lóhùn pé, “Láti lọ síwá sẹ́yìn lórí ilẹ̀ ayé àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”
Tedy rzekł Pan do szatana: Gdzieś był, skąd idziesz? I odpowiedział szatan Panu, a rzekł: Okrążałem ziemię, i przechodziłem się po niej.
3 Olúwa sì wí fún Satani pé, “Ìwọ ha kíyèsi Jobu ìránṣẹ́ mi, pé, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí ń ṣe olóòtítọ́ tí ó sì dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó sì kórìíra ìwà búburú, bẹ́ẹ̀ ni ó sì di ìwà òtítọ́ rẹ̀ mu ṣinṣin, bí ìwọ tilẹ̀ ti dẹ mí sí i láti run ún láìnídìí.”
Zatem rzekł Pan do szatana: Przypatrzyłżeś się słudze memu Ijobowi, że mu nie masz równego na ziemi? Mąż to doskonały i szczery, bojący się Boga, a odstępujący od złego, i który jeszcze trwa w uprzejmości swojej; a tyś mię pobudził przeciw niemu, abym go niszczył bez przyczyny.
4 Satani sì dá Olúwa lóhùn wí pé, “Awọ fún awọ; àní ohun gbogbo tí ènìyàn ní, òun ni yóò fi ra ẹ̀mí rẹ̀.
I odpowiedział szatan Panu, i rzekł: Skórę za skórę, i wszystko, co ma człowiek, da za duszę swoję;
5 Ṣùgbọ́n nawọ́ rẹ nísinsin yìí, kí ó tọ́ egungun rẹ̀ àti ara rẹ̀, bí kì yóò sì bọ́hùn ní ojú rẹ.”
Ale ściągnij tylko rękę twoję, a dotknij kości jego, i ciała jego, ujrzysz, jeźliżeć w oczy złorzeczyć nie będzie.
6 Olúwa sì wí fún Satani pé, “Wò ó, ó ń bẹ ní ìkáwọ́ rẹ, ṣùgbọ́n dá ẹ̀mí rẹ̀ sí.”
Tedy rzekł Pan do szatana: Oto w ręce twojej jest; wszakże żywot jego zachowaj.
7 Bẹ́ẹ̀ ni Satani jáde lọ kúrò níwájú Olúwa, ó sì sọ Jobu ní oówo kíkankíkan láti àtẹ́lẹsẹ̀ títí dé àtàrí rẹ̀.
Wszedłszy tedy szatan od oblicza Pańskiego, zaraził Ijoba wrzodem złym od stopy nogi jego aż do wierzchu głowy jego;
8 Ó sì mú àpáàdì, ó fi ń họ ara rẹ̀, ó sì jókòó nínú eérú. (questioned)
Tak, że wziął skorupę, aby się nią skrobał; i siedział w popiele.
9 Nígbà náà ni aya rẹ̀ wí fún un pé, “Ìwọ di ìwà òtítọ́ mú síbẹ̀! Bú Ọlọ́run, kí ó sì kú!”
I rzekła mu żona jego: A jeszczeż trwasz w uprzejmosci twojej? Złorzecz Bogu, a umrzyj.
10 Ṣùgbọ́n ó dá a lóhùn pé, “Ìwọ sọ̀rọ̀ bí ọ̀kan lára àwọn aṣiwèrè obìnrin ti í sọ̀rọ̀; há bà! Àwa yóò ha gba ìre lọ́wọ́ Ọlọ́run, kí a má sì gba ibi?” Nínú gbogbo èyí, Jobu kò fi ètè rẹ̀ ṣẹ̀.
I rzekł do niej: Tak właśnie mówisz, jako szalone niewiasty mawiają. Izali tylko dobre przyjmować będziemy od Boga, a złego przyjmować nie będziemy? W tem wszystkiem nie zgrzeszył Ijob usty swemi.
11 Nígbà tí àwọn ọ̀rẹ́ Jobu mẹ́ta gbúròó gbogbo ibi tí ó bá a, wọ́n wá, olúkúlùkù láti ibùjókòó rẹ̀; Elifasi, ara Temani àti Bilidadi, ará Ṣuhi, àti Sofari, ará Naama: nítorí pé wọ́n ti dájọ́ ìpàdé pọ̀ láti bá a ṣọ̀fọ̀, àti láti ṣìpẹ̀ fún un.
A gdy usłyszeli trzej przyjaciele Ijobowi to wszystko utrapienie, które nań przypadło, przyszli każdy z miejsca swego: Elifas Temańczyk, i Bildad Suhytczyk, i Sofar Naamatczyk; bo się byli namówili pospołu, aby przyszedłszy pożałowali go, i cieszyli go.
12 Nígbà tí wọ́n gbójú wọn wò ní òkèrè réré, tí wọ́n kò sì mọ̀ ọ́n, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sọkún: olúkúlùkù sì fa aṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya, wọ́n sì ku erùpẹ̀ sí ojú ọ̀run, wọ́n sì tẹ́ orí gbà á.
A podniósłszy oczy swoje z daleka, nie poznali go, i wyniósłszy głos swój płakali, a rozdarłszy każdy płaszcz swój miotali proch nad głowy swe ku niebu;
13 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n jókòó tì í ní inú erùpẹ̀ ní ọjọ́ méje ti ọ̀sán ti òru, ẹnikẹ́ni kò sì bá a sọ ọ̀rọ̀ kan, nítorí tí wọ́n ti rí i pé ìbànújẹ́ rẹ̀ pọ̀ jọjọ.
I siedzieli z nim na ziemi siedm dni i siedm nocy, a żaden do niego słowa nie przemówił; bo widzieli, że się gwałtownie wzmagała boleść jego.

< Job 2 >