< Job 2 >
1 Ó sì tún di ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá síwájú Olúwa, Satani sì wá pẹ̀lú wọn láti pe níwájú Olúwa.
Tendreke indraike te ie nitotsak’eo o anan’ Añahareo hiatrek’ am’ Iehovà, le nitsatok’ am’ iareo ao ka i mpañinjey hiatrefa’e am’ Iehovà.
2 Olúwa sì bi Satani pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Satani sì dá Olúwa lóhùn pé, “Láti lọ síwá sẹ́yìn lórí ilẹ̀ ayé àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”
Le hoe t’Iehovà amy mpañinjey, Boak’ aia v’iheo? Le hoe ty natoi’ i mpañinjey am’ Iehovà, Boak’ ami’ty fihelahelàko an-tane añe naho ty fijelanjelañako ama’e.
3 Olúwa sì wí fún Satani pé, “Ìwọ ha kíyèsi Jobu ìránṣẹ́ mi, pé, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí ń ṣe olóòtítọ́ tí ó sì dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó sì kórìíra ìwà búburú, bẹ́ẹ̀ ni ó sì di ìwà òtítọ́ rẹ̀ mu ṣinṣin, bí ìwọ tilẹ̀ ti dẹ mí sí i láti run ún láìnídìí.”
Le hoe t’Iehovà amy mpañinjey, Fa hinarahara’o hao Iobe mpitorokoy? t’ie tsy añirinkiriñañe an-tane atoy, fa ondaty vañoñe tsy aman-kila; añeveña’e t’i Andrianañahare naho ambohoa’e ty raty; vaho mbe tana’e ty havantaña’e ndra te ihe nañosik’ Ahy ama’e, handrotsak’ aze tsy aman-tali’e.
4 Satani sì dá Olúwa lóhùn wí pé, “Awọ fún awọ; àní ohun gbogbo tí ènìyàn ní, òun ni yóò fi ra ẹ̀mí rẹ̀.
Le hoe ty natoi’ i mpañinjey am’Iehovà, Holitse hasolo holitse, eka, hatolo’ ondaty ze hene fanaña’e ty amy fiai’e.
5 Ṣùgbọ́n nawọ́ rẹ nísinsin yìí, kí ó tọ́ egungun rẹ̀ àti ara rẹ̀, bí kì yóò sì bọ́hùn ní ojú rẹ.”
Fe ahitio henaneo o fità’oo naho gineo ty taola’e naho ty nofo’e vaho honjira’e an-dahara’o.
6 Olúwa sì wí fún Satani pé, “Wò ó, ó ń bẹ ní ìkáwọ́ rẹ, ṣùgbọ́n dá ẹ̀mí rẹ̀ sí.”
Le hoe t’Iehovà amy mpañinjey, Ingo an-taña’o re; fe arovo ty fiai’e.
7 Bẹ́ẹ̀ ni Satani jáde lọ kúrò níwájú Olúwa, ó sì sọ Jobu ní oówo kíkankíkan láti àtẹ́lẹsẹ̀ títí dé àtàrí rẹ̀.
Aa le nienga boak’ añ’atrefa’ Iehovà i mpañinjey vaho zinevo’e am-bae-tovoañe t’Iobe mifotots’ an-dela-pandia’e pak’an-dengo’ i añambone’ey.
8 Ó sì mú àpáàdì, ó fi ń họ ara rẹ̀, ó sì jókòó nínú eérú. ()
Nandrambe tseram-balàñe re hangaotse ty sandri’e, ie niambesatse an-davenoke ao.
9 Nígbà náà ni aya rẹ̀ wí fún un pé, “Ìwọ di ìwà òtítọ́ mú síbẹ̀! Bú Ọlọ́run, kí ó sì kú!”
Le hoe ty vali’e tama’e: Mbe ifahara’o hao ty havañona’o? Injeo t’i Andrianañahare vaho mihomaha.
10 Ṣùgbọ́n ó dá a lóhùn pé, “Ìwọ sọ̀rọ̀ bí ọ̀kan lára àwọn aṣiwèrè obìnrin ti í sọ̀rọ̀; há bà! Àwa yóò ha gba ìre lọ́wọ́ Ọlọ́run, kí a má sì gba ibi?” Nínú gbogbo èyí, Jobu kò fi ètè rẹ̀ ṣẹ̀.
Fa hoe re tama’e, Manao tambaimbain-drakemba deren-drehe. Ty soa avao hao ty ho rambesentika am-pitàn’Añahare? Tsy hirambesañe ka hao ty raty? Amy ie iaby zay, tsy nandilatse am-pivimby t’Iobe.
11 Nígbà tí àwọn ọ̀rẹ́ Jobu mẹ́ta gbúròó gbogbo ibi tí ó bá a, wọ́n wá, olúkúlùkù láti ibùjókòó rẹ̀; Elifasi, ara Temani àti Bilidadi, ará Ṣuhi, àti Sofari, ará Naama: nítorí pé wọ́n ti dájọ́ ìpàdé pọ̀ láti bá a ṣọ̀fọ̀, àti láti ṣìpẹ̀ fún un.
Aa naho nahajanjiñe i fonga feh’ohatse nifetsak’ ama’ey ty rañe’ Iobe telo, le songa nienga an-toe’e t’i Elifatse nte-Temane naho i Bildade nte Sohe vaho i Tsofare nte Naamate, ie fa nifamotoañe te hiheo mb’ama’e hiferenaiñe vaho hañohò’ aze.
12 Nígbà tí wọ́n gbójú wọn wò ní òkèrè réré, tí wọ́n kò sì mọ̀ ọ́n, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sọkún: olúkúlùkù sì fa aṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya, wọ́n sì ku erùpẹ̀ sí ojú ọ̀run, wọ́n sì tẹ́ orí gbà á.
Aa ie nampiandram-pihaino eñe le tsy nahafohiñe aze vaho nipoñafe’ iereo ty fangoihoy; songa nandriatse ty saro’e naho nampibobo debok’ ambone’ ty añambone’e mb’ an-dikerañe ey.
13 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n jókòó tì í ní inú erùpẹ̀ ní ọjọ́ méje ti ọ̀sán ti òru, ẹnikẹ́ni kò sì bá a sọ ọ̀rọ̀ kan, nítorí tí wọ́n ti rí i pé ìbànújẹ́ rẹ̀ pọ̀ jọjọ.
Aa le nindre niambesatse ama’e an-tane eo fito andro naho fito haleñe iereo, sindre tsy nahakofòke volan-draik’ ama’e: amy t’ie nahaoniñe ty halozan-kaorea’e.